Yahaya Bello: Iléẹjọ́ tó ga jùlọ fòǹtẹ̀ lu Yahaya Bello, wọ́n da ẹjọ́ PDP àti SDP nù

Oríṣun àwòrán, Facebook
Iléẹjọ́ tó ga jùlọ fòǹtẹ̀ lu Yahaya Bello gẹ́gẹ́ bí Gómìnà ìpínlẹ̀ Kogi
Ileẹjọ to ga julọ ni Naijiria ti fi ontẹ lu eto idibo to gbe Yahaya Bello wọle gẹgẹ bi Gomina ipinlẹ Kogi.
Ninu idajọ rẹ lọjọ Aje niluu Abuja, ileẹjọ naa tu ẹjọ ti ẹgbẹ oṣelu PDP pe ẹgbẹ oṣelu APC tii ṣe ẹgbẹ Bello ka.
Lọsẹ to lọ ni igbimọ oludajọ ẹlẹni meje ile ẹjọ to ga julọ ni Naijiria labẹ idari adajọ agba ni Naijiria, Tanko Mohammed gbọ ẹjọ ti oludije ibo gomina fẹgbẹ oṣelu PDP, Musa Wada pe Gomina Yahaya Bello to wọle ibo naa.
- Mo ti dàgbà ọ̀jẹ̀, n kò ní díje fún ipò gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo mọ́ - Alao Akala
- Ọ̀fẹ́ ni China yóò kọ́ fásítì $50M ètò ìrìnnà sí Daura ìlú Ààrẹ Buhari- Amaechi
- Irọ́ ni, kò sí olóyún nínú àwọn tí Tírélà pa ní Ondo ṣùgbọ́n awakọ̀ ti sá lọ- Ọlọ́pàá Ondo
- Ọba ni mí, mi ò le b'ọ̀rìṣà, Olorì tuntun tó ń bọ̀ já gbogbo ''scale''- Oluwo ti Iwo
- Ta ni ìyàwó Chadwick Boseman, tó jẹ́ àwòkọ́ṣe rere f'áwọn ọ̀dọ́ Adúláwọ̀?
- Kí ló mú Obasanjo ti ilẹ̀kùn mọ́ ẹbí, òṣìṣẹ́, ojúlùmọ̀ ní ibi òkú àna rẹ̀?
Ninu idajọ ti Adajọ Inyang Okoro ka jade lorukọ igbimọ awọn adajọ mejeeje to ṣapero lori ipẹjọ naa, ileẹjọ fi ontẹ lu idajọ ileẹjọ kotẹmilọrun ati ti igbimọ igbẹjọ to n ri si awuyewuye ibo gomina to dajọ pe Bello lo jawe olubori ninu ibo gomina Kogi.
Lẹyin ti igbimọ oludajọ ṣe agbeyẹwo koko marun un ti ẹgbẹ oṣelu PDP fi gbe Gomina Bello APC lọ si ileẹjọ, ileẹjọ giga ni awọn ẹsun naa ko lẹsẹ nlẹ.
''Lẹyin ti a wo eṣun ti oludije PDP pe ẹgbẹ oṣelu APC pe kudiẹkudiẹ wa ninu eto idibo to gbe Yahaya Bello gẹgẹ bi gomina ipinlẹ Kogi, o ti han gbangba pe ko si ẹri to dalu lati fi idi ẹsun naa mulẹ, nitori naa, a tu ipẹjọ PDP ka,'' adajọ Okoro lo sọ bẹẹ.
Adajọ agba ni Naijiria, Mohammed, adajọ to ka idajọ ileẹjọ, Okoro ati Abba-Aji atawọn ọmọ igbimọ igbẹjọ mii lo fẹnu ko lori idajọ naa.
- Àwọn nkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa ṣíṣe ìṣirò àsìkò tí o bá n yé ẹyin
- Èèyàn méjì kú, méjìdínlógóje míì ṣẹ̀ṣẹ̀ kó COVID-19 lọ́jọ́ Àìkú
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko kéde ọjọ́ tí àwọn iléèwé gígá yóò wọlé
- Ọba ni mí, mi ò le b'ọ̀rìṣà, Olorì tuntun tó ń bọ̀ já gbogbo ''scale''- Oluwo ti Iwo
- Wọ́n tún ti pa omidan ẹni ọdún 18 míràn l'Akinyele ní ìlú Ibadan
Ileẹjọ to ga julọ tun da ẹjọ onikoko meje ti oludije ẹgbẹ oṣelu SPD, Natasha Akpoti naa pe wi pe igbakeji gomina Kogi, Edward Onoja parọ ọjọ ori rẹ ati pe o tun fi ayederu iwe ẹri ranṣẹ si ajọ INEC nu.
Igbimọ oludajọ naa sọ pe ko si ẹri to daju lati fi idi gbogbo ẹsun ti SDP fi kan igbakeji gomina Kogi mulẹ.

















