Abuja-Kaduna Train Attack: Bí èèyàn kan lára èrò ọkọ̀ rélùwè tí wọ́n kọlù ní Kaduna ṣe gba òmìnira láhàámọ́ ajínigbé

Oríṣun àwòrán, FALWAN HASSAN
Àwọn agbebọn to kọlu ọkọ reluwe kan nipinlẹ Kaduna, ti yọnda ẹnikan lara awọn ero ọkọ ti wọn jigbe.
Ọjọ Aje ọ̀sẹ̀ to kọja ni ìkọlù naa waye lasiko ti ọkọ reluwe naa n rinrinajo lati ilu Abuja si Kaduna.
Mọlẹbi ẹni ti wọn yọnda, Alwan Hassan, to jẹ oludari Banki eto iṣẹ agbẹ ni Naijiria, sọ fun BBC pe alẹ Ọjọ́rú ni wọn tu u silẹ.
Hassan ni ẹni àkọ́kọ́ to gba ominira lara awọn ero ọkọ reluwe ti awọn agbebọn naa jigbe.
Ninu fidio kan to wa lori ayelujara, eyi ti àwọn ajinigbe naa yà ṣáájú ominira rẹ, a ri Hassan to duro laarin gende ọkùnrin mẹrin to fi nkan bo oju wọn, ti wọn si gbe ìbọn dani.
"Wọn duro ninu igbó lẹgbẹ́ ọkọ ijagun kan to dabi pe o ti jona".
Àwọn agbebọn naa sọ pe awọn pinnu lati yọnda rẹ nitori pe aanu rẹ ṣe wọn, paapaa nitori ọjọ́ ori rẹ, ẹ̀bẹ̀ to bẹ àwọn, ati nitori awẹ Ramadan to n lọ lọwọ.
Ẹnikan lara awọn agbebọn naa sọ pe ijọba gbọ́dọ̀ ṣe nkan ti awọn n fẹ́, ki àwọn to fun àwọn eeyan to ku ni òmìnira.
Ṣùgbọ́n wọn ko sọ awọn nkan ti wọn fẹ, tabi iye eeyan to kù si ahamọ wọn.
Àmọ́ wọn ni kii ṣe owó itusilẹ ni àwọn n fẹ́.
"Ìjọba, a ko fẹ owo yin. Ẹ mọ awọn nkan ti a n beere lọwọ yin."
Bakan naa ni wọn kò sọ ẹgbẹ́ ti wọn n sisẹ fun.
Titi di asiko yii, a ko tii mọ iye eeyan ti wọn jigbe lasiko ìkọlù naa.
Ṣùgbọ́n awọn alaṣẹ sọ pe ọtalelọọdunrun ati meji, 362, eeyan lo wa ninu ọkọ reluwe naa.
Wọn pa eeyan mẹjọ. Ko si iroyin kankan ti a gbọ nipa eeyan mejidinlaadọsan.
A ko le sọ boya gbogbo awọn ero ọkọ to di awati ni wọn jigbe tabi boya àwọn kan lara wọn ti lọ si ile wọn lẹyin ti wọn bọ́ ninu ikọlu naa, lai sọ fun ijọba.
Gomina ipinlẹ Kaduna, Nasir el-Rufai sọ pe àwọn agbesunmọmi Boko Haram lo ṣe ikọlu naa, pẹlu ajọṣepọ awọn ọ̀daràn kan to n sisẹ ni agbegbe ọhun.

Oríṣun àwòrán, NRC
Eeyan 168 la ṣi n wa lara awọn to wa ninu ọkọ Reluwee
lleeṣẹ ọkọ reluwe ti kede pe eniyan mejidinlaadọjọ(168) ni awọn ṣi n wa lẹyin oṣẹ kan ti awọn agbebọn ṣekọlu si ọkọ irinna reluwe Abuja si Kaduna.
O kere tan eniyan mẹjọ lo ku ninu iṣẹlẹ naa to waye ni Ọjọ Kejidinlọgbọn, Osu Kẹta, ọdun 2022.
Awọn agbebọn naa lo lo ado oloro lati fi ṣọṣẹ ti wọn bẹrẹ si ni yinbọn lu ọkọ naa.
