Helicopter crash in Lagos: Àbájáde ìwádìí ẹlikọ́pítà to já ni Opebi laipẹ yii ti jáde

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Ìgbìmọ̀ ìwádìí ìṣẹ̀lẹ̀ ìjàmba ti fi abájáde ìwádìí wọ́n síta lórí ẹlikọpítà to já ni Opebi nílùú Eko lọ́jọ́ kejìlélógójì, oṣù kẹjọ, ọdún 2020.
Iṣẹ̀lẹ̀ náà tó kan ẹlikọ́pítà Bell 206B lll pẹlu nọ́mba ìdánimọ 5N-BQW tí ilé iṣẹ́ ọkọ̀ òfurufú Quorum Aviation Limited ni wọ́n ti sàlàyè gbogbo ǹkan tó fa ìṣẹ̀ll ńlá ibi náà.
Ìwádìí fi han pé ẹlikọ́pítà náà ni ìwé to pé pérépéré ti o si yẹ láti má a rin lójú òfurufú ti o si múlẹ̀ títí di ọjọ́ kẹfa ọsù kẹjọ ọdún 2020.
- Wo àwọn báńkì tó wà lẹ́yìn àwọn olówó èlé bí MMM
- Ẹ̀yin òṣìṣẹ́ elétò ìlera, ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́- JOHESU
- Wo bí Sunday Shodipe ṣe pa Funmilayo tó pa kẹ́yìn l' Akinyele
- Ìjọba Kaduna kéde ọjọ́ mẹ́ta fún ìdárò Emir Zazzau, Buhari, Tinubu, Babangida náà ń ṣèdárò
- Sudan tí bẹ̀rẹ̀ ìjìròrò lórí bí US yóò ṣe yọ òrúkọ̀ wọn kúrò nínù ikọ̀ agbẹ́sùnmọ̀mí àgbáyé
Bákan náà ni kò si ẹ̀rí láti fi hàn pé ilé iṣẹ́ ẹlikọ́pítà náà kọ ìwé fún àjọ NCAA lati yọnda ọkọ ọ̀hun fún ìrìnàjò lẹ́yìn ti àsìkò to le rìn ti parí.
Kò tún sí ààyè epo tó tó fún ọkọ òfurufú ọ̀hun.
"Àbájáde ìwádìí náà lọ báyìí, pé " Wọ́n rọ epo kúnú ọkọ òfurufú náà lọ́jọ́ kẹtàdínlógún, oṣù kẹjọ, ọdún, 2020, wọ́n ẹnjínì rẹ̀ ṣiṣẹ́ fún ìṣẹ́jú mẹ́wàá fún àyẹ̀wò, bákan náà ni wọ́n tún wàá wò fún ogún ìṣẹ́jú ní ìlú Port Harcourt"
Wákàtí mẹ́tà àti ìṣẹ́ju mẹ́ẹ̀dógún ni ẹlikapítà náà le farada iṣẹ́ mọ, sùgbọ́n ó ìrìnàjò wákàti méjì àti iṣẹ́jú mọ́runlélógójì ni wọn rán.
Wọ́n taná si ẹ́njìnì rẹ̀ ní ààgo mẹ́sàn kọjá ìṣẹ́ju mẹ́ẹ̀dógún, ó sì gbéra ni aago mẹ́sàn kọjá ogún ìṣẹ́jú. Ó já ni aago méjìlá kọ́já ìṣẹ́jú mẹ́rìnlá.
" Ko si epo kankan ninu ọkọ náà ńgbà ti ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ṣe, bákan náà ni abẹ̀bẹ̀ orí rẹ̀ dúró déédé lásìkò àbẹ̀wò lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ ọ̀hún.
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí ọkùnrin tó gé akẹ́kọ̀ọ́ ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ wẹ́lẹ́ wẹ́lẹ́ fún òògùn owó ní Ikorodu
- Áṣẹyin kìlọ̀ fáwọn adarí olóṣèlú Nàìjíríà láti ṣe ohun tó yẹ nítorí ará ọ̀run ń wò wọ́n!
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá sọ afurasí ọlọ́pàá tó yìnbọn fún ọ̀dọ́kùnrin tó fún èèyàn lóyún s'átìmọ́lé
- Wo bí odò Nile tó gùn jù l'Áfíríkà, ṣe ń fójúu ilẹ̀ Egypt, Ethiopia àti Sudan han màbo
- Ọ̀wọ́ngógó búrẹ́dì gbòde kàn lẹ́yìn tí àwọn oníbúrẹ́dì da iṣẹ́ sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, Twitter/Gboyega Akosile
Helicopter crash in Lagos: Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko ti bẹ̀rẹ̀ àtúnkọ́ ilé tí bàlúù agbéra pá tó jábọ́ bàjẹ́ ní Eko
Ijọba ipinlẹ Eko ti bẹrẹ atunkọ agbegbe Opebi ti ọkọ baalu ẹlikọpita jabọ si ni ọsẹ to kọja.
Oluranlọwọ pataki fun gomina ipinlẹ Eko, Gboyega Akosile fi lede ni ori opo ikansiraẹni Twitter wọn.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
- Akomolede: Bolaji Faleke ni Olùkọ́ tó ń kọ́ wa ní àṣà oge ṣiṣe lórí BBC Yorùbá
- Ìwọ tó ń ṣí ara sílẹ̀ lọ ṣọ́ọ̀ṣì, ṣé apàyàn kọ́ ni ẹ́ báyìí?- Mike Bamiloye
- Ọkùnrin kan da ṣọ́ọ̀ṣì rú lásìkò ìgbéyàwó, Ó ní òun lọkọ àárọ̀ ìyàwó tuntun
- Mi ò fẹ́ ìrànwọ́ ẹgbẹ́ òṣèré, àwọn kọ́ ló kóbá mi- Chief Kanran
- Èèyàn mẹ́jọ jónà ráúráú nínú ìjàmbá ọkọ̀ akérò tó ṣẹlẹ̀ ní mọ́rosẹ̀ Eko sí Ibadan
Ninu atẹjade to fi lede naa sọ wi pe Gomina Sanwo Olu gbe igbesẹ naa lẹyin wakati mejidinlaadọta to jẹjẹ lati tun agbegbe Opebi ti baalu naa jabọ ṣe pada.
Aarin ile ni agbegbe Salvation road ni Opebi naa ni ọkọ ofurufu hẹlikọpita wo si, to si ṣe ọpọlọpọ ipalara fun awọn to wa ni agbegbe naa.

