Ogun Cult Clash: Ìjọba fajúro sí ìkọlù àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn

Oríṣun àwòrán, Daily post
Ìfigagbága tó ń wáyé láàárín àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn níbi tí wọ́n ti ń pa ara wọn bí adìyẹ ní ìpínlẹ̀ Ogun ti tàn dé ìlú Sagamu báyìí bí ènìyàn mẹ́jọ ti ṣe pàdánù ẹ̀mí wọn níbi ìkọlù tí wọ́n ń ṣe síra wọn ṣe peléke si lọ́jọ́ Ajé.
Láti nǹkan bí ọ̀sẹ̀ kan sẹ́yìn ní àwọn afurasí bí ọmọ egbẹ òkùnkùn Ayé àti Ẹyẹ ti bẹ̀rẹ̀ ìkọlù sí ara wọn ní ìlú Abeokuta tí wọ́n sì ti ṣekúpa ènìyàn méje.
Ìròyìn ní ìkọlù náà bẹ̀rẹ̀ sí ní gbópọn nígbà tí wọn ṣekúpa ọmọ ìta kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tommy ní agbègbè Oluwo, Abeokuta, tí àwọn ènìyàn sì ti ń gbé nínú ìbẹ̀rù bojo láti ìgbà náà.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Agbébọn kọlu rélùwéè Kaduna sí Abuja, pa ọ̀pọ̀ èèyàn, jí àwọn míì gbé lọ
- À ń wá láti Ibadan, wá jí ọ̀pọ̀ ọmọ gbé l‘Eko fún ètùtù ọla - Afurasi ajọmọgbe
- Adájọ́ pàṣẹ kí wọ́n ó gbé Abba Kyari lọ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n Kuje ní Abuja
- Tíkẹ́ẹ̀tì 20,000, ọkọ̀ ọ̀fẹ́ wà fún yín láti fi wòran bọ́ọ̀lù Ghana àti Nàíjíríà lọ́fẹ̀ẹ́ - Ìjọba àpapọ̀
- Wo bí òògùn lílò àtàwọn nǹkan mìí ṣe le mú kí nkan oṣù obìnrin dáwọ́ dúró láìpé ọjọ́
- Bàbá ẹni ọdún 72 di èrò ẹ̀wọ̀n ní Ilorin nítorí ayédèrú ìwé ìrìnnà ọkọ̀
- Agbẹjọ́rò mi yóò tẹsẹ̀ òfin bọ ìṣẹ̀lẹ̀ Shoprite àmọ́ àwọn aláṣẹ ibùdó ìtajà náà sì ń bẹ̀ mí lọ́wọ́ - Toyin Asewo to re Mecca
- Ènìyàn mẹ́rin kú lásìkò tí wọ́n ń lé olè tó ja àwọn oní PoS lólè n'Ibadan
- Ẹ fura o! Ètò ààbò Nàìjíríà ti ń dàbí ti Afghanistan - Afenifere lọgun
- Malami ń forí ilé ẹjọ́ gba ara wọn lórí òfin ètò ìdìbò - Falana
- Ìjàmbá ọkọ̀ gbẹ̀mí ènìyàn mẹ́jọ l’Ékòó lópin ọ̀sẹ̀
Kòdá ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ará Panseke, Onikolobo, Oluwo, Adigbe ti sá kúrò nílé báyìí nígbà tí ìró ìbọn kò jẹ́ kí wọ́n gbádùn nílé.
Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn tún ṣèkọlù ní Sagamu
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ní àwọn tí nawọ́ gán ènìyàn méjìdínlógún tó lọ́wọ́ nínú ìṣẹ̀lẹ̀ náà, ó jọ wí pé ìkọlù náà ṣì ń peléke si nítorí àwọn afurasí náà ti ya wọ ìlú Sagamu báyìí, tí wọ́n sì tún ń ṣọṣẹ́.
Ní agbègbè Ajegunle, Soyindo, Ijagba, àti Sabo ni àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn náà ti ṣekúpa ènìyàn tí àwọn ará ìlú sì ti ń ké sí ìjọba láti wá wọ̀rọ̀kọ̀ fi ṣàdá lórí ọ̀rọ̀ náà.
Awoyemi Micheal, ará ìlú Sagamu tó bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ ní àláfíà ní àwọn ń fẹ́ kó jọba ní ìpínlẹ̀ Ogun àti wí pé ìkọlù gbogbo ìgbà tó máa ń wáyé láàárín àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn ní ìpínlẹ̀ náà ti sú àwọn.
Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ń ṣiṣẹ́ láti fòpin sí àwọn ìkọlù báyìí
Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá, Abimbola Oyeyemi ní gbogbo àwọn tó lọ́wọ́ nínú ẹgbẹ́ òkùnkùn ìpínlẹ̀ náà ni àwọn yóò fi ojú wọn wína òfin.
Oyeyemi ní àwọn ti ń ṣe gbogbo ohun tó wà ní ìkáwọ́ àwọn láti dá àláfíà padà sí ìpínlẹ̀ náà ní kíákíá.
Bákan náà ló ní gbogbo àwọn onílé tí wọ́n ń gba àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn sílè ni àwọn yóò fi póró òfin gbé, tó sì rọ àwọn òbí láti ba àwọn ọmọ wọn níwọ̀ọ́ kí wọ́n yé kó ọ̀rẹ́kọ́rẹ̀ẹ́.
Gómìnà ìpínlẹ̀ Ogun, Dapo Abiodun náà ní olójú kò ní lajú rẹ̀ sílẹ̀ kí tàlùbọ̀ kó síbẹ̀ láéláé, wí pé àwọn kò ní gba àwọn jàǹdùkú láàyè láti da omi àláfíà ìpínlẹ̀ náà rú.
Abiodun sọ àrídájú rẹ̀ pé ìpínlẹ̀ Ogun yóò dùn gbé fún tẹrú tọmọ.



















