Insecurity in Nigeria: Ilana Omo Oodua kín àgbààgbà Àríwá lẹ́yìn pé kí Buhari kọwe fí ipò sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, Muhammadu Buhari
Agbẹnusọ fun ẹgbẹ to n polongo fun idasilẹ orilẹ-ede Yoruba, Ilana Omo Oodua, Ọgbẹni Maxwell Adeleye, ti sọ pe ko si nkan to buru ninu bi awọn agbaagba ni Ariwa Naijiria ṣe sọ pe ki Aarẹ Muhammadu Buhari kọwe fi ipo rẹ silẹ.
O sọ eyi gẹgẹ bi esi si atẹjade ti ẹgbẹ Northern elders Forum fi sita lọjọ Iṣẹgun pe Buhari ko kajuẹ lati pese aabo fun orileeede Naijira.
Ọgbẹni Adeleye sọ pe asiko iwulo Buhari fun Naijiria ti tan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Mo fẹ́ pokùnso torí ìjákulẹ̀ tí ọ̀gá mi, Yekini Ajileye fún mi, ọpẹ́ tọ́ọ́gì kan... - Abija
- Nǹkan márùn-ún tó yẹ kí o mọ̀ nípa Peter, ọkọ Osinachi, tí wọ́n fi ẹ̀sùn ikú aya rẹ̀ kàn
- Ẹ̀yà Yorùbá kò mọ̀ sí ìwọ́de onímílíọ̀nù kan èèyàn tí IPoB ń gbèrò - Ilana Omo Oodua
- Ọdún mẹ́jọ ni ọkọ ọmọ mi kò jẹ́ ki n fojú kan ọmọ mi lẹ́yìn ìgbéyàwó - Ìyá Osinachi
- Ẹ̀yin obìnrin, ẹ tètè jápa tí ìgbéyàwó yín bá ti la ìgbájú-ìgbámú lọ - Olori Silekunola
- Ẹ dákun, ẹ gbà mí, Auxillary ń lépa ẹ̀mí mi - Olopoeyan kọ̀wé sí ọlọ́pàá, DSS
- Buhari, 2023 pẹ́ jù, àsìkò tó láti kọwe fí ipò sílẹ̀ - Àgbààgbà Àríwá
- Kí ló dé tí ẹnu ń kun ìgbeyàwó Funke Akindele pé ó ti dàrú? Àbọ̀ ìwádìí wa rèé
- Ó ti tán fún Nàìjíríà bí ará Àríwá bá tún di Ààrẹ lọ́dún 2023 - Adebanjo
- Ọdún mẹ́jọ ni ọkọ ọmọ mi kò jẹ́ ki n fojú kan ọmọ mi lẹ́yìn ìgbéyàwó - Ìyá Osinachi
- Àkàrà tú sépo fún ayédèrú ọ̀gágun tó fi Khaki lú jìbìtì N266.5m
"A nilo aarẹ ti yoo gbọ nkan ti oriṣiriṣi ẹya to wa ni Naijiria n sọ."
O ni ka ni Buhari n ṣe daadaa ni, ko ni si idi kankan fun ẹgbẹ Ilana Omo Oodua lati ma a beere fun idasilẹ oríle-ede Oduduwa, tabi Biafra ti awọn Igbo n beere fun.
Adeyeye sọ pe ko si nnkan to buru ninu ki Buhari kọwe fi ipo silẹ, bo tilẹ jẹ pe o ti lo ọdun meje nipo.

Àwọn Àgbààgbà Àríwá ní kí Buhari kọwe fí ipò sílẹ̀ tí kò bá rí ojútùú sí ààbò tó mẹ́hẹ

