BBC News, Yorùbá - Ìròyìn
Ìròyìn tó ṣe kókó
Òní ni ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ FCT yóò wáyé
Ẹwẹ, ajọ INEC ni o le ni miliọnu kan abọ ọmọ Naijiria to ti gba kaadi eto idibo, PVC, wọn ni FCT.
Afenifere korò ojú sí bí agbébọn ṣe gbẹ̀mí Kabiesi l'Ondo, ọlọ́pàá ṣèlérí ìdájọ́ òdodo
Awọn ẹbi Kabiyesi naa sọ pe awọn agbebọn naa ti wọn to mẹwaa ya wọ aafin ori ade naa ti wọn si pa si iwaju aafin rẹ.
NPLF gbé ìdájọ́ kalẹ̀ fún Kwara United lẹ́yìn tí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lu rẹfirí àti ikọ̀ Rivers United lálùbami
Ajọ naa tun fofin de lilo papaluu isṣere Rashidi Yekini to wa ni Ilorin fun ikọ Kwara United.
Wo àwọn olóṣèlú tí ìjọba Tinubu ti fẹ̀sùn kíkó owó Naijiria sápò kan
Latigba ti ijọba Aarẹ Bola Tinubu yii ti bẹrẹ ni iwadii awọn oloṣelu bẹẹ ti n waye, to bẹẹ ti awọn oloṣelu ẹgbẹ alatako n sọ pe APC n mọ-ọn-mọ lo ọwọ agbara lori awon ni.
Àwọn Oníṣẹ̀ṣe ní kí INEC sún ọjọ́ ìdìbò Gómìnà Osun síwájú
Dokita Oluseyi tẹsiwaju pe, ọjọ Kẹtadinlọgbọn oṣu Keje si ọjọ Keje oṣu Kẹjọ ọdun 2026 yii ni ayẹyẹ ọdun Ọṣun Oṣogbo, o si maa n to aago mẹfa asalẹ ki ayẹyẹ ọdun naa to pari lọjọ ti idibo yoo ku ọla.
Orin, Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́, Duration 0,52
Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Ìjọba fẹ̀sùn kan ẹgbẹ́ alákatakítí ẹ̀sin Islam pé wọ́n ṣekúpa èèyàn 34 ní àwọn abúlé káàkiri
Awọn ti ori koyọ ṣapejuwe to ṣe ikọlu gẹgẹ bii ti awọn akọsẹmọsẹ, ti wọn si n yin ibọn kaakiri gbogbo ile.
Àwọn alákatakítí ẹ̀sìn kọlu ọjà tòmátò, ṣekúpa ọmọ Ghana méje
Lati ọdun 2019 lawọn agbebọn naa ti n kọlu agbegbe Titao ti iṣẹlẹ ọhun ti waye.
Taiwo Hassan Ogogo: Àwọn èèyàn kan ní Cocaine tú sínú mi, àwọn míì ní mo ní HIV ni
Ogogo ní lọ́dún 2004 ni àárẹ̀ ọ̀hún bẹ̀rẹ̀ gan títí di ọdún 2012 amọ ọdún 2013 ni ara òun ṣẹ̀ṣẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní bọ̀ sípò.
Àwọn ẹ̀gbọ́n ṣekúpa àbúrò wọn àti olólùfẹ́ rẹ̀ tó jẹ́ ẹlẹ́sìn ọ̀tọ̀
Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ní àwọn ẹ̀gbọ́n Kajal ló lù wọ́n títí tí ẹ̀mí fi bọ́ lọ́rùn wọn, tí wọ́n sì sọ pé àwọn afuarsí náà ti wà ná àhámọ́ àmọ́ àwọn afurasí náà kò ì tíì sọ ohunkóhun lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.
BBC ṣèwádìí àwọn ọkùnrin tó ń ya fídíò àwọn obìnrin ní bòńkẹ́lẹ́ lálẹ́ láti fi pawó lórí ayélujára
A ṣe àwárí àwọn obìnrin bíi àádọ́ta tí wọ́n ti ya fídíò wọn, tí a sì ri pé ọ̀pọ̀ wọn ni kò mọ̀ pé wọ́n ya àwọn.
Fídíò, Ṣé lóòótọ́ ni ẹran ajá ni jíjẹ le pa oró májèlé?, Duration 2,07
Orilẹede Naijria jẹ ọkan lara orilẹede ti wọn ti n jẹ aja ni ile Afrika, koda n jẹ mọ pe ọkan lara ọja aja to tobi ju, nibi ti wọn ti n ta aja fun jijẹ wa lorilẹede Naijiria?
Móríwú
BBC News Yorùbá ti wà lórí ìkànnì WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ
Ìròyìn Àkàgbádùn
Àwọn agbébọn tún kọlu agbègbè Kakafu àti Saare ni Kwara
Ikọlu yii waye ni agbegbe Kakafu nijọba ibilẹ Patigi, ti omiran si tun waye ni agbegbe Saare, ni ijọba ibilẹ Ifelodun.
