Health workers Strike: Àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera lábẹ́ àsìá JOHESU fagilé ìyanṣẹ́lódì káàkiri Nàìjíríà

Awọn dokita to n ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, others

Ẹgbẹ oṣiṣẹ eleto ilẹra lapapọ labẹ ẹgbẹ JOHESU ti kesi awọn oṣiṣẹ wọn lati pada si ẹnu iṣẹ.

Ọjọ meje ṣẹyin ni wọn gunlẹ iyanṣelodi lati pe akiyesi ijọba si awọn ohun to jẹ ẹdun kan fun wọn.

Amọ nibayii, awọn adari ẹgbẹ JOHESU naa ti wa paṣẹ fun wọn lati pada si ẹnu iṣẹ kaakiri orilẹede Niajiria.

JOHESU ni awọn gbegile iyanṣẹlodi naa bi o tilẹ jẹpe ijọba apapọ ko i tii dahun si ibeere wọn.

Ohun ti wọn n bere fun ni ki ijọba san owo oṣu ti wọn jẹ wọn, ki wọn si san owo ajẹmọnu ti ijamba ba ṣẹlẹ si oṣiṣẹ ilera lẹnu iṣẹ.

Amọ, titi di wakati yii ijọba apapọ ko dahun si ibeere wọn, ki wọn to gunlẹ iyanṣẹlodi lati kilo fun ijọba.

Nibayii, ẹgbẹ JOHESU ni awọn ọmọ ẹgbẹ yoo ṣe ipade lati ri wi pe awọn wa wọrọkọ fi sada lori igbesẹ ijọba yii, eleyii ti ko dun mọ wọn ninu.

Ẹgbẹ oṣiṣẹ eleto ilera marun un lo wa labẹ ẹgbẹ oṣiṣẹ JOHESU.

Ọjọ Kẹtala, Oṣu Kẹsan an, ọdun 2020 ni awọn oṣiṣẹ ilera naa gunle iyanṣẹlodi, ki wọn to ṣẹṣẹ pada si ẹnu iṣẹ bayii.

Ẹgbẹ́ àwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera, JOHESU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì káàkiri Nàìjíríà

Egberin ọtẹ lọrọ iyanṣẹlodi awọn oṣiṣẹ eleto ilera lorilẹede Naijiria yii o.

Lẹyin ọjọ mẹta pere ti ẹgbẹ awọn dokita da iyanṣẹlodi ti wọn gunle duro, ẹgbẹ gbogbo oṣiṣẹ eleto ilera ni Naijiria, Joint Health Sector Unions, JOHESU naa ti kede iyanṣẹlodi kaakiri orilẹede Naijiria.

Ẹgbẹ JOHESU paṣẹ pe ki awọn oṣiṣẹ eleto ilera da iṣẹ silẹ laago mejila oru ọjọ Aiku ọjọ kẹtala oṣu kẹsan an ọdun 2020.

Ninu atẹjade kan ti ẹgbẹ JOHESU kede iyanṣẹlodi ọhun ninu atẹjade kan to fi sita lọjọ Aiku.

Awọn alaṣẹ ẹgbẹ naa ti kọkọ ṣepade pọ pẹlu ijọba apapọ lọjọ Ẹti lori erongba rẹ lati gunle iyanṣẹlodi.

Ẹgbẹ JOHESU sọ ninu atẹjade naa pe iyanṣẹlodi ọhun yoo tẹsiwaju nitori ijọba ko ṣetan lati ṣe ohun tawọn n fẹ fawọn oṣiṣẹ eleto ilera.

Ẹgbẹ naa ti kọkọ fun ijọba ni ọjọ mẹẹdogun pe awọn yoo gunle iynaṣẹlodi ki wọn to bẹrẹ lọjọ Aiku.

Lara ohun ti wọn n beere lọwọ ijọba atunṣe owo idojutofo fu itọja coronavirus, sisan owo oṣu ti ijọba n jẹ awọn oṣiṣẹ eleto ilera to fi mọ owo oṣu wọn kẹrin ati ẹkarun un ọdun 2018 to wa nilẹ.

Amọ aiṣetan ijọba lati ṣe gbogbo nnkan yii lo mu wọn pada gunle iyanṣẹlodi lọjọ Aiku.

Àwọn dókítà Nàìjíríà ti fòpin sí ìyanṣẹ́lódì wọn

Ẹgbẹ awọn dokita ni Naijiria ti da iyanṣẹlodi ti wọn gunle duro fun saa diẹ.

Aarẹ ẹgbẹ naa, Aliyu Sokunbo sọ fu awọn akọroyin pe ẹgbẹ ọhun ti gunle idunadura miran pẹlu ijọba apapọ lori awọn ohun ti wọn n bere fun.