Oríṣun àwòrán, @HQNigerianArmy
Agbarijọpọ awọn agbaagba ilẹ Ariwa Naijiria ti kesi ààrẹ Muhammadu Buhari pe ko kọwe fipo silẹ.
Wọn ni igbesẹ yii di dandan pẹlu bi ko ṣe kajuẹ lati pese aabo fun orileeede Naijira.
Agbẹnusọ awọn agbaagba fun ariwa naa, Hakeem Baba-Ahmed lo fi ọrọ yi sita ninu atẹjade kan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló dé tí ẹnu ń kun ìgbeyàwó Funke Akindele pé ó ti dàrú? Àbọ̀ ìwádìí wa rèé
- Ó ti tán fún Nàìjíríà bí ará Àríwá bá tún di Ààrẹ lọ́dún 2023 - Adebanjo
- Ọdún mẹ́jọ ni ọkọ ọmọ mi kò jẹ́ ki n fojú kan ọmọ mi lẹ́yìn ìgbéyàwó - Ìyá Osinachi
- Àkàrà tú sépo fún ayédèrú ọ̀gágun tó fi Khaki lú jìbìtì N266.5m
- Rògbòdìyàn ṣẹlẹ̀ n‘Ibadan, ọwọ́ tẹ jàǹdùkú nílé Olopoeyan pẹ̀lú káàdì ìdámọ̀ ẹgbẹ́ Auxillary
- "Àwọn ọmọ ogun Russia fipá bá mi lòpọ̀, wọ́n tún pa ọkọ mi"
- Kí ló dé tí ẹnu ń kun ìgbeyàwó Funke Akindele pé ó ti dàrú? Àbọ̀ ìwádìí wa rèé
- Ìjà ńlá bẹ́ sílẹ̀ l‘Eko láàrin igun MC Oluomo àti ẹgbẹ́ awakọ̀ márúwá TOOAN
- Ẹ̀yin obìnrin, ẹ tètè jápa tí ìgbéyàwó yín bá ti la ìgbájú-ìgbámú lọ - Olori Silekunola
Awọn agbaagba naa sọ pe idojuti nla ni pé lẹyìn nkan bi ọdun meje ti Buhari wa lórí aleefa, ko ri ojutu si ipenija aabo to n koju Naijiria.
Atẹjade naa ni "Ko jọ pe ijọba ààrẹ Buhari ni idahun sí àwọn ipenija aabo tá n koju"
"A ko le máa gbé igbe aye aifọkanbalẹ labẹ awọn ajinigbe, apaniyan ati awon to n fipa ba ni lopọ, ti wọn ti gba ẹtọ igbe aye alaafia ati aabo lọwọ wa"
Atẹjade naa tẹsiwaju pe iwe ofin Naijiria fi igbalaye silẹ pe ki olori ti ko ba rojutu ìjọba to n dari, fi t'inu fẹdọ kọwe fipo silẹ"
O ni nitori naa "asiko ti to ki ààrẹ dipo silẹ nitori ijọba rẹ kuna lati pese aabo fun araalu.O ye wa bi ọrọ yi se wuwo sí bẹẹ náà ni ko ruju pe a ko le máa gbé igbe aye ibẹrubojo bayi titi di ọdun 2023 ti aarẹ Buhari yoo fipo silẹ"
Ipo wo ni aabo Naijiria wa bayi?
Ko fẹẹ si apa kan orileede Naijiria ti ipenija aabo to n koju Naijiria yii ko dé.
Yala nipa awọn agbebọn, agbesunmọmi, ajinigbe tabi awọn janduku, ipenija aabo yii jẹ nkan to n koju araalu.
Ni apa Ariwa Naijiria, o sebi ẹni peleke ju awọn ibomiran lọ pẹlu bi awọn janduku ti ṣe jẹ gaba lori araalu, ti awọn eeyan sí wa ninu ibẹrubojo.
Lẹnu ọjọ mẹta yíi, iroyin orisirisi ni o gba ori afẹfẹ kan, ti a sì n gbọ nipa àìmọye eeyan ti o padanu ẹmi wọn lọwọ àwọn alaburu naa.
Ni ipinlẹ bii Kaduna, Plateau, Kebbi, Zamfara to fi mọ Borno ati ibomiran, ojoojumọ ni awọn araalu n gbe oku sin ti awọn alaburu ẹda sí n fun okun mọ alaafia ati aabo lọrùn.