Agbésùnmọ̀mí kọlu ìlú mẹ́ta ní Niger, ṣekúpa èèyàn 30, dáná sun ilé àti àgọ́ ọlọ́pàá
A gbọ pe oniruru ohun ija oloro lawọn agbebọn naa ko lọwọ, bi wọn ṣe yinbọn pa awọn kan naa ni wọn fi ọbẹ rẹ ọrun awọn mii ti wọn si sọ ina si ọpọlọpọ ile ninu ikọlu ọhun.
Israel rọ òjò àdó olóró lé Gaza lórí, èèyàn mọ́kànlá jáde láyé
Ileeṣẹ ọmọ ogun Israel loun ju awọn ado oloro naa lẹyin ti awọn ọmọ ogun Hamas yẹ adehun jogun-o-mi to wa laarin wọn.
Ìjọba àpapọ̀ kọminú lórí bí àwọn ọmọ Naijiria ṣe ń lọ jagun nílẹ̀ òkèrè láì mọ̀
Ninu atẹjade kan lọjọ Aiku, agbẹnusọ ileeṣẹ ijọba to n ri si ọrọ ilẹ okere, Kimiebi Imomotimi Ebienfa, sọ pe awọn ilẹ okere kan n tan ọmọ Naijiria ẹ lati mu ki wọn lọ jagun nilẹ okeere laimọ.
Ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ Abuja: Mo máa ṣiṣẹ́ tako olùdíje tí kò bá ṣe tí Ààrẹ Bola Tinubu - Wike
Wike sọ ọrọ yii niluu Abuja lasiko ọjọbi Sẹbetọ Sandy Onor, to pe ọgọta ọdun laye.
Ọdún Ajé gbéra sọ ní Ile-Ife lónìí
Ọdun Aje yii maa n waye lọdọọdun ni Ile Ife nipinlẹ Osun, to si tun ti bẹrẹ lonii, ọjọ Kẹrindinlogun, oṣu keji ọdun 2026.
Ọwọ́ tẹ afurasí kan tó fipá bá ọrẹ́ méjì ló pọ̀ ni Eko
Ileeṣẹ ọlọpaa lo kede eyi, ti wọn si ni Emmanuel tan awọn ọdọmọbinrin pe oun ni iṣẹ oge ṣiṣe fun wọn ni agbegbe Ajao Estate ni ọjọ Kẹjọ oṣu keji ọdun 2026.
"Àwa òṣìṣẹ́ ilé ẹ̀kọ́ Rufus Giwa nìkan ni òṣìsẹ́ tó ṣì n gba ₦18,000 owó oṣù ní Naijiria"
Awọn oṣisẹ naa pejọ si iwaju ẹnu ọna abawọle ile ẹkọ naa ni ilu Ọwọ nipinlẹ Ondo ti wọn si n kọ oniruru orin, pẹlu akọle pe iya yii to gẹ.
Aráàlú fi ìlú sílẹ̀ ní Kwara lẹ́yìn tí àwọn agbébọn kọ lẹ́tà pé àwọn ń bọ̀
Aṣoju kọroyin wa kan si awọn ile ẹkọ meji ni ilu ọhun, Muslim Primary school ati Ira Grammar School Ira, ṣe ni gbogbo ẹ da paro paro latari bawọn akẹẹkọ ati olukọ ṣe fìdi mọ le.
Àwọn ọmogun Naijiria ṣekúpa àwọn jàndùkú agbébọn méjì l'Ondo
Awọn ikọ ọmogun 32 Artillery Brigade ti wọn ko lọ si agbegbe Auga nipinlẹ Ondo lo ṣe isẹ naa lasiko ti wọn wa loju isẹ ni opopona Akunu si Auga ni ọjọ kẹrinla oṣu yii.
INEC kéde ọjọ́ ìbò ààrẹ 2027 àtàwọn mí-ín
Alaga ajọ INEC, Ọjọgbọn Joash Amupitan lo fi alakalẹ eto idibo naa lede lọjọ Ẹti, ọjọ kẹtala, oṣu Keji ọdun 2026, nibi ipade oniroyin kan l'Abuja.
"Awuyewuye lórí aṣọ tó bo Kaaba, tó jẹ́ ohun mánigbàgbé tí wọ́n fi ránṣẹ́ sí Epstein''
Aṣọ yii ni wọn fi siliki dudu ṣe, Kiswa jẹ aṣọ to ni awọn akọle Al-Qur'an lara ti wọn kọ pẹlu wura ati fadaka. O bo gbogbo awọn odi ode mẹrin ti Kaaba, eto okuta ni aarin Mossalassi nla ni Mekka.
Ìròyìn Pàtàkì
Ẹ tẹ̀lé wa lórí ìkànnì ayélujára
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Seyi Makinde sọ Baálẹ̀ mẹ́rìnlá di ọba aládé l'Oyo
Igbakeji gomina Oyo, Bayo Lawal to soju fún Makinde lo gbe ọ̀pá àṣẹ fún àwọn baalẹ tó di ọba náà.
