Lateef Adedimeji: Mo ti gba ₦1,000 péré rí láti kópa nínú fíìmù

Lateef Adedimeji

Oríṣun àwòrán, @adedimejilateef

Gbajumọ oṣere tiata Yoruba, Lateef Adedimeji ti tu pẹrẹpẹrẹ bo ṣe kọ ẹyin si oogun owo, igbo mimu atawọn iwa ipa mii to si rọju fun nnkan bii ọdun marundinlogun ki okiki rẹ to tan kari aye.

Adedimeji lo fi ọrọ naa lede lasiko to n sọrọ nibi idanilẹkọọ Ramadan kan to waye ni gbagede ileeṣẹ iroyin NTA Channel 10.

Nigba to n sọrọ nipa idagbasoke awọn ọdọ, Adedimeji to jẹ oṣere ati olukọ ẹsin Musulumi gba awọn ọdọ nimọran lati ma ṣe kọ Ọlọrun silẹ ninu ilepa wọn fun aṣeyọri.

Àkọlé fídíò, Seye Malaolu: Bí mo ṣe rí àgbára ẹ̀jẹ̀ tó kúnlẹ̀, mò ń bèrè pé ṣé wọ́n pa Turkey níbí ni,
Àkọlé fídíò, 'Ojú mi méjèjì pé lọ sí ọ́fíìsì àwọn ọlọ́pàá SARS, bí mo ṣe di afọ́jú ọ̀sàn gangan lórí ẹ̀sùn jíjí pọ́ọ̀sì “customer” tí mi ò mọ

O ni ikoro ni yoo gbẹyin awọn ọdọ to n ṣe oogun owo.

Adedimeji sọ pe "Ọpọ awọn ọdọ to ni okun bii temi bayii lo n ṣe oogun owo laye ode oni."

"Omugọ nikan ni ko ni ṣiṣẹ ti yoo si maa reti owo... Awọn baba kan nibikan yoo sọ fun yin pe ki ẹ po awọn nnkankan pọ lọna ati lowo, iya ni yoo gbẹyin rẹ o."

"Mi o ni okiki ti mo ni loni yii titi di ẹyin ọdun marundinlogun ti mo ti n ṣe iṣẹ tiata, emi na iba ti ṣe awọn nnkankan ti ko ṣee fẹnusọ amọ mo kọ lati ṣe bẹẹ nitori mo ni imọ."

Àkọlé fídíò, BBC Africa Eye díbọ́n bíi ọmọ ìjọ, àṣírí àwọn Pásítọ̀ èké nílẹ̀ yìí tú sí wa lọ́wọ́

"Lọdun naa lọhun, mo ri awọn ti a jọjọ bẹrẹ ti wọn di gbajumọ ṣaaju mi, ti mo ba jẹ ẹni ti ko ni oye ni, ni ṣe ni mo maa lọ ba wọn fun iranlọwọ."

"Amọ kaka ki n ṣe bẹẹ, ni ṣe ni mo lọ ba afaa mi, ti mo si sọ fun pe adura mi ko tii gba, ṣugbọn o ni ki n ni suuru pe akoko temi yoo de."

Mo ti gba 1,000 lati ṣe fiimu ri

Adedimeji sọ siwaju si pe wọn ti san ẹgbẹrun kan naira fun oun ri lati kopa ninu fiimu, ti oun si lo ọjọ mẹwaa gbako ni ibi ti wọn ya fiimu ọhun.

O fi kun pe adura oun ti gba bayii nitori owo gọbọi ni oun n gba lati kopa ninu sinima.

Oṣere naa pari ọrọ rẹ pe adura oun gba nitori oun duro ti Ọlọrun dipo ki oun maa fa igbo gẹgẹ bii awọn kan ṣe gba oun niyanju lakoko naa lọhun, bẹẹ si ni oun kọ lati da ọgbọn si ṣugbọn oun duro de akoko Ọlọrun.

Àkọlé fídíò, Babatunde Adejumo: Ọdún méje ní mi fi sá kúrò nídìí iṣẹ́ aṣerunlọ́sọ̀ọ́ àmọ́ mo padà