Èèmọ̀ wọ̀lú! Àwọn agbébọn pa ènìyàn 135 lọ́jọ́ kan ṣoṣo

Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe kò dín ní ènìyàn márùndínlógóje tí àwọn agbébọn ṣekúpa ní ìpínlẹ̀ Plateau níbi ìkọlù oríṣiríṣi tó wáyé ní ọjọ́ Àìkú, ọjọ́ kẹwàá, oṣù kẹrin.
Ìlú mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ní ìjọba ìbílẹ̀ Kanam ni àwọn agbébọn náà ṣe ìkọlù sí lórí ọ̀kadà, tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní yìbọn mọ́ àwọn ènìyàn, jó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé, tí wọ́n sì tún jí ọ̀pọ̀lọpọ̀ málùú gbé lọ.
Ọ̀kan lára àwọn olórí nínú àwọn ìlú náà tó bá ikọ̀ ìròyìn BBC sọ̀rọ̀ ní òkú ènìyàn márùnléláàdọ́ta ní àwọn ti rí ní ìlú Kukawa, tí àwọn sì ti tún rí mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ní ìlú Gyambau.
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ní pé Osinbajo dalẹ̀ Tinubu pẹ̀lú bó ṣe kéde láti du ipò ààrẹ?
- Mo fi Ọlọ́run bẹ̀ yín, ẹ má bú ọkọ mi mọ́ torí ìgbéyàwó wa tó túká - Yewande Adekoya
- Kí ló dé tí ọkùnrin yìí fi dojúkọ Kìnìún ààyè?
- Àwọn ọmọ Palestine kọlu ìbòjì Josẹfu ọmọ Jakọbu, wọ́n dásá sún
- "Ẹ̀yin onítíátà, ẹ gbàdúrà fún Kemi Afolabi, Ọlọ́run nìkan ló mọ ibi tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò já sí"
- Mo gbìyànjú láti ṣẹ́yún àkọ́bí mi saájú ìgbeyàwó - Iyabo Ojo
- Oluwo ṣe àbẹ̀wò sí Aláàfin lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ mẹ́ta tó gbé ìyàwó tuntun
- Bí Sunday Igboho bá sọ èròǹgbà rẹ̀ nípa Yoruba Nation, inú gbogbo ọmọ Yorùbá yóò dùn - Banji Akintoye
- Àgùnbánirọ̀ ya fọ́tò Bàbá Onílù láti tà á, òjò owó rọ̀ fún bàbá
- Adigunjalè kọlu iléeṣẹ́ Rédíò Yinka Ayefele ní Ibadan
- Ìtara láti du ẹ̀mí mi gbópọn si torí ìfẹ́ tẹ fi hàn mí - Kemi Afolabi
- Tí mo bá di ààrẹ, ìwúrí ni màá jẹ́ fọ́mọ Nàíjíríà - Tunde Bakare
Bákan náà ló tún fi kun pé àwọn tún ṣàwárí òkú ènìyàn mọ́kànlélọ́gbọ̀n mìíràn ní ìlú méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ mìíràn.
Ó ní àwọn agbébọn mẹ́rìndínlógún náà bá ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún lọ.

Oríṣun àwòrán, TUKUR BUHARI
Ìwádìí fi hàn pé àwọn ọmọdé àti àwọn ọ̀dọ́ wà lára àwọn tó lùgbàdì ìṣẹ̀lẹ̀ láabi náà.
Bákan náà ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti di àwátì nígbà tí wọ́n sá kúrò ní ilé nítorí ìkọlù náà.
Àwọn ará ìlú ní àwọn ti sá kúrò nílé ṣaájú kí àwọn ẹ̀ṣọ́ aláàbò tó wá sí àwọn ìlú náà ní ọjọ́ kejì.
Wọ́n ní ìkọlù yìí ni èyí tó burú jùlọ láti ìgbà tí wọ́n ti máa ń ṣe ìkọlù sí agbègbè yìí.
Ìpínlẹ̀ Plateau ti máa ń kojú ìṣẹ̀lẹ̀ ẹlẹ́yàmẹ̀yà àti ti ẹ̀sìn ṣùgbọ́n àwọn agbébọn àti àwọn ajínigbé ti mú kí ìkọlù náà tún peléke si báyìí.

