Baba Legba: Foluke Daramola ní òun kò ní gbàgbé àdúrà òwúrọ̀ tó máa ń gbà fún òun

baba Legba ati Owolabi Ajasa

Gomina ẹgbẹ TAMPAN ni ipinlẹ Ogun, Owolabi Ajasa ti ṣapejuwe Baba Lẹgba to di oloogbe, gẹgẹ bi baba awọn oṣere nigba aye rẹ to ko awọn eniyan mora.

Ajasa ni, baba ni Baba Lẹgba jẹ fun wọn nigba to wa laye, to si tun jẹ awokọṣe iwa ọmọluwabi laarin wọn, to si ma n gba wọn nimọran.

O ni bi o tilẹ jẹ pe oloogbe naa kii ṣe ọmọ ẹgbẹ oṣere TAMPAN nigba aye rẹ, to jẹ wi pe ọmọ ẹgbẹ ANTP ni, sibẹ o sunmọ gbogbo awọn oṣere.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

"Gbogbo ohun ti a ba fẹ, lo maa n ṣe fun wa nigba to wa laye, a si ṣe ojuṣe wa fun nigba to dubulẹ aisan, ki o to di wi pe o doloogbe.

Eto isinku Baba Legba

Oríṣun àwòrán, Others

Aisan to rọmọ ọjọ ogbo lo ṣe Baba legba to fi papoda, amọ, ede aiyede to ṣẹlẹ laarin ẹgbẹ TAMPAN ati ANTP, lo mu ka maṣe pe oloogbe naa si iṣẹ pẹlu aisan to ṣe wọn."

Owolabi Ajasa fikun pe aisan Baba legba tun peleke si ni ọdun to kọja, sugbọn oun maa n pe oloogbe naa si iṣẹ.

Ninu ọrọ tirẹ, gbajugbaja oṣere Yoruba, Foluke Daramọla Salako ṣe apejuwe Baba Lẹgba gẹgẹ bi ẹni to ni imọ ati oye nipa oṣere, to si kun fun ọgbọn.

Awọn osere to peju sibi eto isink Baba Legba

Oríṣun àwòrán, Others

Foluke Daramọla ni ohun manigbagbe ti oloogbe naa ṣe fun oun ni adura to maa n gba fun oun ni araarọ, to ba ti pe oun lori aago.

"Itoju ti ẹgbẹ TAMPAN n ṣe fun awọn agbalagba to wa ninu ẹgbẹ oṣere lo mu mi mọ Baba Lẹgba.

Amọ, ọdun to kọja ni aisan asetọ taa mọ si prostate mu, eyi to ṣekupa nitori ọjọ ogbo rẹ."

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC: Mọ̀ si nípa oríṣìí ẹ̀ka ìsọ̀rí ọ̀rọ̀ àti ìwúlò wọn

Bakan naa lo pe oun yoo ṣe idaro Baba Legba nitori ipa ribiribi to n ko ninu fiimu nigba aye rẹ.

Mo kábàámọ̀ pé ń kò bẹ Baba Legba wò, nígbà tó pè mí - Foluke Daramola

Ilumọọka osere tiata lobinrin, Foluke Daramola Salako ti n gbarata lori iku to mu agba ọjẹ osere tiata miran, Alhaji Yekeen Omobolanle lọ.

Ọjọ Aje ni iroyin iku agba ọjẹ ninu isẹ tiata naa gbalẹ kan, ẹni ti ọpọ eeyan mọ si Baba Legba.

Yekeen Omobolanle Baba Legba

Oríṣun àwòrán, Others

Nigba to n kẹdun iku to mu akikanju osere naalọ, Foluke sọ loju opo Instagram rẹ pe kii dun mọ oun ninu lati ri ki awọn agba osere maa jade laye.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Foluke to ni lootọ ni baba naa dagba, ti oun si ba sọrọ lọsẹ to kọja sugbọn ọwọ mi di pupọ nile ounjẹ ti oun da silẹ lati bẹ ẹ wo.

"Ọwọ mi di lati lọ bẹ ẹ wo gẹgẹ bi mo se maa n se nitori o sọ fun mi pe oju ọjọ taa wa yii tutu fun oun.

Yekeen Omobolanle Baba Legba

Oríṣun àwòrán, Others

O dun mi pe n ko le ni anfaani lati juwọ si pe o digbose ko to gbẹmi mi, o si se ni laanu pe a padanu rẹ."

Foluke fikun pe "mo da ara mi lẹbi pe n ko lọ bẹ Baba Legba wo nigba to pe mi, ams sa, o dara, Sun re o, Baba."

Wọn ti sin oloogbe naa nilana ẹsin Musulumi lọjọ Aje.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa lori BBC: Mọ̀ si nípa oríṣìí ẹ̀ka ìsọ̀rí ọ̀rọ̀ àti ìwúlò wọn

Àrà mánigbàgbé tí Baba Legba dá lágbo tíátà rèé

Ikudoro, iku ti sika, iku ti mu gbajumọ agba ọjẹ ninu isẹ tiata miran lọ.

Oluwa rẹ ni Alhaji Yekeen Omobolanle ti ọpọ eeyan mọ si Baba Lẹgba.

Baba Lẹgba lo maa n sere awada pẹlu baba Sala laye ọjọsi, ki agba to de.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Agba ọjẹ osere tiata naa lo jade laye nile rẹ to wa nilu Abeokuta nipinlẹ Ogun nirọlẹ ọjọ Aiku.

Nigba to n fidi isẹlẹ iku oloogbe naa mulẹ fun BBC Yoruba, gbajumọ osere tiata miran, Ebun Oloyede, ti ọpọ eeyan mọ si Olaiya Igwe ni lootọ ni baba naa ti lọ.

Irọlẹ oni ọjọ Aje si ni wọn yoo fi iyoku ara Baba Legba fun ilẹ nile rẹ nilu Abeokuta nilana ẹsin Musulumi.

Yekeen Omobolanle Baba Legba

Oríṣun àwòrán, Others

Ọdun 1974 ni Baba Legba dara pọ mọ ikọ osere tiata Awada kerikeri labẹ akoso Moses Olaiya, taa mọ si Baba Sala.

Nigba miran, Baba Legba tun maa n ba awọn akẹẹgbẹ rẹ ninu isẹ tiata sere itage, awọn bii Bolaji Amusan taa mọ si Mr Latin ati Segun Ogungbe.

Gẹgẹ bi ọmọ Baba Sala to kede iku oloogbe naa loju opo Facebook rẹ, Adejumọ Boisala Emmanuel ti wi, Baba Lẹgba maa n se babalawo ninu ere tabi ọlọpaa.

Àkọlé fídíò, Temitope Akinnusi: Ọ̀pọ̀ iléeṣẹ́ ló takú láti gbà mí síṣẹ́ torí mo ní ojú kan

Sugbọn o ni lọpọ igba, alawada ni oloogbe naa ati baba Sala saba maa n se ninu ere.

Adejumọ fikun pe Sunday Omobolanle ni baba naa n jẹ tẹlẹ, ko to lọ si Mecca, to si yi orukọ rẹ pada si Yekeen.

O wa gbadura pe ki Ọlọrun tẹ oloogbe naa safẹfẹ rere.