Seyi Makinde: Láàrin àáwọ̀ àárín ẹgbẹ́ PDP, ìdí tí mo fi fẹ́ lọ fún sáà kejì gẹ́gẹ́ bíi gómìnà Oyo rèé

Oríṣun àwòrán, SeyiMakinde/Facebook
Gomina ipinlẹ Oyo Seyi Makinde ti fesi si idi to fi fi erongba rẹ han lati dije du ipo gomina fun saa keji.
Agbẹnusọ fun gomína ìpinlẹ Oyo Taiwo Adisa fi aridaju iroyin naa han pe gomina ipinlẹ Oyo Seyi Makinde ti fì erongba rẹ hàn látí dìje dupo gomìnà ípìnlẹ̀ Oyo.
O jẹ ko di mimọ pe nigba ti gomina fi ọrọ naa lọ awọn eeyan ni ẹlẹgbẹ jẹgbẹ ni ipinlẹ Oyo bẹ Makinde lati dije lẹẹkan sii.
Bo tilẹ jẹ pe aawọ oriṣiriṣi lo wa nínù ègbẹ ṣùgbọ́n gòmìnà Makinde ti gbé igbèṣẹ̀ látì mu òpìn ba gbògbò ikùnsínù to wa nínù ẹgbè oṣelu PDP nìpìnlẹ óyò nìtórì gbògbò ádárì inu ẹgbẹ ni gòmìnà Makinde ṣe ìpàdé pẹlu.
O ṣalaye pe awọn iṣẹ ìlù tì gòmìnà Mákìndè ti bẹrẹ látí 2019 ló ní láti ṣe pari.
Lara aawọ mii to tawọn eeyan tun maa n sọrọ gẹgẹ bii aawọ to wa laarin awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu PDP nilẹ Yoruba tun ni eyi to wa laarin Makinde ati Ayo Fayose, gomina ipinlẹ Ekiti tẹlẹ.
Ẹwẹ, ọrọ yii ko yọju rara ninu iwadii wa tori gomina Seyi Makinde ni ko si ẹnikẹni ti ẹgbẹ yan ti oun ko ni ti lẹyin.
"Niwọn igba to ba ti jẹ afẹnuko ẹgbẹ wa ni, digbi ni mo wa lẹyin ẹni ti ẹgbẹ ba fẹnuko le lori koda bo ṣe gomina Ekiti tẹlẹ, Ayo Fayose".
Ti ẹyin ara ilu Oyo ba gba mi laaye, ṣe mo ri 'kan sii?
Gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde ti fi ero rẹ han lati dije dupo gomina fun saa keji ni ipinlẹ Oyo.
Makinde fi eyi lede ninu lẹta ti o ma n fi lede fun awọn eniyan ni ẹẹmẹji ni oṣu.
Gẹgẹ bi ọrọ rẹ, O ni oun ti ṣeleri ninu lẹta oun ti saa to kọja wi pe nigba ti eleyii ba ma a fi jade, oun ati pinnu boya lati dije dupo fun saa keji gẹgẹ bi gomina nipinlẹ Oyo.
- Ijọba gbé ìlànà tuntun jáde fún ìgbẹ́jọ́ àwọn agbesùnmọ̀mí bí Nnamdi Kanu ṣe ń farahàn nílé ẹjọ́ lónìí
- Mo tọrọ àforíjì pé mo parọ́ ìgbéyàwó! Mi ò ṣe ìgbéyàwó kankan!
- Pásítọ̀ Leke Adeboye tọrọ̀ àforíjì ,ó kọ̀wé ẹ̀bẹ̀ sí àwọn pásítọ̀ ìjọ tó kàn labùku
- Ìjọba Eko sọ àgádágodo sí ilé ìwòsàn lẹ́yìn tí alákọ́bí pàdánù ẹ̀mí rẹ̀ lásìkò ìkúnlẹ̀
- MC Oluomo di alága ìgbìmọ̀ ẹgbẹ́ awakọ̀ èrò ìpínlẹ̀ Èkó
''Ọsẹ to kọja ni mo gba fọọmu lati fi ero mi han nipa idije dupo fun saa keji gẹgẹ bi gomina awọn eniyan rere ni ipinlẹ Oyo''
''Bẹẹni mo fẹ ṣiṣẹ fun awọn ara ilu ipinlẹ Oyo lẹẹkeji ti wọn ba gbami laaye''
''Lati nkan bi ọdun mẹta ṣẹyin ni a ti n ṣiṣẹ takuntakun, ti a ko si yọ agbegbe kankan silẹ''

''A ti ṣiṣẹ lati mu ipinlẹ Oyo di ilu igbalode ti awọn eniyan yoo ti ni igbeaye irọrun ti gbogbo iṣọrọ to n koju wọn yoo si di ohun igbagbe.
- Ọ̀rọ̀ 'Consensus' ò kàn mí, láíláí mí ò lè fagilé èròńgbà mi láti dupò ààrẹ torí ẹnikẹ́ni - Ayo Fayose
- 'Olówó tabua ní Tinubu kó tó wọ òṣèlú, iṣẹ́ àánú ló ń ṣe kiri'
- Wo ǹkan tí o kò mọ̀ nípa ESABOD tí òun àti Lizzy Anjorin jọ ń fi omi èpè wẹ ara wọn
- Ọgá Báńkì tàá tú sílẹ̀, tórí ọjọ́ orí rẹ̀ àti ọlá Ramadan ni - Ajínigbé
- Ẹ̀ṣọ́ Ààrẹ Nàìjíría tẹ́lẹ̀ rí Goodluck Jonathan méjì pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìjàmbá ọkọ̀
- Ẹ wo ohun tó mú ọkùnrin ẹni ọdún 67 fẹ́ kó sí ''lagoon'' l'Eko l'ọ́jọ́ ìbí rẹ̀
Gomina ipinlẹ Oyo naa fikun pe o wu oun lati ṣe gudugudu meje yaya mẹfa ju ti tẹlẹ lọ.
Ọdun 2019 ni awọn ara ipinlẹ Oyo dibo yan Seyi Makinde lati ẹgbẹ oṣelu PDP gẹgẹ bi gomina wọn.

















