MC Oluomo NURTW: Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko yan MC Oluomo gẹ́gẹ́ bí alága ìgbìmọ̀ adarí ẹgbẹ́ awakọ̀ Èkó

Mc Oluomo

Oríṣun àwòrán, Instagram/mcoluomo

Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ti yan ọgbẹni Musiliu Akinsanya, MC Oluomo gẹgẹ bi olori igbimọ ti yoo ma ṣakoso awọn garaji ọkọ ero nipinlẹ naa.

Iyansipo Oluomo waye leyin wakati diẹ ti awọn alasẹ ẹgbẹ́ awakọ ero ni Naijiria, NURTW, yọ MC Oluomo nipo alaga ẹgbẹ́ naa nipinlẹ Eko. Atẹjade ti kọmisana eto iroyin nipinlẹ Eko, Gbenga Omotoso fi sita sọ pe ìjọba da igbimọ olusako naa silẹ, lati le mu adehun ti ijọba ṣe pe oun ko nii jẹ ki wahala to n waye ninu ẹgbẹ́ NURTW da eto aabo ilu rú. Ọgbẹni Omotoso sọ pe nitori naa ni ijọba ṣe lo agbara ofin lati ri pe aye adari ẹgbẹ́ awakọ ko ṣófo, eyi to le da alaafia ipinlẹ Eko ru.

O ni "ojúṣe ti á ni re e si awọn eniyan ipinlẹ Eko, ati awọn olugbe ipinlẹ yi". Oṣu to kọjá ni ìjọba ipinlẹ naa kede pe oun ti ofin de isẹ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ NURTW. Igbesẹ naa waye lẹyin ti awọn adari ẹgbẹ́ naa ni Naijiria da MC Oluomo duro nitori iwa afojudi ati awọn ẹ̀sùn miran. Ni kete ti wọn kede igbesẹ naa, ni awọn adari NURTW nipinlẹ Eko sọ pe awọn ko ṣe ẹgbẹ́ mọ. Yatọ si Ọgbẹni Akinsanya ti yoo jẹ adari ìgbìmọ̀ tuntun naa, kọmisanna ọlọpaa nipinlẹ Eko nigba kan ri, Hakeem Odumosu, ni yoo jẹ alarina laarin igbimọ naa ati ijọba.

Aworan kọmisana ọlọpaa nigba kan ri nipinlẹ Eko Kayode Odumosu

Oríṣun àwòrán, Nigeria Police

Eréepá, yẹ̀yẹ́ lásán lẹ̀ ń ṣe pẹ̀lú bí ẹ ṣe yọ mí nípò alága NURTW ní Eko - MC Oluomo

MCOLUOMO

Oríṣun àwòrán, InSTAGRAM/MCOLUOMO

Alhaji Musiliu Akinsanya ti ọpọ eniyan mọ si MC Oluomo ti sọ pe ere ọmọde ati yẹyẹ ni wọn n ṣe pẹlu bi wọn ṣe yọ oun ni ipo gẹgẹ bi Alaga Ajọ National Union of Road Transport Workers (NURTW) nipinlẹ Eko.

Ọjọru ni Ajọ NURTW lapapọ yọ igbimọ muṣẹya ti NURTW to wa nipinlẹ Eko, ti wọn si yọ MC Oluọmọ gẹgẹ bi alaga ẹgbẹ naa.

Igbimọ naa ni awọn yọ Oluọmọ gẹgẹ bi iwe ofin ẹgbẹ ṣe fi lọlẹ.

Àkọlé fídíò, Bí wọ́n ṣe ń gbé àwọn akẹgbẹ́ mi tó jóná nínú ọkọ̀ jáde, ṣe lara wọn ń bó, wọ́n ń tẹ́ wọn s'atẹ́gùn - Akẹkọ̀ọ́ Akungba

Amọ, ninu esi rẹ si igbesẹ yii ni MC Oluọmọ ti ni ere ọmọde ni ajọ NURTW ti ijọba n ṣe, nitori ẹgbẹ NURTW nipinlẹ Eko ti yọ ara rẹ kuro ninu ẹgbẹ NURTW.

Bakan naa lo beere lọwọ aarẹ ẹgbẹ NURTW idi to fi tapa si ofin to de ẹgbẹ to si gbe igbesẹ ajọ naa kalẹ.

MC Oluomo

Oríṣun àwòrán, @MC Oluomo

O fikun pe igbesẹ naa ko mu ọpọlọ dani.

''Igbẹsẹ yii safihan ohun ti a n sọ nipa iṣekuṣe to n waye ninu ijọba aarẹ Buhari gẹgẹ bi a ṣe sọ lasiko ti a n ba awọn oniroyin sọrọ saaju iṣẹlẹ yii''

''Bi wọn ṣe tuwaka ko mu ọpọlọ dani, amọ a ko ni iṣoro kankan pẹlu ẹgbẹ ni apapọ amọ aarẹ ni a ni iṣoro pẹlu.''

''Bakan naa ni a o bẹrẹ si ni woye ẹni ti wọn yoo fi si ipo lati tukọ ẹgbẹ naa nipinlẹ Eko.''

''Ibeere mi ni pe ṣe ẹgbẹ NURTW ni apapọ ni agbara ju ijọba ipinlẹ Eko to fofin de ẹgbẹ NURTW nipinlẹ naa.''

Àkọlé fídíò, Olaiya Igwe ló wá ra epo níbi tí mo ti ń di "nussle" epo mú mo bá bẹ́ mọ́ ọ́, bí ayé mi ṣe yí padà di òṣèré fíìmù rèé
Àkọlé fídíò, Seye Malaolu: Bí mo ṣe rí àgbára ẹ̀jẹ̀ tó kúnlẹ̀, mò ń bèrè pé ṣé wọ́n pa Turkey níbí ni,

MC Oluomo ni ko bojumu pẹlu bi wọn ṣe yọ awọn ọmọ ẹgbẹ NURTW ti ijọba ipinlẹ Eko ti fofin de ni abẹle.