Ibrahim Chatta: Ó gba àwọn òṣèré tíátà nímọ̀ràn láti máa ṣaájò ẹgbẹ́ wọn

Oríṣun àwòrán, ibrahimchatta_lordthespis
Ilumọọka osere tiata, Ibrahim Chatta ti dupẹ lọwọ gbogbo awn eeyan to se aajo rẹ lori aworan to gbe soju opo Instagram rẹ lọjọ Abamẹta.
Ninu aworan naa ni Chatta ti wa lori ibusun, ti wọn n fa omi ati oogun si lara.
Ọpọ eeyan lo ro pe o n se aisan lo se wa nile iwosan lai mọ pe ere sinima lasan ni.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Njẹ́ o mọ̀ pé bíi ọdún 700 sẹ́yìn ni wọ́n ti ń bọ Osun-Osogbo? Mọ̀ síi nípa ìtàn ojúbọ̀ nàá
- Aya gómìnà Kwara gba ilé fún Risikat olójú búlúù àti ọkọ rẹ̀
- Aṣòfin méje yarí mọ́ Akeredolu lọ́wọ́ torí ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ tí kò pín fún wọn
- Risikat, ìyá àwọn ọmọ olójú búlù tí bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́sẹ́ aṣojú lóge
- Àwọn ọ̀daràn tó jí ìbejì ọmọ Akeugbagold kó ti fojú ba ilé ẹjọ́ lòníì
- Àjọ ECOWAS yan Aàrẹ Ghana, Nana Akufo-Addo gẹgẹ bíi aàrẹ tuntun
- Àrà mánigbàgbé tí Baba Legba dá lágbo tíátà rèé
- Ẹgbẹ́ akọ̀ròyìn NUJ ìpínlẹ Oyo bà àwọn ọmọ ẹgbẹ́ tó lọ ìpàdé tí Femi Fani Kayode pè ní Ibadan wí
- Fìdíhẹẹ́ ní Banji Akintoye nínú YWC, lílọ ni yóò lọ - Tola Adeniyi
Amọ nigba to n fesi lori aworan naa, ati bi ọpọ eeyan se fi ifẹ han si, Chatta ni aworan naa lo fara jọ owe to ni " Ẹ́ jẹ́ ka diju, ka se bi ẹni to ku, ka wo ẹni ti yoo sunkun ẹni."
O wa dupẹ pupọ lọwọ awọn ololufẹ rẹ ti wọn pe, tabi gbadura fun nigba ti wọn ri aworan hun, o ni awọn naa ko ni se aisan.

Oríṣun àwòrán, bimbooshin
Bakan naa lo fi ohun ransẹ si awọn akẹẹgbẹ rẹ ti wọn dijọ n sisẹ tiata pe ki wọn maa sugba akẹẹgbẹ wọn to ba gbe iru aworan bayii sita, ki wn si wadii boya ere ni ọrọ naa abi otitọ.
Agba osere tiata naa ni "Ti onitiata yoo fi ku, ere lasan ni wọn yoo ro pe o n se."
Ki lo gbe Ibrahim Chatta dele iwosan?
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe isẹlẹ aramanda to n waye lori ayelujara lọwọ lọwọ bayii ni ti aworan kan ti gbajugbaja osere tiata, Ibrahim Chatta fi soju opo Twitter rẹ.
Idi si ree ti ọpọ ọmọ Naijiria fi ń beere pe ki lo ṣe agba oṣere Ibrahim Chatta, to fi dùbúlẹ̀ lóri ìbùsùn nilé ìwòsàn.