Ohun tí a mọ̀ rèé nípa ìpàdé ìdákọ́nkọ́ tí Makinde ṣe pẹ̀lú Atiku àti Babangida
Ọpọ eeyan lo ti n beere wi pe ki ni ipade Makinde to jẹ ọmọ ẹgbẹ PDP ati Atiku ti i ṣe ọmọ ẹgbẹ oṣelu ADC pẹlu Babangida le da le lori.
Kenya fòfin de fífi owó ṣe òdòdó
Láti fi owó ṣe òdòdó, wọ́n máa ká owó, tí wọ́n sì máa to àwọn owó náà papọ̀ dáadáa láti lè jẹ́ kó dàbí òdòdó.
Ajara wà láàrin wa báyìí, O ń wo ǹkan tí à ń ṣe.....Alfa Ibrahim to rọ́ wáàsí
Oṣere ti ọpọ eeyan mọ si Anti Ajara naa jade laye lọjọ karun-un oṣu Keji ọdun 2026 yii, lẹyin aisan to ni I ṣe pẹlu ẹdọ, to si tun wa nipo iloyun lasiko ti ọlọjọ de naa.
Ilé ẹjọ́ nỉ Eko sọ ọmọ ilẹ̀ China méjì sẹ́wọ̀n fún jìbìtì orí ayélujára
Ilé ẹjọ́ ní tàbí káwọn èèyàn náà san owó ìtanràn mílíọ̀nù márùndínlọ́gọ́ta náírà.
Ṣọ́ọ̀ṣì tó bá ṣe ìsìn kọ́ja aago mẹ́rin ìrọ̀lẹ́ yóò fojú winá òfin- ìjọba Kogi kìlọ̀ nítorí ìkọlù agbébọn
Gẹgẹ bi Kọmiṣanna eto iroyin ni Kogi, Kingsley Femi Fanwo, ṣe wi, ikilọ yii n waye lati dena ikọlu awon agbebọn fun awon olujọsin lasiko ti wọn ba n ṣe isin to pẹ ju lọwọ.
Agbébọn ṣàfihàn fídíò ọ̀gọ̀rọ̀ èèyàn tí wọ́n jí gbé ní Kwara, wọ́n ní 176 làwọn jí gbé, kìí ṣe 32
Ọjọ kẹta osu Keji, ọdun 2026 yii ni awọn agbebọn ṣakọlu si ilu Woro ni ijọba ibilẹ Kaiama ni ipinlẹ Kwara ti wọn si pa ọgọọrọ eeyan, wọn si tun gbe aimọye awọn obinrin ati awọn ọmọde gbe lọ.
Wo orílẹ́èdè mẹ́sàn án tí ìjọba ti fòfin de tàbí tí ó ti nira láti ṣe àyájọ́ ọjọ́ olólùfẹ́
Ayajọ naa bẹrẹ pẹlu awọn ọmọlẹyin Kristi nigba ti wọn maa n ranti agbaọjẹ kan ninu igbagbọ ti wọn n pe orukọ rẹ St. Valentine ẹni ti wọn gbagbọ wi pe o fi ifẹ han sawọn eeyan.
Atiku, Bashir Ahmad korò ojú sí oṣù Kejì ọdún 2027 tí INEC kéde fún ìbò ààrẹ torí Ramadan, INEC ṣàlàyé ìdí abájọ
INEC ṣalaye ninu atẹjade kan to fi sita eyi ti ọkan lara awọn ọga agba ajọ naa, Muhammed Kudu Haruna, buwọlu wi pe asiko to wa ninu iwe ofin Naijiria ti ọdun 1999 ni awọn fi ṣe agbekalẹ ọjọ idibo ọhun.
Wo ohun mẹ́fà tó yẹ kí o mọ̀ nípa Ismail Abba Yusuf alága àjọ Hajj tuntun tí Tinubu yàn
Ọpọ iroyin lo jade lọjọ Aje pe Usman kọwe fipo rẹ silẹ nitori ọpọ ẹsun ti wọn fi kan.
APC, NNPP Kọminú lórí ìgbésẹ̀ Amẹ́ríkà láti fòfin de Kwankwaso lórí ìkọlù sáwọn Kristẹni
Ní ọjọ́ Kẹwàá, oṣù Kejì, ọdún 2026 ni aṣòfin ilẹ̀ Amẹ́ríkà, Riley Moore kéde lójú òpó X rẹ̀ pé òun àtàwọn akẹgbẹ́ òun, Chris Smith, Brian Mast àti Bill Huizenga ti gbé àbá kan dìde láti kojú bí wọ́n ṣe ń pa àwọn ọmọlẹ́yìn Kristi ní Nàìjíríà.
Èèyàn 80 móríbọ́ lọ́wọ́ ikú bí bààlúù tó ń lọ sí Port Harcourt ṣe balẹ̀ sí Benin
Gẹgẹ bi a ṣe gbọ, ilu Eko ni ọkọ baaluu Arik Air Boeing 737-700 naa ti gbera, ṣugbọn ko le de Port Harcourt to n lọ to fi koju iṣoro laaarin ọna.















































