Oríṣun àwòrán, Twitter/Gboyega Akosile
Eniyan mẹtẹẹta to wa ninu ọkọ baluu naa lo ti ku bayii, amọ eniyan meji lo kọkọ ku lẹsẹkẹsẹ ti iṣẹlẹ naa waye.
Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo Olu jẹjẹ lati ri wi pe awọn ogiri to wo naa di titun kọ pada.

Oríṣun àwòrán, Twitter/Gboyega Akosile
Bakan naa lo ba awọn ẹbi ati ara ti ajalu naa ṣẹlẹ si kẹdun, pẹlu adura wi pe wọn ko ni rogun ibanujẹ mọ, ati wi pe Olorun yoo tu wọn ninu.
- Ọmọ Nàìjíríà, àfikún owó iná tuntun bẹ̀rẹ̀ lónìí: ọjọ́ kínní, oṣù kẹsàn án, ọdún 2020- NERC, Disco
- Ọwá Ale Ikarẹ, Oba Adegbite-Adedoyin papòdà lẹ́ni ọdún márùndínláàdọ́rùn ún!
- Wọ́n ti búra wọlé fún Akinwunmi Adesina gẹ́gẹ́ bí ààrẹ Banki ilẹ̀ Afrika, AfDB
- Ohun tí a mọ̀ nìyí nípa gbọ́nmi síi omi ò tó lórí ọ̀rọ̀ oyè Babaloja-General ní ìpínlẹ̀ Oyo
- YWC yọ Ààrẹ Banji Akintoye nípò àbi Akintoye tú ìgbìmọ̀ aláṣẹ YWC ká?

Helicopter crash in Lagos: Gbogbo arìnrìnàjò inú ẹlíkọ́pítà tó já ní Opebi ti tẹ́rí gbaṣọ!
Ìṣẹ́jú méjì péré tó máa fi bàlẹ̀ ni pápákọ̀ òfurufú ni ẹlikọ́pítà Quarom aviation já lulẹ̀ ní Opebi, Ikeja
Arinrinajo kẹta to wa ninu ẹlikọpita to ja lulẹ ni Opebi, Ikeja niluu Eko ko pada ye e, o ti rekọja s'alakeji.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post
Ajọ LASEMA ati agbẹnusọ ajọ to maa n wadii ọrọ to ni ṣe pẹlu ijamba lorilẹede Naijiria, Accident Investigation Bureau lo fidi ọrọ naa mulẹ.
Bakan naa, iroyin ti a ri ko jọ ni pe iṣẹju meji pere lo ku ki ẹlikọpita naa balẹ ni papakọ ofurufu Murtala Muhammed ti Eko lo di wọ̀ọ̀ nilẹ̀.
Nibayii, o tumọ si pe gbogbo awọn mẹtẹẹta to wa ninu ẹlikọpita naa lo ti ku.

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Ajọ to ma n wadii ijamba ni Naijiria lo ṣawari apoti dudu, to wa ninu ẹlikọpita, to ja lulẹ ni agbegbe Ikeja, nipinlẹ Eko.
Awọn oṣiṣẹ ajọ AIB sọ pe ni nkan bi aago mẹta ọsan ni wọn ri apoti naa.
Alukoro ajọ naa, Tunji Oketunbi, sọ pe awọn ti bẹrẹ iwadii ohun to fa ijamba naa.
Ẹlikọpita naa, Bell 206, to ni nọmba idanimọ 5N BQW, jẹ ti ileeṣẹ Quorum Aviation lo ja lulẹ lati inu ofurufu wọ inu ogiri to la ile meji ni nọmba 16A Salvation Road, Opebi Ikeja ni Eko ni nkan bii agogo mejila abọ ọsan ọjọ ẹti.
- Oral Sex: Bóo bá ń gba ẹnu ní ìbálòpọ̀, wo àìsàn tóo lè kó lójú ara rẹ
- Ìdí tí mo fi gbàdúrà ìyàwó bíi Chanel Chin fáwọn tó d'ẹ̀bi ìkọ̀sílẹ̀ rẹ̀ rù mí rèé - Oluwo
- 'Gómìnà Akeredolu ló wà nídí ìgbésẹ̀ yíyọ igbákejì rẹ̀, ìdí wàhálà wa nìyí'
- Wo sẹ́nẹ́tọ̀ mẹ́rin tó jáde láyé ní Nàìjíríà láàrin oṣù mẹ́fà sẹ́yìn