Oríṣun àwòrán, Ibrahim Chatta/Instagram
Nínú àwòràn tó gbé sójú opo instagram rẹ lọjọ Abamẹta, a ri ti ó sùn si orí ibùsùn, tí wọ́n si fa gbogbo oníruuru ọkun àti omi síi lára, gẹgẹ bi wọn se maa n se fawọn alaisan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àwọn òṣèré Nollywood tí wọn ò sí lóri amóhùmáwòrán mọ́
- Àwọn fíìmù Nollywood ń mú kí òògùn owó àti ìjínigbé gbilẹ̀ síi - Fashola
- Díẹ̀ lára àwọn òṣèré Nollywood ti wọ́n ti ṣe ìgbéyàwó lẹ́ẹ̀kejì
- Kíni ẹ mọ̀ nípa àwọn gbajúgbaja Yollywood?
- Ǹjẹ́ o mọ àwọn òṣèré bí Oyin Adejọbi, Funmi Martins àtàwọn míì tó ti dágbére fáyé?
- Ọ̀nà kan ò wọjà fáwọn òṣèré tíátà, bí wọn ṣe ń ta ìpara ìbóra ni wọ́n ń ta aṣọ ẹbí
Ibrahim Chatta, to maa n se ere adẹrinposonu nigba miran, lo kọ akọle kan sabẹ aworan naa, to ni "Stay Safe".
Eyi si lo tumọ si pe ẹ maa gbe ni ailewu.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 1
Irísí agba osere tiata naa jọ ti ẹni to ṣe àìsàn sùgbọ́n ọrọ ti awọn akẹẹgbẹ kan kọ sabẹ aworan ọhun mu ifura dani.
Idi ni pe, bi àwọn kan ṣe n ki pe Ọlọ́run yoo fun ara rẹ lokun, ni awọn míràn ń fi àwòràn náà dápárá, eyi to mu ifura lọwọ pe abi inu ere itage lo ti ya aworan naa.
- Wo àànfàní ‘Masturbation’, fífún ara rẹ̀ ní adùn ìbálòpọ̀
- Wo àwọn ìlànà tuntun ti o gbọdọ tẹlèé rèé ki ó to le wọkọ̀ òfurufú lọ sókè òkun
- Ìdí ti mo fi da sọ́ọ̀sì rú lásìkò ìgbéyàwó ìyáwó mi tó ló fẹ́ ọkọ míran- Osadebe
- Risikat olójú búlù dí aya Wasiu ní ìlànà Islam, tẹbí tará péjú síbẹ̀
- Ìdí ti mo fi da sọ́ọ̀sì rú lásìkò ìgbéyàwó ìyáwó mi tó ló fẹ́ ọkọ míran- Osadebe
Ibrahim ni inu oun dun pe awọn ololufẹ oun pe oun lati mọ ohun to n sẹlẹ, to fi mọ aafin Oyo, to si n bu awọn akẹẹgbẹ rẹ ti ko wa ẹyin rẹ wo lati mọ boya ootọ lo wa lori akete aisan abi bẹẹ kọ.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 2
Chatta ni "Ẹ́ jẹ́ ka maa wẹyin ara wa wo lati mọ ohun to n sẹlẹ nitori ti onitiata yoo ba fi ku, ere lasan ni wọn yoo ro pe o n se."
O wa gbadura pe, gbogbo ẹni to fi adura ransẹ si oun, titi to fi de aafin Oyo lọdọ Alaafin, aye gbogbo wọn ko ni bajẹ.
Gbajumọ osere naa ni lẹyin ti oun fi aworan naa sori ayelujara ni ẹrọ ibaraẹnisọrọ oun ku, tawọn eeyan ko si le kan si oun, eyi to mu ki ibẹru gba ọkan wọn.
O wa sisọ loju rẹ pe, inu ere tiata ni oun ti ya fọto naa nile iwosan, ko ko ko si ni ara oun le.
Yollywood: Toyin Abraham ṣe àjọ̀dún ogójì ọdún, èyí láwọn mánigbàgbé ìrìnàjò ayé rẹ

