Oba Abd-Ganiyu Adekunle Salaueen Oloogunebi Ajinese 1 ti kéde pẹ orò ló kù láti lé àwọn ajínigbé

Oríṣun àwòrán, Oro Festival
A fẹ́ gbé orò láti lé àwọn ajínigbé kùrò ní ìpínlẹ̀ Oyo- Asẹyin
Aseyin ti ilu Iseyin, Oba Abd-Ganiy Adekunle Salaueen Oloogunebi Ajinese 1 ti sọ idi pataki ti ọdun oro yoo fi waye ni ilu Isẹyin ni asiko yii.
Oba Abd-Ganiy sọ eyi lasiko to n ke gbajare wi pe awọn ajinigbe ti poju lagbegbe naa, lẹyin ti wọn kede orisirisi iṣẹ ijinigbe to ti waye lagbegbe Ibarapa ati Oke-Ogun ni ipinlẹ Oyo.
O rọ ijọba apapọ lati gbiyanju lati ba wọn da si ọrọ naa ni kiakia nitori o ti n da ọrọ ojoojumọ.

Oríṣun àwòrán, Google
- Ẹ wo ọ̀nà àbáyọ sí ọ̀rọ̀ àgbàlagbà tò ń tọ̀ sílé
- Mo mọ̀ọ́mọ̀ sin ọmọ-ọmọ mi, ìkókó jòjòló láàyè ni, nítorí wọ́n fipá bá ọmọbìnrin mi lòpọ̀ ló fi lóyún rẹ̀!
- Obìnrin bíi Ruth Bader ni yóò gba ipò rẹ́ ní iléẹjọ́ tó gajùlọ nílẹ̀ Amerika- Donald Trump
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí ọkùnrin tó gé akẹ́kọ̀ọ́ ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ wẹ́lẹ́ wẹ́lẹ́ fún òògùn owó ní Ikorodu
Oba Abd-Ganiy sọ eyi lasiko ti ọdun ọrọ bẹrẹ ni aafin Iṣẹyin ni opin ọsẹ.
Aṣẹyin ni ọdun oro ni ọdun 2020 yii yoo wa fun adura lati le awọn ajinigbe kuro ni ayika wọn, ki ijọba Makinde le ni alaafia.
Bakan naa lo ni wi pe ọjọ keje ati ikarundinlogun ọdun oro naa ni awọn yoo gbe oro naa.
Ni ọjọ ti wọn ba gbe oro naa, awọn obinrin kii jade titi oorun yoo fi wọ ni awọn ọjọ wọnyii.
Asẹyin ni: ''A ti fun awọn ajinigbe ni epe lati ma ṣe rojuraye ni agbegbe wa mọ, nitori o ti pọju ni agbegbe Ibarapa ati Oke-Ogun.''
''Bakan naa ni a kesi ijọba apapọ lati jọwọ ran wa lọwọ lati wa ọna abayọ si ijinigbe yii.''
Ninu atẹjade naa ni wọn ti fikun un wi pe awọn ẹsọ alaabo ti wa ni pesẹ lati ri i wi pe ayẹyẹ naa lọ ni irọwọ-rọsẹ.
Aseyin ti ilu Iseyin, Oba Dr. Abd-Ganiy Adekunle Salaueen Oloogunebi Ajinese 1 fikun un pe igba ati akoko gomina Seyi Makinde yoo rọ wọn lọrun.
O gba awọn adari nimọran lati ṣe ohun to yẹ fun igbadun ati alaafia ara ilu nitori awọn alalẹ ati ara ọrun n wo wọn.
- Ilé ìjọsìn lè bẹ̀rẹ̀ ìsìn àárín ọ̀sẹ̀ padà, Mọ́sáláṣí àti Ṣọ́ọ̀ṣì lé gba iye èèyàn tó wù wọ́n ṣùgbọ́n...
- Obìnrin bíi Ruth Bader ni yóò gba ipò rẹ́ ní iléẹjọ́ tó gajùlọ nílẹ̀ Amerika- Donald Trump
- 'Mo mọ̀ọ́mọ̀ sin ọmọ-ọmọ mi, ìkókó jòjòló láàyè ni, nítorí wọ́n fipá bá ọmọbìnrin mi lòpọ̀ ló fi lóyún rẹ̀'!
- Ọkùnrin tí wọ́n fẹ̀sùn kàn pé ó jí ǹkan nílé ìjọsìn rí ẹ̀wọ̀n he!
- Aya gómìnà Kwara gba ilé fún Risikat olójú búlúù àti ọkọ rẹ̀
Ṣaaju ni Ifayemi Elebuibọn ti sin awọn Ọba alade ni gbẹrẹ ipakọ lori oro gbigbe gẹgẹ bii aṣa ti ko yẹ ko parun
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Ọbalayé ní kò yàtọ̀ sí èèyàn lásán - Elebuibon
"Ọpọlọpọ awọn ọbalaye ni ilẹ Yoruba ni ko yatọ si eeyan lasan nitori wọn n tapa si iṣẹṣe ati iṣẹmbaye".
Araba ilu Oṣogbo, Oloye Ifayẹmi Ẹlẹbuibọn lo ṣọ ọrọ yii lasiko ajọdun ọdun kẹwaa rẹ lori oye gẹgẹ bi araba awo ilu Oṣogbo.