Afurasí ajínigbé pàgọ́ sí Eko, wọ àdúgbò kan lẹ́ẹ̀mẹta láàrin ọjọ́ méjì

Oríṣun àwòrán, NPF
Bi wọn se n ge awọn ajinigbe lọwọ, bẹẹ ni wọn n bọ oruka yika orilẹede wa Naijiria.
Iroyin kan to tun n gbalẹ bayii ni bi awọn afurasi ajinigbe kan si pagọ si ẹba agbegbe ilegbe Ayobo to wa nilu Eko.
Laipẹ yii si ni ariwo sọ nipa bi wọnb se wọle pa ọkunrin meji ti wọn jẹ ọmọ iya kan soso, ti wọn si tun ji eeyan mẹta ladugbo naa lọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- $50,000 ti mo rí he, tí mo da padà, mú ìyípadà bá ayé mi - Emmanuel
- Igboho ti dé padà! òòsà dé! mi ò sàìsàn! kokoko lára le - Sunday Igboho
- Ṣé Iyabo Ojo ń gbèrò láti ṣe ìgbéyàwó? Wo àwọn ohun tó sọ nípa olólùfẹ́ rẹ̀
- Àyè wá dà, èmi ti ní ọ̀rẹ́kùnrin míràn nítèmi o - Nkechi Blessing
- Wo àwọn ìlú tó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti èèwọ̀ ni kí ènìyàn kú níbẹ̀
- Àwọn agbébọn ṣe ìkọlù sí ilé Kọmíṣọ́nà, jí ìyàwó àti ọmọ rẹ̀ gbé lọ
- MC Oluomo di alága ìgbìmọ̀ ẹgbẹ́ awakọ̀ èrò ìpínlẹ̀ Èkó
Afurasi ajinigbe kọlu agbegbe Ayobo nigba meji laarin ọjọ mẹta:
Gẹgẹ bi iwe iroyin Tribune ti salaye, igba keji ree ti awọn afurasi ajinigbe to dihamọra pẹlu ohun ija oloro naa, yoo ya bo agbegbe Ayobo laarin ọjọ mẹta.
Lọwọ lọwọ bayii, awọn ara adugbo naa ti fẹsẹ fẹ nitori bi wọn se kẹẹfin pe awọn afurasi ajinigbe naa ti pagọ sẹba irekọja odo to wa lagbegbe naa.
Ẹba odo yii si ni wọn pa agọ wọn si, nibi ti wọn n gbe awọn ẹni ti wọn ba ji gbe lọ, ti wọn si n gba owo idoola ẹmi lori wọn.
Ko tan sibẹ, yatọ si tẹgbọn taburo tawọn afurasi ajinigbe naa ran sọrun ọsan gangan, alaga fẹgbẹ awọn onile lagbegbe naa tun ti dero ọrun.
Eyi ko si sẹyin ojora ati iporuru ọkan to mu lasiko tawọn afurasi ajinigbe naa ya bo agbegbe ọhun.
Idi si ree tawọn olugbe agbegbe Ayobo fi n rawọ ẹbẹ sijọba pe ko wa doola ẹmi awọn lọwọ awọn afurasi ajinigbe to mule ti wọn naa.
Ọwọ ti ba afurasi ajinigbe kan lori isẹlẹ yii - Ọlọpaa
Ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Eko ti wa sisọ loju rẹ pe oun ko kawọ gbera lori itu tawọn afurasi ajinigbe n pa ladugbo Ayobo.
Agbẹnusọ fun ileesẹ ọlọpaa Eko, David Hundeyin salaye pe lootọ ni awọn isẹlẹ ijinigbe ati ipaniyan naa waye lagbegbe naa.
Hundeyin ni Kọmisana ọlọpaa ni Eko ti wa pasẹ fawọn agbofinro lati tẹdo si agbegbe naa, ti ọwọ si ti ba eeyan kan to ni nnkan se pẹlu awọn isẹlẹ ọhun.