Oríṣun àwòrán, Instagram/toyin abraham
Gbajugbaja oṣere sinima Yoruba, Toyin Abraham ti ṣe ọjọ ibi ogoji ọdun laye.
Ninu ọrọ kan to fi sita loju opo twitter rẹ @toyin_abraham1 kede pe ogoji ọdun ohun pe oun o si yọnu.
Toyin Abraham wa lara awọn eekan elere sinima taraye n wari fun julọ lori ayelujara.
Ilu Auchi ni wọn ti bi Toyin Abraham ni ogoji ọdun sẹyin ṣugbọn ilu Ibadan lo ti lo ibẹrẹ aye rẹ.
- Òṣèré tíátà Toyin Abraham daya Kolawole Ajeyemi
- Toyin Abraham rèé, ọmọ ìpínlẹ̀ Edo tó di àràbà nínú tíátà Yorùbá
- Obaseki, Ize-Iyamu àti Osagiobare ṣàlàyé ohun tí kóówá ní lọ́kàn fún ìpínlẹ̀ Edo lórí ètò BBC
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ní Kano tí ṣe àyẹ̀wò àwọn 13, 048 tó fẹ́ darapọ̀ mọ́ wọn
- Facebook mú àyípadà bá àtẹ̀jíṣẹ́ síra ẹni lórí òpó Instagram, wo àwọn ǹkan tó kàn ọ níbẹ̀
O lọ si ileewe gbogboniṣe poly ipinlẹ Ọṣun to wa nilu Iree ki o to kọri si ileewe gbogboniṣe Polytechnic Ibadan
Eyi ni ohun marun un to duro laaye ọtọ laarin ogoji ọdun ti Toyin Abraham ti pe laye

Oríṣun àwòrán, Instagram/toyin abraham
Ọdun 2003 lo bẹrẹ iṣẹ sinima
Ọdun 2003 lo bẹrẹ iṣẹ sinima lasiko ti Bukky Wright lọ ya iṣẹ sinima kan nilu Ibadan.
Lati igba naa wa lo ti di alekun-alekun fun un lagbo awọn oṣere sinima titi kan eyi to gbe jade gbẹyin, Elevator Bab.
Oniruuru ami ẹyẹ lo si ti gba pẹlu titi kan ami ẹyẹ awọn elere sinima agbelewo ni Afirika iyẹn, AMVCA lọdun 2019.

Oríṣun àwòrán, others
'Mo lee ku tori Goodluck Jonathan.'
Nitori pe o jẹ gbajugbaja oṣere, ọpọ igba lawọn oloṣelu ti pe Toyin Abraham pe ko wa fi epo ati ata si ipejọpọ ipolongo idibo wọn.
Ninu ọkan lara ipe ipejọpọ bẹẹ ti wọn pee fun lasiko ipolongo ibo fun Goodluck Jonathan to fẹ dije fun ipo aarẹ lẹẹkeji lọdun 2015 ni Toyin ti sọ pe oun lee ku nitori ẹgbẹ oṣelu PDP.
Eleyii fa ọpọlọpọ awuyewuye ati ariwo nigba naa. Toyin pada wa tuuba fun awọn ololufẹ rẹto si rọ wọn pe ki wọn maa ṣe ta ẹjọ silẹ nitori oloṣelu kankan.

Oríṣun àwòrán, others
Igbeyawo rẹ akọkọ foriṣanpọn
Ni ọdun 2013 ni Toyin kọkọ ṣe igbeyawo. Oṣere ẹgbẹ rẹ, Adeniyi Johnson to pade lọdun 2012 lo fẹ.
Igbeyawo naa la ọpọlọpọ iji kọja to jẹ pe bi wọn ṣe n ja ni wọn n pari rẹ ki o to di pe wọn kuku ja ajatuka lẹyin lẹyin ọdun diẹ, iyẹn lọdun 2017.

Oríṣun àwòrán, Instagram/toyin abraham
Toyin yi orukọ pada
Ni igba to wọ agbo ere sinima, Toyin Aimakhu ni gbogbo eeyan mọ ọmọge Alakada si.
Amọṣa nigba to di ọdun 2016 ni iroyin jade pe Toyin fẹ yi orukọ rẹ pada.
Toyin funra rẹ lo wa kede pe oun ti pa orukọ da kuro ni Toyin Aimakhu bayii ohun ti di Toyin Abraham.
Nigba ti wọn bii pe ki lo fa idi eyi, ohun ti Toyin Abraham sọ ni pe 'ipinnu gbogbo ẹbi oun ni eyi, nitorina Toyin Abraham loun fẹ ki wọn maa pe oun" lati igba naa lọ.