Oríṣun àwòrán, Crown-art
- Ọdún mọ́kànlá rèé témi àti ọkọ mi bẹ̀rẹ̀ ìfẹ́ láti ilé ẹ̀kọ́ girama - Bukunmi Oluwasina
- Ohun méje tí Jimoh Aliu fi yàtọ̀ lágbo tíátà
- Ikorodu Bois fí àwàdà bọ àwòrán àwọn ọmọ Otedola, ẹ wo ará tí wọ́n dá
- Adunni Oluwole, akọni obìnrin tó tako òmìnira Nàìjíríà, ó ní òyìnbó kò gbọ́dọ̀ lọ
- Àṣírí ńlá tó ń bẹ láàrín Alaafin àtàwọn onílù rẹ̀ rèé
- Àlàyé rèé lórí bo ṣe le è dá Emèrè mọ̀ tàbí dara pọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ wọn
Oloye Ifayẹmi ni ọpọlọpọ awọn Ọba ni ko karamasiki orò ilu tabi aṣa ati iṣẹṣe mọ.
"Ọba ti wọn ko ba ṣoro fun, ti ko tẹfa ti ko ṣe gbogbo nnkan ibilẹ to jẹ ọba le lori, ko yatọ si eeyan lasan."
Baba Araba ni ohun to n da awọn ọba ya sọtọ naa ni awọn oro, ati nnkan ibilẹ ati iṣẹdalẹ ilu rẹ to jẹ ọba le lori.
Ọba ti ko ba ti wa ṣe e, baba Araba ni kii ṣe Ọba, eeyan lasan ni.
O ni bi awọn Ọbalaye ba n tẹriba fun iṣẹṣe ati iṣẹdalẹ ilu wọn ni yoo mu ki ilu o toro ki o si tuṣẹ.
O rọ awọn aṣiwaju ni ilẹ Yoruba lati gbe aṣa ati iṣe Yoruba nitori ibi a gbe laa ṣe.

Oríṣun àwòrán, Getty Images / flev
O wa rọ awọn adari lorilẹede Naijiria pe ki wọn ṣee re nitori ohun wọn ba ṣe silẹ n labọwaba.
Ni ọdun 2010 ni wọn fi oloye Ifayẹmi jẹ oye Araba awo ti ilu Osogbo eyi to fihan pe oun ni olori gbogbo onifa ati alawo ni ilu Oṣogbo.
- Ẹ̀rọ CCTV tú àsírí ọkùnrin ẹni ọgbọ̀n ọdún tó fi ipá bá ọmọ ọdún mọ́kànlá lòpọ̀
- Ó ń bọ̀ lọ́nà! Odunlade Adekola, Femi Adebayo, Jenifa ṣi aṣọ lójú àwọn fíìmù tuntun tẹ́ẹ tiń retí
- Àwọn ọmọ Naijiria ṣèdárò gbajúgbajù agbábọ́ọ̀lù Super Eagles tó dolóògbè
- Ọmọ Ààrẹ lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣe ìgbéyàwó yálà àwọn ará ìlú fẹ́ràn ìjọba bàbá rẹ̀ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́ - Aisha Buhari
- Aya gómìnà Kwara gba ilé fún Risikat olójú búlúù àti ọkọ rẹ̀