Àwọn agbébọn ṣe ìkọlù sí ilé Kọmíṣọ́nà, jí ìyàwó àti ọmọ rẹ̀ gbé lọ

Oríṣun àwòrán, Google
Àwọn agbébọn ti ṣe ìkọlù sí ilé igbé Kọmíṣọ́nà fétò àyíká ìpínlẹ̀ Plateau, Usman Bamaiyi, tí wọ́n sì jí ìyàwó àti ọmọbìnrin rẹ̀ gbé lọ.
Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn ṣe fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, ilé ìgbé Kọmíṣọ́nà náà tó wà ní Gindiri, ìjọba ìbílẹ̀ Mangu, ìpínlẹ̀ Plateau ni àwọn agbébọn náà ya wọ̀ ní òwúrọ̀ ọjọ́ Àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹsàn-án, oṣù kẹrin.
Óṣojúmi kòró kan tó bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ ní nǹkan bí aago méjì òru ni àwọn àwọn agbébọn náà ya wọ ìlú Gindiri tí wọ́n sì lọ tààràtà sí ilé Bamaiyi.
- Igboho ti dé padà! òòsà dé! mi ò sàìsàn! kokoko lára le - Sunday Igboho
- Àyè wá dà, èmi ti ní ọ̀rẹ́kùnrin míràn nítèmi o - Nkechi Blessing
- Ẹkùn sọ bí ìròyìn ikú gbajúgbajà olórin ẹ̀mí tó kọ orin 'Ekwueme' ṣe jáde
- Ìtàkùn àpapọ̀ iná mọ̀nàmọ́ná 'National grid' ní Nàìjíríà tún ti paná pi
- Ọ̀rọ̀ ''Zoning'' ipò ààrẹ ní Naijiria dàbí àgbàlàgba tí wọ́n ń fún ní ''baby Formula'' - Dino Melaye
- Tóò bá so síìmù MTN, Glo, Aitel àti 9mobile rẹ pọ̀ tí wọ́n sì tún gbégi lé síìmù rẹ, wo ohun tóo lè ṣe
- Wo àwọn ìlú tó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti èèwọ̀ ni kí ènìyàn kú níbẹ̀
- Ọmọ Nàìjíríà àtàwọn orílẹ̀èdè mìí kò ní l'ánfàní láti ra ilé sí Canada mọ́ o! ìdí nìyí
- À ǹ gbìyànjú láti yánjú àáwọ̀ àárín ẹgbẹ́ wa, àmọ́ àwọn èèyàn ló bẹ̀ mí kí n lọ fún sáà kejì
- Ilé ẹjọ́ wọ́gilé ẹ̀sùn mẹ́jọ nínú mẹ́ẹ̀dógún tí wọ́n fi kan Kanu
- Ẹ wo àwọn ǹkan tó ń fàá tí àwọn kan kò lè ṣe láì ní ìbálòpọ̀ lemọ́ lemọ́ láì sinmi
- Mo tọrọ àforíjì pé mo parọ́ ìgbéyàwó! Mi ò ṣe ìgbéyàwó kankan!
Bamaiyi, tó tún ti fi èròńgbà rẹ̀ láti díje dupò sí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin lọ́dún 2023, ni kò sí nílé lásìkò tí àwọn agbébọn náà ṣe ìkọlù sí ilé rẹ̀.
Ó ṣàlàyé wí pé lẹ́yìn tí àwọn agbébọn ọ̀hún lọ tán ni àwọn tó mọ̀ wí pé wọ́n ti jí ìyàwó àti ọmọ Bamaiyi gbé lọ.
Agbébọn àti àwọn agbéṣùmọ̀mí ti máa ń ṣe ìkọlù sí ìlú wa púpọ̀
Ọ̀kan lára àwọn ara ìlú Gindiri, Ibrahim Chindo ní kìí ṣe ìgbà àkọ́kọ́ rèé tí àwọn agbébọn yóò ṣe ìkọlù sí ìlú àwọn.
Chindo ní inú fo àyà fo ni awọn ènìyàn ìlú náà máa ń wà ní gbogbo ìgbà nítorí kò jọ wí pé àwọn yóò móríbọ́ lórí ọ̀rọ̀ náà láìpẹ́.
Nínú oṣù kejìlá ọdún tó kọjá, àwọn agbébọn yabo ìlú yìí bákan náà tí wọ́n sì jí Ọba ìlú náà, Charles Mato gbé.
A ti ń sa gbogbo ipá wa láti wá wọn rí - iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Plateau, Ubah Ogaba fi ìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀ ṣùgbọ́n ó ní àwọn ti ń ṣiṣẹ́ láti wá àwọn tí wọ́n jí gbé náà rí.



