- Ọ̀nà kan dí, ọ̀nà míì ṣí lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀! Imáàmù táwọ́n aláṣẹ́ dá dúró ti ríṣẹ́ míì tó ta lẹ́nu
- "Mo sá fún oògùn owó, igbó mímu, mo tún ní sùúrù fún ọdún 15 kí n tó di olókìkí"
- Ìjọba pàṣẹ fún àwọn iléeṣẹ́ ìbánisọ̀rọ̀ láti fi òfin de ìpè lórí fóònù àwọn tí kò so NIN mọ́ nọ́mbà wọn
- A máa ń lọ yọjú wo Yinka Quadri tó bá ń ṣe fíìmù ládùúgbò wa - Ẹ wo bí Dejo Tunfulu ṣe bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ Tíátà
Ninu atẹjade ti ileeṣẹ ọkọ reluwe gbe jade ni wọn ti salaye pe eniyan ọ́talelọ́ọ̀dúnrún (362) lo wa ninu ọkọ reluwe naa nigba ti awọn agbebọn ṣekọlu si wọn.
Wọn fikun un pe awọn ko mọ ibi ti eniyan mejidinlaadọjọ(168) wa lọwọlọwọ.
Ileeṣẹ reluwe naa fikun un pe o ṣeeṣẹ ki awọn ẹlomiran ninu wọn ti pada si ile wọn tabi ki wọn wa lara awọn ti wọn jigbe lọ.

N kò rí oorun sùn lórí iṣẹ́ ibi àwọn agbésùnmọ̀mí, òògùn oorun gan kò ràn mí - El-Rufai
Gomina ipinlẹ Kaduna, Nasir El-Rufai ti tọrọ aforijin lọwọ araalu lori ikọlu asekupani to n waye nipinlẹ Kaduna, paapaa si reluwe.
Gomina naa, ẹni ti ara rẹ si n gbọn lori awọn ikọlu lemọlemọ ọhun ni oun ko tii ri oorun sun lati ọjọbọ, koda oogun oorun gan ko sisẹ lara oun nitori iporuru ọkan.

Oríṣun àwòrán, KDGOV
El-Rufai, ẹni ti igbakeji rẹ, Hajiya Hadiza Sabuwa Balarabe atawọn ọmọ igbimọ alasẹ ijọba rẹ kọwọrin lọ sabẹwo si ijọba ibilẹ Giwa lọjọbọ lati bawọn eeyan ibẹ kẹdun, lo salaye bẹẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹ wo orúkọ àti ojú àwọn èèkànlú tó forí sọta ìkọlù rélùwéè àti ipò tí wọn dì mú
- Osinbajo ṣe àbẹ̀wò síbi ìkọ̀lù ọkọ̀ rélùwè ní Kaduna, ó ní kí ọmọ Naijiria ṣe ọkàn gírí
- Ẹ fura o! Ètò ààbò Nàìjíríà ti ń dàbí ti Afghanistan - Afenifere lọgun
- Tẹ̀gbọ́n tàbúrò hú òkú bàbá wọn láti fi ṣe òògùn owó ní Kwara
- Adájọ́ gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹ̀bẹ̀ Rahmon Adedoyin tó ní òun kò ní ẹjọ́ láti jẹ́
- Agbébọn ṣé ikọlù sí pápákọ̀ òfurufú Kaduna, èèyàn kàn kú níbẹ
- Tọkọtaya kó sí gbaga ọlọ́pàá f'ẹ́sùn jíjí ọmọ ọjọ́ mẹ́fà gbé
- À ń wá láti Ibadan, wá jí ọ̀pọ̀ ọmọ gbé l‘Eko fún ètùtù ọla - Afurasi ajọmọgbe
- Ẹ̀mí 15 bọ́ ní Abeokuta àti Sagamu bí ìjà ẹgbẹ́ òkùnkùn ṣe ń ràn kiri l‘Ogun
Ninu fọnran ohun gomina ti amugbalẹgbẹ gomina naa fi ransẹ si BBC, El-Rufai ni akoko diẹ ni ohun ni ẹtọ lati se adari ijọba mọ.