Oríṣun àwòrán, Instagram/toyin abraham
Toyin ṣe igbeyawo lẹẹkeji.
Lẹyin to kọ ọkọ akọkọ silẹ, Toyin simi fun igba diẹ ki o to tun mu orin ifẹ bọnu.
Lọtẹ yii ẹwẹ, oṣere ẹgbẹ rẹ naa lo tun fẹ.
Ọgbẹni Kọlawọle Ajeyẹmi ni o fẹ ni Oṣu kẹjọ ọdun 2019 lẹyin ti Toyin funrarẹ sọ ọ ninu ifọrọwerọ kan pe ọdun 2017 lawọn pade
Awọn mejeeji si ti n tamige ifẹ lati igba yii wa ti eleduwa si ti fi ọmọ ọkunrin, Ire, ta wọn lọrẹ.

Oríṣun àwòrán, @allwell
Ṣaaju lọsẹ yii ni Ademola Allwell naa ti sọrọ lori ọjọ ibi rẹ pe:
Ìdí tí mo fi ń ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ìbí 35 lọ́dọọdún rèé- Allwell Ademola
Gbajugbaja oṣere to tun n kọrin ni Allwell Ademola ni ọpọ eeyan n sọrọ lori ayelujara latari ayẹyẹ ọjọ ibi ọdun marundinlogoji lọdọọdun.
Lati bii ọdun mẹrin sẹyin lo ti n ṣe ayẹyẹ ọdun yii laipaarọ iye ọjọ ori rẹ.
Ninu ifọrọwanilẹnuwo pẹlu ileeṣẹ iroyin kan ni ilu Eko ni Allwell ti ṣalaye pe ko si ohun to buru ninu pe oun n ṣe ayẹyẹ ọjọ ibi ọdun marundinlogoji lọdọọdun.
- Wo ojú Akeem t'Ọlọ́pàá mú pé ó fipá bá ọ̀dọ́mọbìnrin kan sùn létí odò l'Oṣun
- Iléẹjọ́ tó ga jùlọ fòǹtẹ̀ lu Yahaya Bello gẹ́gẹ́ bí Gómìnà ìpínlẹ̀ Kogi
- Ìjọba Ghana ṣí iléeṣẹ́ àwọn ọmọ Nàìjíríà padà. ó fún Nàìjíríà l'èsì àwọn ẹ̀sùn tó fi kàn-án
- Wo nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Tolanibaj, Wathoni àti Brighto ni wọ́n lé kúrò ni BBNaija l'ọ́sẹ̀ yìí
Allwell ni oun kan n se oun to n mu oun dabi ọdọ sii lọdọọdun ni ati pe iyẹn ko sọ pe ẹni ọdun marundinlogoji ṣi ni oun rara.
O fi imoore han si Olorun pe oun ṣi wa laye lasiko ajakalẹ arun Covid 19 yii.
O ni eyi ko sọ pe ọdun ohun ko yi pada ati pe o yẹ ki awọn eeyan mọ pe awada lati mu inu ara oun dun lo n jẹ ki oun ṣe ayẹyẹ ọjọ ibi ọdun naa nigba gbogbo.
Oṣere Allwell Ademola ni oun gbadura pe ọkan awọn oṣere ẹgbẹ oun a tubọ balẹ.
Ati pe ki Olorun mu inu oun dun sii ṣaaju ayẹyẹ ọjọ ibi oun lọdun to m bọ.

Oríṣun àwòrán, @All well
Bí ó ṣe lọ lágbo àwọn òṣèré Yollywood lọ́sẹ̀ yìí rèé

Oríṣun àwòrán, Others
Nollywood Round Up: Bí ó ṣe lọ lágbo àwọn òṣèré Yollywood lọ́sẹ̀ yìí rèé
Oníruuru àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ lo ti wáye láàrín ọ̀ṣẹ̀ yiìí lágbo òṣèré Nollywood.

