Sheikh Nuru Khalid: Imáàmù táwọ́n aláṣẹ́ dá dúró ti ríṣẹ́ míì tó ta lẹ́nu

Oríṣun àwòrán, Sheik Nuru Khalid
Ṣẹ́ẹ mọ̀ pe Yoruba ni "bi wọn ṣe n ṣe nilee wa, eewọ ibomii ni lo mu oriire ba Imaamu Nuru Khalid to sọrọ si aarẹ Buhari to si tori rẹ gba idaduro ni Mọṣalaṣi.
Imaamu Mọṣalaṣi to wa ni agbegbe Apo Legislative Quartres ni Abuja eyi to ṣẹ gba idaduro iyẹn Sheik Nuru Khalid ti riṣẹ mii bayii.
Iroyin ni awọn alaṣẹ ati oludari Mọṣalaṣi Jumaa tuntun kan ni Area 11 ni ẹyin Banki apapọ Naijiria ti ni ko bẹrẹ iṣẹ lẹsẹkẹsẹ ni Jumaa ọjọ Jimoh to n bọ, ọjọ kẹjọ oṣu Kẹrin.
Khalid gba idaduro lẹyin to sọ ọrọ alufansa si Aarẹ Muhammadu Buhari nitori ikọlu si ọkọ oju irin to ṣlẹ lọjọ Aje to kọja ni ọna Abuja si Kaduna.
Ẹwẹ, oun funrarẹ ṣapejuwe idaduro rẹ gẹgẹ bi ara ifarada to oun ni lati la kọja pe oun ni imọlara iya to n jẹ awọn araalu ati pe o sọ otitọ. Khalid fi ọrọ sita pe "nipa ore-ọfẹ Ọlọrun, n o maa dari awọn olujọsin mi ni ọjọ Ẹti yii, nitoripe gẹgẹ bii adari ẹsin, a nilo ibi kan lati maa darapọ mọ".
Bí wọ́n ṣe yọ ìmáàmù Mọ́ṣáláṣí Apo, Sheik Nuru
Sẹnetọ Saidu Dansadau to jẹ alaga igbimọ Mọṣalasi Apo, niluu Abuja ti sọ pe awọn ti da Sheik Muru Khalid duro lẹyin ti wọn ti kọkọ ni ko lọ rọọkun nile ṣaaju.
Sẹnetọ Dansadau ṣalaye fun BBC pe awọn gbe igbesẹ naa lẹyin ti Imaamu ọhun kọ lati tuba lẹyin awọn ọrọ to sọ ninu waasi rẹ lọjọ Ẹti.
Ninu iwe idaduro ti wọn fi ranṣẹ si Imaamu naa, wọn ni awọn ṣawari pe ko kabamọ ohun to ṣe lẹyin ti wọn ni ko lọ rọokun nile, eredi ree ti ijiya rẹ fi gbe pẹẹli si.
- Ǹkan ọmọkùnrin rẹ ńgbálẹ̀ kiri, gbogbo ìlú ló wà fún; Gbas gbos tún bẹ̀rẹ̀ láàrin Tontoh dike àti olólùfẹ́ rẹ̀
- "Mo sá fún oògùn owó, igbó mímu, mo tún ní sùúrù fún ọdún 15 kí n tó di olókìkí"
- Hafsat Abiola-Costello, o tàbùku àwa táa dìbò fún bàbá rẹ̀ pẹ̀lú bóo ṣé ṣàfiwé Yahaya Bello àti MKO
- Ìjọba pàṣẹ fún àwọn iléeṣẹ́ ìbánisọ̀rọ̀ láti fi òfin de ìpè lórí fóònù àwọn tí kò so NIN mọ́ nọ́mbà wọn
- A máa ń lọ yọjú wo Yinka Quadri tó bá ń ṣe fíìmù ládùúgbò wa - Ẹ wo bí Dejo Tunfulu ṣe bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ Tíátà
- Ó bọ́ mọ́ Wizkid, Femi Kuti, Burna Boy lọ́wọ́ ní Grammy Awards, wo àwọn tí wọ́n jọ figagbága
- 'Àwọn tó yẹ kó yan olùdíje ipò Soun ní ìdílé wa ti fi òjóró bọ̀ọ́, wọn kọ̀ láti fún Oyebode Oyetunde ní fọ́ọ̀mù'
- Ẹ̀tànjẹ lásán ni, tí ẹnì kan bá sọ pé òun le dá yanjú ìṣòro ètò ààbò ní Naijiria báyìí - Obasanjo
- Bàbá wọ̀ gàù lórí ẹ̀sùn pé ó fún ọmọbínrín rẹ̀ lóyún, ó tún ṣẹ́yún fún un!
- Mi ò tíì lè sọ bóyá ètò ìdìbò ọdún 2023 yóò wáyé - Adeboye
Lẹta ọhun ka pe "Sheik, iwọ funra rẹ mọ ohun ti ẹsin Islam sọ nipa ibọwọfun ati eto."
"Amọ iha ti o kọ si bi a ṣe ba ọ wi lori awọn ọrọ ti o sọ fihan pe o ko kabamọ ohun ti o ṣe."
Ki ni ẹṣẹ Sheik Nuru Khalid?
Ọjọ Ẹti, to jẹ ọjọ kinni, oṣu Kẹrin, ọdun 2022 yii ni Imaamu naa sọrọ nipa ikọlu ọkọ oju rin to waye ni ipinlẹ Kaduna.
Ninu waasi naa lo ti sọrọ tako ijọba apapọ lori ikuna rẹ lati bojuto eto abo to mẹhẹ ni Naijiria.