O ni lẹyin ipade ti wọn ṣe pẹlu ijọba apapọ ni wọn pinnu lati da iyanṣẹlodi ọhu duro fun oṣe meji lati wo ibi ti ọrọ awọn ati ijọba yoo yuọri si.

Ṣaaju ni ijọba apapọ ti sọ oun ti fi biliọnu mẹsan an din diẹ naira kun owo ajẹmọnu owo Covid-19 wọn, eyii to jẹ wọn fun oṣu kẹfa ọdun 2020.

Àkọlé fídíò, Mayowa Omoniyi: Kò sí orin Obey, Sunny Ade abí tàkasúfèé tí ń kò le ta gìtá sí

Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?

Mínísítà ní kò bójúmu fáwọn dókítà láti woṣẹ́ níran lásìkò àrùn Covid-19

Awọn dokita to n ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, others

Ijọba apapọ ti paṣẹ fun awọn dokita agba nile iwosan rẹ gbogbo, pe ki wọn fi awọn agunbanirọ to jẹ dokita rọpo awọn dokita to n yanṣẹ lodi.

Ijọba apapọ paṣẹ pe ki wọn fi awọn dokita agunbanirọ to n sinru ilu lọwọ, rọpo awọn dokita iṣegun to n yanṣẹ lodi lawọn ileewosan to jẹ ti ijọba apapọ naa.

Ijọba ni oun n gbe igbesẹ naa ki iṣẹ ipese ilera ati itọju awọn alaisan ma baa dawọ duro nibẹ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Minisita feto ilera, Dokita Osagie Ehanire lo pa aṣẹ yii lọjọru nilu Abuja lasiko to n sọrọ lori iyanṣẹlodi awọn dokita nile iwosan ijọba, NARD.

Awọn dokita to n ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, others

Iyansẹlodi naa n waye lori sisan owo ajẹmọnu fun ewu ti wọn la kọja lasiko ajakalẹ arun COVID-19 atawọn ẹdun miran.

Minisita Ehanire ni "ko si aniani pe, ojuṣe awọn dokita ati gbogbo awọn oṣiṣẹ eleto ilera ni lati doola ẹmi.

Ko si yẹ ko jẹ pe awọn dokita bẹẹ lo wa n da iṣẹ silẹ niru asiko bayii ti Naijiria n ba ajakalẹ arun finra."

O ni iru asiko yii lo yẹ ki gbogbo oṣiṣẹ lẹka eto ilera parapọ, wa koju ọta ọmọniyan yii, nitori naa, ohun to ku diẹ ka a to ni idaṣẹsilẹ naa.

Àkọlé fídíò, Mayowa Omoniyi: Kò sí orin Obey, Sunny Ade abí tàkasúfèé tí ń kò le ta gìtá sí

O fi kun un pe, bi o tilẹ jẹ wi pe ijọba ti mojuto ibeere yii, ti ijiroro lori awọn yooku si ti de ipele to lapẹẹrẹ, suuru ni awọn dokita naa ko ba fi yanju ọrọ naa.

"Ohun to ṣe pataki fun ijọba ni lati wa awọn ọna gbogbo to ba yẹ, lati fi rii daju pe irora iyanṣẹlodi naa ko pọ lapọju fun araalu.

Idi niyi ti ijọba fi paṣẹ pe, ki awọn dokita agba lawọn ile iwosan ijọba apapọ maa lo dokita agunbanirọ, lati maa tọ awọn to n gba itọju pajawiri lọdọ wọn.

Àkọlé fídíò, Bolaji Faleke ni Olùkọ́ tó ń kọ́ wa ní àṣà oge ṣiṣe lórí BBC Yorùbá

O wa ke s'awọn dokita ti n woṣẹ niran naa lati pada si ẹnu iṣẹ wọn, ki wọn lee tẹnpẹlẹ mọ ijiroro wọn to n lọ lọwọ pẹlu ijọba apapọ, lori awọn ibeere wọn naa.

Iná míràn tún fẹ́ ràn lẹ́ka ilera Nàìjíríà

A n jekuru ọrọ l'agboeto ilera lorilẹede Naijiria ko tan lawo, ṣe ni wọn tun n gbọn ọwọ rẹ sinu awo.

Lẹyin ti awọn dokita bẹrẹ iyanṣẹlodi wọn lọjọ Aje, ti ọpọ ọmọ orilẹede Naijiria si ti n pariwo, awọn oṣiṣẹ eto ilera yoku naa ti gbe ikilọ sita pe awọn pẹlu yoo gunle iyanselodi bẹrẹ bi ijọba apapọ ba kuna lati sise lori ẹdun wọn.