Oríṣun àwòrán, oTHERS
Funke Akindele-Bello gbe nkan mẹta ṣe lẹẹkanṣoṣo
Ní ilé gbájúgbàja òṣèré Funke Akindele Bello ti gbogbo ènìyàn mọ sí "Jennifa" ohun mẹtalọkan lo jẹyọ níbẹ̀.
Bí ó ṣe n ṣe ayẹyẹ ọjọ́ ibi ló n ṣe ajọdun igbéyawo bákan náà lo tún fi yé àwọn ọlólùfẹ́ rẹ pe wọn kú afojusọ́nà, sinima agbélewo rẹ̀ túntun to n bọ.
- Gbajúgbajà òṣèré Black Panther jáde láyé!
- Àwọn òṣèré Nollywood tí wọn ò sí lóri amóhùmáwòrán mọ́
- Ǹjẹ́ o mọ àwọn òṣèré bí Oyin Adejọbi, Funmi Martins àtàwọn míì tó ti dágbére fáyé?
- Ọkọ Funke Akindele kó eléré àti òṣìṣẹ́ jọ fi ṣe "Surprise Pato" fún un lọ́jọ́ ìbí rẹ̀
- Lizzy Anjọnrin fẹ̀si fáwọn agbọ́yì-sọ̀yí lórí ìgbéyàwó rẹ̀, Madam Sajẹ dasójú ilé iṣẹ́, àti àwọn ǹkan míràn tó ṣẹlẹ̀ lágbo tíátà lọ́sẹ̀ yìí

Oríṣun àwòrán, OTHERS
Iròyìn tó tó wa léti ni pé, gbájúgbajà òṣèré náà ń pinu láti tún gbé atunṣe eré míràn jáde lára ọ̀kan lárá èyí to ṣe tẹ́lẹ to fi di ìlúmọ̀ọ́ká.

Oríṣun àwòrán, MO_Adebimpe/instagram
Lateef Adedimeji àti Adebimoe Oyebade
Lọ́sẹ̀ yìí bákan náà àwọn tọ́kọtiyawó orí ayéluujara tí wọ́n dá awuyewuye silẹ́ lọ́jọsi lórí asọ igbéyawo ti wọ́n wọ̀ papọ tún ti gbe òmíràn yọ.
Gẹ́gẹ́ bi ìṣe wọ́n àwọn méjèèjì tún wọ ànkoo bii tọkọtiyàwò ti wọ́n sí fọ́n fóto wọ́n ka sórí ayelujara bi ina wẹ́dà.
Ọ̀pọ̀ ọmọ Naijiria lo tún ti wa n bere bayii pé, ṣe tọkọtaya ni awọn méjeeji lootọ ni?
Sùgbọ́n gẹ́gẹ́ bi ǹkan ti ọgbẹ̀ni Adedimeji sọ, ó ni gbígba àdúra ni ńkan ti àwọn ènìyàn ń rí tori ìpólówó ọja ni àwọn ń se.
- Awọn afurasí Babaláwo pa ìyáwó Ìmáàmù àgbà ìlú Ayere ní Kogi, Alayere dá sọ́rọ̀
- Ọ̀fíìsì ni mo wà tí mo rí Hẹlikọ́ptà tó ń yí bírí bírí lójú òfurufú, àfi tí a gbọ́ gbàà! - Olùgbé Opebi l'Eko
- Akeredolu ń fẹ́ kí wọ́n dìbò fún òun ló jẹ́ kó ṣàdínkù owó ilé ìwé AAUA - Akẹ́kọ́ọ̀ AAUA
- Wo àṣẹ tuntun tí Buhari gbé síta nípa owó iná ọba

Oríṣun àwòrán, others
Lágbo òṣèré bákan náà nínú ọ̀sẹ yiìí ni àwọn àwọn àgbáríjọ àwọn oṣerẹ agbálewò ti kìí ṣe ti Yoruba níkan ti ko àrawọn jọ.
Wọ́n sì ni ki gbogbo ènìyàn maa fójú sónà láti mọ idí abaájọ ńkan ti àwọn fẹ́ ṣe.
Gẹ́gẹ́ bi Yomi Fabiyi to jẹ ọ̀kan gbòógi lara awọn òṣere Nollywood Yoruba ṣe sọ, ó ni láìpẹ́ yii àwọn yoo ṣe àtẹjáde àti èrèdí ti àwọn fi darapọ̀ síta ninu fọto.
Àwọn to péjọ náà ni:
OGE OKOYE
MUTIU ADEPOJU
YEMI sOLADE
ARALOLA OLAMUYIWA
Awọn miran ni:
SAHEED MUHAMMED (FUNKY MALLAM)
YOMI FABIYI
KEMI AFOLABI ADESIPE
STEPHEN UGOCHUKWU (RUGGEDMAN)
MURPHY AFOLABI
FOLUKE DARAMOLA



