Ti ẹ ko ba gbagbe, ọjọ kejidinlọgbọn, oṣu Kẹta ni awọn agbesumọmi kọlu ọkọ oju irin naa to n lọ lati ilu Abuja si Kaduna, nibi ti wọn ti pa eeyan mẹjọ, ti wọn si tun ti ji awọn mọkanlelogun mii gbe.
Amọ lọjọ Aje, Imaamu naa sọ fun ileeṣẹ iroyin BBC pe oun ko kabamọ ọrọ ti oun sọ.
O ni o dun oun lọpọlọpọ pe alaga igbimọ to gba iṣẹ lọwọ oun yii jẹ ọmọ bibi ipinlẹ Zamfara, nibi ti ko si abo kankan nibẹ.
Sheik Muru Khalid fi kun pe Ọlọrun nikan lo maa n gbe eeyan de ipo giga ati pe oun ko ni dẹkun lati maa sọ ootọ.
Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?
Ìmáàmù Abuja tó takò ààrẹ Buhari nínú ìwàásù rẹ̀ gba ìdádúro, àlàyé rèé

Oríṣun àwòrán, Screen shot
Awuyewuye ti n waye lori ayelujara lẹyin ti awọn alaṣẹ mọṣalaasi kan ni Apo, nilu Abuja da imaamu mọṣalaṣi naa duro.
Ọjọ Ẹti ni iroyin sọ pe Sheikh Nuru Khalid sọ ninu waasi rẹ pe ko dara bi aarẹ Buhari ṣe kọ lati lọ si ipinlẹ Kaduna lẹyin ikọlu awọn agbesunmọmi si ọkọ reluwe.
Kaakiri loju opo ayelujara ni ọrọ yi ti n mu iriwisi ọtọọtọ wa ti awọn ọmọ Naijiria si ni o ku diẹ kaato pẹlu bi wọn ṣe da imaamu yi duro.
Ikọlu to mẹnu ba ninu iwaasu rẹ jẹ eleyi to n kọ awọn araalu lominu nitori iye ẹmi to ba lọ.
Nilu Kaduna ni awọn agbesunmọmi ajinigbe ti da ọkọ reluwee lọna ti wn si sọ ado oloro si oju irin.
Ninu ikọlu yi, o kere tan eeyan mẹjọ ni ijọba sọ pe o padanu ẹmi wọn ti awọn ọpọ si farapa.
- N kò rí oorun sùn lórí iṣẹ́ ibi àwọn agbésùnmọ̀mí, òògùn oorun gan kò ràn mí - El-Rufai
- Ẹ wo orúkọ àti ojú àwọn èèkànlú tó forí sọta ìkọlù rélùwéè àti ipò tí wọn dì mú
- Gbẹgẹdẹ gbiná! Kí ló mú kí ọkọ dáná sún ìyàwó àti àbúrò rẹ̀ mọ inú ilé?
- Lẹ́yìn oṣù díẹ̀ tí wọ́n sìnkú rẹ̀, obìnrin yìí di dédé yọ sí ìlú rẹ̀, l'ọ̀rọ̀ bá di...
Titi di ba ṣe n sọrọ yi awọn eeyan kan wa ti wọn ko mọ ibi tawọn ajinigbe gbe wọn salọ.
Gomina Kaduna ti n tori ọrọ yike gbajare to si ni awọn ologun Naijiria ko ṣe iṣẹ wọn bi iṣẹ ni lati koju awọn janduku ajinigbepawo yi.
Ki lawọn eeyan sọ nipa idaduro imaamu Nuru Khalid?
Loju opo Twitter niṣe ni awọn eeyan n da si ọrọ aṣẹ lọ rọọkun nile ti igbimọ mọṣalasi Apo gbe kalẹ fun Imam Khalid.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
@farooqkperogi to jẹ alatako ijọba aarẹ tun alaye ọrọ Imaamu naa sọ nibi to ti ni ko bojumu bi aarẹ ko ṣe kan si ilu Kaduna nitori nigba to nilo ibo wọn, o lọ sibẹ.
Gimba Kakanda ti oun naa jẹ onwoye lori ọrọ to kan orileede Naijiria da si ọrọ yi to si ni awọn eeyan a mu bu awọn olori ẹlẹsin pe wọn gbe lẹyin ijọba ṣugbọn eeyan kan re ti o sọrọ tako ijọba
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Sẹnẹtọ Sheu Sani to fi igba kan ṣoju ipinlẹ Kaduna nile aṣofin agba kesi awọn igbimọ mọṣalasi Apo lati yi aṣẹ yi pada.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 3
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 4
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 5
Kini ẹsun ti Igbimọ Mọsalaṣi fi kan Imam Khalid?
Ninu iwasuu ọjọ Jimọ rẹ to ṣe niṣe ni Imaamu Nuru Khalid bẹnu atẹ lu ijọba Naijiria lori ailekoju ipenija aabo ati ipaniyan to n koju Naijiria.
Ninu iwaasu rẹ, o gba araalu nimọran lori awọn igbesẹ ti wọn le gbe lati fẹhonu han si aiṣedeede ijọba nipa ipeese aabo fun araalu.
O gbawọn nimọran pe ti ijọba ko ba dẹwọ ipaniyan to n waye, ki araalu ma ṣe jade dibo.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 6
Ninu ifọrọwanilẹnuwo BBC pẹlu alaga igbimọ Mọṣalasi naa, ṣẹnẹtọ Saidu Muhammad Dansadau sọ pe awọn da imaamu naa duro nitori ọrọ iwaasu to le da wahala silẹ.
Atẹjade ti wọn fi sita ni iwaasu Imam Khalid tako ẹsin Islaamu ti wọn si ni awọn ti yan imaamu mi ti yoo rọpo Imam Khalid

