Amọ o ni lọjọ kan, oun yoo duro niwaju Oluwa lati salaye nipa awọn ohun to n sẹlẹ yii ati igbesẹ ti oun gbe nipa rẹ.
"Mo n bẹru ọjọ ti maa duro niwaju Oluwa lati sọ awọn ohun gbogbo ti mo ti gbe ile aye se, ki wa ni maa ma sọ?
Nitori naa, mo n bẹbẹ fun idarijin yin, ki n le roju raye se ijọba."
Ko si aniani pe a ti kuna, ohun gbogbo si ti dojuru:
Bakan naa ni gomina ipinlẹ Kaduna n fi ika hanu pe ijba to wa lode yii ti kuna, awọn ko si ni awijare kankan lori awọn ohun to n sẹlẹ yii.
O ni labẹ irora to lagbara ni oun ti n jẹwọ ẹsẹ oun, bẹẹ si ni ijẹwọ ẹsẹ naa gan tun n mu irora nla ba oun.
"Mo n ro tẹlẹ pe ko si isoro rara, amọ lọwọ lọwọ bayii, mo ti ri pe wahala gidi lo wa.
Lọdun meji si mẹta sẹyin, a mọ ibi tawọn adunkookomni naa wa, gbogbo rẹ la mọ.
A ni awọn eeyan to n se alami fun wa, to fi mọ awọn osisẹ ọtẹlẹmuyẹ, ọlọpaa, ologun atawọn osisẹ alaabo miran.
Koda, a da awọn olubi ẹda to n sisẹ laabi yii mọ nitori ọ̀pọ wọn ni wọn ti pa sẹyin."
Wọn ko awọn aba mi danu ni:
El-Rufai tẹsiwaju pe akoko kan wa ti oun daba pe ki awọn yabo gbogbo awọn igbo kijikiji ati abule tawọn agbesunmọmi yii wa, ka si maa jo wọn nina kanlẹ.
O ni oun daba naa nitori bi ọwọja isẹ ibi awọn agbesunmọmi naa se n peleke si lojoojumọ ni.
Amọ o ni oun ko ri atilẹyin awọn ologun gba lori aba naa nitori wọn ni niwọn igba ti kii se ogun lawọn n ja, tawọn ba se amusẹ aba mi, awọn le kan isoro lọjọ iwaju.
El-Rufai ni awọn ologun naa lo lero pe ni ọjọ iwaju, wọn le mu awọn tawọn ba lọ soke okun, ki wọn si fi ẹsun hihu iwa ọdaran loju ogun kan awọn pe awọn pa araalu.
O wa n kabamọ pe wọn ko se da ẹbi fawọn apaniyan yii, to si ni niwọn igba ti ile ẹjọ ti kede pe agbesunmọmi ni wọn, lawọn ti n pariwo pe ki wọn sun awn igbo nlanla naa, amọ wn ko tẹle imọran oun.
Mo ti gbọ saaju pe wọn yoo kọlu reluwe:
Gomina ipinlẹ Kaduna ni o ti to osu meji sẹyin ti oun ti gbọ latẹnu awọn osisẹ alaabo ọtẹlẹmuyẹ pe awọn agbesunmọmi n gbero lati kọlu reluwe.
"Koda, gbogbo awọn ihuwasi ati lilọ bibọ awọn agbesunmọmi yii la mọ ati ibuba wọn pẹlu
Koda a ba awọn alasẹ ileesẹ reluwe sọrọ lori pe ki wọn mase rin ni alẹ amọ wọn kọ jalẹ.
A salaye ninu lẹta ta tun kọ si wọn pe o rọrun lati se akoso eto irinna loju mọmọ ti ohunkohun ba tiẹ sẹlẹ amọ wọn ko gbọ."
Mo n sọ gbogbo eleyi lati jẹ kawọn araalu mọ pe awọn eeyan kan to yẹ ki wọn se isẹ wọn, ni wọn kọ, ti wọn kuna lati se.
Amọ gomina naa ni awọn ko ni tu eekanna lọrun aarẹ ati ileesẹ ologun titi ti eto aabo to peye yoo fi fidi mulẹ.
























