Mike Bamiloye, adarí Mount Zion bèrè bóyá àpaàyàn kọ́ ní ẹni tó ń ṣí ara sílẹ̀ lọ ṣọ́ọ̀ṣì, ṣé apàyàn kọ́ ni ẹ́ báyìí?

Awọn aṣẹwo ni Naijiria

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Gbajugbaja oṣere kritẹni, Mike Bamiloye to jẹ oludasilẹ ẹgbẹ oṣere Mount Zion ti ja gudugbẹ ọrọ lulẹ lori aṣọ wiwọ ni ṣọọṣi.

Bamiloye ni ''o n wọ aṣọ to ṣi ara silẹ lọ si ṣọọṣi, o tumọ si pe o ti pinnu lati di apayan ni ṣọọṣi.''

''Iwọ ni tiẹ, ijo ati mu ọmọlakeji ṣubu ni iwọ mọ ọ jo ni tiẹ ti wọn ba n kọ irin ninu isin,'' Bamiloye lo sọ bẹẹ.

Bamiloye ni ''iwọ to sọ pe o n jo lati yin Ọlọrun ni ti o si mọ pe fun ra rẹ pe irọ lo n pa.''

Skip Facebook post

Content is not available

View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.

End of Facebook post

Gbajugbaja oṣere kristẹni naa wa beere pe ''njẹ apayan ni ṣọọṣi kọ niọ bayii.''

Àkọlé fídíò, Bolaji Faleke ni Olùkọ́ tó ń kọ́ wa ní àṣà oge ṣiṣe lórí BBC Yorùbá

Ọpọ lo ti di ẹbi aṣọ iwọkuwọ ṣọọṣi ru awọn obinrin nikan, ṣugbọn awọn mii sọ pe ki lawọn ọkunrin naa n wo lara obinrin ti wọn kko kọ oju mọ isin ni ṣọọṣi.

Awọn miiran tiẹ ni aṣọ iwọkuwọ lawujọ gan an lo sẹ okunfa iwa ifipabanilopọ to ti pọ si ni Naijiria bayii.