Yollywood: Ọ̀pọ̀ òṣèré Yorùbá ń ṣelédè lẹ́yìn Yusuf Satia tó d'olóògbé

Oríṣun àwòrán, others
Ta ni Yusuf Satia ti iku mu lọ?
Oṣere yii kii ṣe ọkan lara awọn oṣere ti wọn maa n saaba gbe nkan jade lori ayelujara nipa ara wọn tabi nipa iṣẹ wọn.
Igba to gbe nkan sori ikansira ẹni facebook gbẹyin ni lọjọ kẹrin, oṣu kẹta, ọdun 2013.
Lasiko yii lo sọ nipa ifojusọna ọjọ ibi rẹ lọdun 2013.
A bi Yusuf Ojewale Satia lọjọ kẹsan, an, oṣu kẹta lọdun naa lọhun.
Ipinlẹ Eko ni guusu Iwọ Oorun Naijiria ni Yusuf gbe dagba.
Nibẹ naa lo ti ka iwe alakọbẹrẹ ati iwe ipele girama.
Koda, o ri lọ si Fasiti ijọba apapọ to wa ni Akọka nilu Eko.
O tun gba iwe ẹri jade ni John Curtin College ni Australia.
O doloogbe ni ọjọ kọkanlelogun, oṣu keje, ọdun 2020.
- Wo bí ètò ìsìnkú Tolulope Arotile ṣe lọ nílùú Abuja
- Èmi Ọba tí wọ́n ń kó jẹ nígboro- Oluwo ti ilú Iwo
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kano tí wọ́gilé ayẹyẹ lẹ́yìn ìrun ọdún Iléyá!
- Ṣé Akpabio ṣetán láti dárúkọ àwọn Aṣòfin tó gba iṣẹ́ àkànṣe lọ́wọ́ NDDC?
- Donald Trump ti gbà pé Coronavirus yóò burú jáì kí ǹkan tó dára fún Amẹ́ríkà
Awọn oṣerẹ bii Toyin Adewale ati Bose alao ati awọn miran ni wọn n ṣe ilede lẹyin rẹ ti wọn si banujẹ nigba ti wọn gbọ iroyin iku Satia Yusuf

Oríṣun àwòrán, Kunle Afod/instagram
Ikú ti yọ́wọ́ òṣèré Nollywood Yorùbá, Yusuf Satia l'áwo
Oṣere Nollywood Yoruba, Yusuf Satia, ti ku.
Ibanujẹ lo jẹ fun agbo ile tiata Yoruba, Lẹyin ti iroyin iku rẹ jade sori ayelujara.
Akẹgbẹ rẹ, Kunle Afod, lo kede iku Satia loju opo Instagram rẹ ni ọjọ Iṣẹgun, ọjọ kọkanlelogun, oṣu Keje, ọdun 2020.

Oríṣun àwòrán, kunle afod/instagram
Afod sọ pe oun gbiyanju lati kàn si Satia ninu ọdun yii, ṣugbọn ko ṣeeṣe.
A ko ti i le sọ nkan to pa oloogbe naa.

Oríṣun àwòrán, Yusuf_satia/instagram
Satia di mimọ fun awọn ololufẹ rẹ fun ipa to ko ninu ere agbelewo Yoruba kan, Ijinlẹ Pam Pam to gbe jade logun ọdun sẹyin.
Awọn kan figba kan n ri Satia lẹyin KWAM 1 agba ọjẹ onifuju n ni lọpọ ọdun sẹyin.

Oríṣun àwòrán, Yusuf_satia/instagram
Awọn oṣere bi i Toyin Adewale, ati Bose Alao naa ti n ṣe idaro rẹ.
Oṣu to kọja ni gbajugbaja oṣere, Ogun Majek naa jade laye lẹyin aisan.
- Wo àwọn òṣìṣẹ́ kólẹ̀-kódọ̀tí tó ń fi ẹ̀mí wọn wéwu kí Abuja leè mọ́ tónítóní
- Mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ń bá àwọn tí a jọ díje nínú ìdìbó abẹ́lé sọ̀rọ̀ kí àláàfíà léè jọba - Akeredolu
- Èèyàn 576 míràn tún kún àwọn tó ní àrùn COVID-19 ní Nàìjíríà
- Wo àwọn nkan tó yẹ́ kí o mọ̀ nípa 'Awawa Boys', ọ̀kan lára ẹgbẹ́ òkùnkùn tó n dá Eko rú