Ilu Port Harcourt, nipinlẹ Rivers, lo ti gbera, to si n bọ nipinlẹ Eko.
Awakọ baalu kan, oṣiṣẹ baalu kan, ati ero kan lo wa ninu rẹ.
Oludari ajọ apapọ to n mojuto iṣẹlẹ pajawiri ni Naijiria, Ibrahim Farinloye, sọ fun BBC pe lati ibi idanilẹkọ kan nilu Port Harcourt ni ẹlikọpita naa ti n bọ.
Bakan naa lo sọ pe awọn olugbe inu ile ti ẹlikọpita naa ja lulẹ si, ti pada sile wọn.
Agbẹnusọ Ileeṣẹ to n ri si iṣẹlẹ pajawiri ni ipinlẹ naa, LASEMA, Nosa Okubo sọ fun BBC pe eeyan meji lo ba iṣẹlẹ naa lọ ti ẹnikan si farapa.
Iṣẹlẹ ọhun waye lọsan ọjọ Ẹti ni ile to wa ni nọmba 16, Salvation, ni Opebi to wa ni Ikeja.
- Akeredolu ń fẹ́ kí wọ́n dìbò fún òun ló jẹ́ kó ṣàdínkù owó ilé ìwé AAUA - Akẹ́kọ́ọ̀ AAUA
- Ta ni Ọmọ ọdún 17 tí wọ́n fẹ̀sùn kàn pé ó pa èèyàn méjì ní Kenosha?
- Músò Músò! Akinwumi Adesina jáwé olúborí gẹ́gẹ́ bí adarí Báńkì AFDB
- Wo àṣẹ tuntun tí Buhari gbé síta nípa owó iná ọba
- Awọn afurasí Babaláwo pa ìyáwó Ìmáàmù àgbà ìlú Ayere ní Kogi, Alayere dá sọ́rọ̀
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Kọmiṣọna ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu sọ fun BBC lojuko iṣẹlẹ ọhun pe ni kete ti iroyin naa tẹ awón ọlọpaa leti ni awọn oṣiṣẹ rẹ tẹkọ leti lọ sojuko ọhun.

Oríṣun àwòrán, LASEMA
LASEMA sọ pe ọkunrin ni gbogbo awọn eeyan to ninu ọkọ ofurufu ọhun to jẹ ti ileeṣẹ Quorun Aviation ni ilu Eko.

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Ẹni ti ọrọ naa ṣoju rẹ, Olusunmade Olubunmi Damola sọ pe "iṣẹlẹ yii ṣẹlẹ ni dede aago mejila kọja iṣẹju mẹrinla, a gbọ ariwo nla kan ninu ọfiisi wa to dun bi iro ibugbamu."
"Igba ti a sa jade ni a to ri pe ọkọ ofurufu ẹlikọpita lo ja lulẹ."
- Ipò kíní ré sórí ìpínlẹ̀ Plateau! Èèyàn 296 ló forí kó Covid -19 ní Nàìjíríà lọ́jọ́bọ
- Wo ojú àwọn afurasí tó fipá bá Uwaila, akẹ́kọ̀ọ́ Uniben sùn tí wọ́n tún pa á sínúu ṣọ́ọ̀ṣì
- Kìí ṣe torí ìbèérè ni mo ṣe bẹ́ Fani-Kayode, àwọn akẹẹgbẹ́ mi ló kó mi láyà jẹ - Eyo Charles
- Ìjọba Nàìjíríà ti sún ọjọ́ tí ìrìnàjò bàálù sílẹ̀ òkèèrè yóò bẹ̀rẹ̀ padà síwájú
Damola sọ pe oun atawọn ti wọn jọ n ṣiṣẹ yọ eeyan meji jade ninu ọkọ ofuru naa ṣugbọ ko ri aye yọ ẹnikan to ku tititi awọn adoola ẹmi fi de.
Awọn asọju ileeṣẹ ijọba ijọba to n ri si iṣẹlẹ pajawiri to wa lojuko ti iṣẹlẹ naa ti waye ni iwadii ti bẹrẹ lati ohun gan pato to fa iṣẹlẹ'naa.
Wọn ni wọn ko tii le sọ ibi ti ọkọ ofurufu na ti n bọ tabgi ibi to n lọ, ṣugbọn gbogbo eyii ni yoo di mimọ lẹyin iwadii.
