Ninu ọrọ to ba awon akọroyin sọ nilu Abuja, agbarijọpọ awọn ẹgbẹ oṣiṣẹ lẹka eto ilera lorilẹede Naijiria salaye pe ijoba ti n mu awon lọbọ lori ijiroro won.

Ninu ọrọ to sọ lorukọ awọn ẹgbẹ naa, alaga apapọ, JOHESU, Bio Josiahrọ minisita keji fun ọrọ oṣiṣẹ, Festus Keyamọ SAN lati kewaju ijiroro naa dipi Chris Ngige to n ṣe kokaari rẹ tẹlẹ

Lara awon ẹdun ọkan awọn oṣiṣẹ naa ni sisan aṣẹku owo ajẹmọnu oo asiko ajakalẹ arun COVID-19 fun awọn oṣiṣẹ naa ni ileewosan ijoba apapọ eleyii ti wọn ni o jẹ ida mẹwaa dipo ida ọgọta ninu ọgọrun ti o jẹ adehun ẹgbẹ oṣiṣẹ naa ati ijoba.

Bakan naa lo ke s'awọn ijobaipinlẹ ati ibilẹ ti wọn ko tii bẹrẹ si nii ṣe iṣẹ lori sisan owo ajẹmonu asiko ajakalẹ arun COVID-19 lati bẹrẹ si nii san an lẹyẹ o ṣọka.

Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?

Àwọn Dókítà Nàìjíríà bẹ̀rẹ̀ ìyànṣẹlódí lẹ́yìn tí ìjọba àpapọ̀ yẹ àdéhùn rẹ̀ pẹ̀lú wọn

Awọn dokita to n ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, others

Ẹgbẹ awọn dokita ni Naijiria ti bẹrẹ iyanṣẹlodi loni ọjọ aje.

Ẹgbẹ naa ni igbesẹ yii ko ṣẹyin bi ijọba apapọ ko ṣe mu adehun ṣẹ lori awọn ohun ti wọn jọ fẹnuko le lori.

National Association of Resident Doctors (NARD) ṣalaye pe lati osu kẹfa ni wọn ti ṣepade pẹlu ijọba apapọ lori igbesẹ yii.

Àkọlé fídíò, Temitope Akinnusi: Ọ̀pọ̀ iléeṣẹ́ ló takú láti gbà mí síṣẹ́ torí mo ní ojú kan

O to ida ogoji dokita Naijiria to wa ninu ẹgbẹ yii ti wọn n beere fun ẹkunwo owo oṣu, itọju to peye lẹnu iṣẹ, atunṣe to yẹ si awọn ile iwosan Naijiria paapaa lasiko Coronavirus yii

Aarẹ ẹgbẹ yii, Dokita Aliyu Sokomba sọ fun ileeṣẹ iroyin AFP pe awọn dokita to n tọju alaisan coronavirus naa yoo darapọ mọ wọn lasiko yii laiyọ ẹnikẹni silẹ

Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?

Nítorí aìsan owó àjẹmọ́nú, àwọn dókítà yóò bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódí lọ́jọ́ Ajé

Awọn dokita to n ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, others

Ẹgbẹ awọn dokita nileeẹkọṣẹ iṣegun gbogbo lorilẹede Naijiria, NARD ti kede pe awọn yoo bẹrẹ iyanṣẹlodi ọlọjọgbọọrọ bẹrẹ lati ọjọ Aje, ọjọ keje oṣu kẹsan ọdun 2020.

Ninu atẹjade kan ti ẹgbẹ naa fi sita lẹyin ipade igbimọ iṣakoso rẹ lo ti kede yii.

Wọn ni lai jẹ pe ijọba gbe igbesẹ lori awọn ẹdun ọkan wọn ti wọn gbe ka iwaju ijọba awọn yoo tẹsiwaju lori igbesẹ naa.

Lara awọn ohun to fa ẹhonu naa ni sisan owoona fun eto dokita abẹnu nileeṣẹ ẹkọṣẹ iṣegun Residency funding, owo gba ma binu fun ajakalẹ arun COVID-19, sisan owo ewu ẹnu iṣẹ (hazard allowance) pẹlu owo ajẹẹlẹ owo osu ọdun 2014, 2015 ati 2016.

Awọn dokita naa ti kọkọ lọ fun iyanṣẹlodi onikilọ ọlọjọ mẹkanlelogun lati fi fa ijọba leti ṣugbọn ti ko si ọrọ kankan latọdọ ijọba titi di bi a ṣe n sọrọ yii.

Awọn dokita to n ṣe iwọde

Oríṣun àwòrán, others