Ibadan Robbery: Ènìyàn mẹ́rin kú lásìkò tí wọ́n ń lé olè tó ja àwọn oní PoS lólè n'Ibadan

Àwọn ọlọ́kadà àti ará àdúgbò Omi Ado mẹ́rin ní ìlú Ibadan, ìpínlẹ̀ Oyo, ti pàdánù ẹ̀mí wọn, nígbà tí wọ́n ń lé àwọn afurasí olè kan tó wá ṣọṣẹ́ ní agbègbè náà.
Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn ṣe sọ, àwọn ìgárá ọlọ́ṣà náà yabo agbègbè Ladeowo ní Omi Ado lálẹ́ ọjọ́ Ẹtì ní nǹkan bí ago méje ìrọ̀lẹ́, tí wọ́n sì ń gba owó lọ́wọ́ àwọn tó ń ṣe POS.
Bí i ṣọ́ọ̀bù márùn-ún ni wọ́n ti ṣọsẹ́ kí àwọn ará ìlú tó fi igbe ta léyìí tó mú kí àwọn olè náà fi ẹsẹ́ fẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Toyin Asewo to re Mecca fa wàhálà nílé ìtajà ShopRite n‘Ibadan lórí ẹ̀sùn ìbanilórúkọ jẹ́
- Ìjàmbá ọkọ̀ gbẹ̀mí ènìyàn mẹ́jọ l’Ékòó lópin ọ̀sẹ̀
- Wike tí kéde èròngbà rẹ láti gbé àpótí ìdìbò ààrẹ Nàìjíríà
- O fi owó wa jókòó sí Dubai, o sì ní ká máa gbàdúrà fún Nàìjíríà-Aráàlú fèsì sí Aisha Buhari
- Àlàyé rèé lórí bí ayédèrú ìwé ẹ̀rí NYSC ṣe dé ọwọ́ mi - Kemi Adeosun
- Mo ohun mẹ́wàá pàtàkì nípa Abdullahi Adamu, alága tuntun fẹ́gbẹ́ òṣèlú APC
- Ọjọ́ wo gan ní àyájọ́ obìnrin lágbàyéé Mothers Day, kí ló dé tí wọn fí n ṣé ajọyọ rẹ̀ lọ̀pọ̀ ìgbà?
- Ọ̀rẹ́kùnrin sanwó ẹ̀mí ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ fún agbanipa torí pé ó lóyún fún-un
- Agbébọn ṣé ikọlù sí pápákọ̀ òfurufú Kaduna, èèyàn kàn kú níbẹ
- Ajá pa ọmọ olówó rẹ̀ láàrin ọ̀sẹ̀ kan tí wọn rà á
- Lẹ́yìn ò rẹyìn, Amẹ́ríkà bẹ̀rẹ̀ ìpèsè ìrànwọ́ fún Ukraine lórí ìkọlù Russia
Óṣojúmi kòró tó bá àwọn àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ ní kété tí àwọn olè náà fẹsẹ̀ fẹ ni àwọn ọlọ́kadà àdúgbò náà àti àwọn ará ìlú náà bá gbé ọ̀kadà láti fi lé àwọn olè yìí.
Ṣùgbọ́n ní kété tí àwọn olè náà mọ̀ wí pé àwọn ènìyàn náà ń lé àwọn ni wọ̀n dàbọn bolẹ̀ tí ìbọn sì ba ènìyàn mẹ́rin nínú àwọn ènìyàn náà.
Bákan náà ló ní gbogbo ìgbìyànjú àwọn láti pe àwọn ọlọ́pàá lálẹ́ ọjọ́ náà ló já sí pàbó bí wọn kò ṣe gbé fóònù títí tí àwọn olè náà fi sá lọ.
Ìwádìí ń lọ lọ́wọ́ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà - iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Oyo, Adewale Osifeso ní àwọn ti gbọ́ sí ọ̀rọ̀ náà tí àwọn sì ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí le lórí.
Osifeso ní kété tí àwọn bá ti ni ohun tuntun lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà ni àwọn yóò fi léde.



















