Kayode Williams ọmọ lẹyin Oyenusi, ògbóǹtarìgì adigunjalè tó ń fi àyípadà rẹ̀ ran àwọn ẹlẹ́wọ̀n lọ́wọ́

Àkọlé fídíò, 'Oyenusi ló mú mi wọ ẹgbẹ́ adigunjalè kó tó di pé mo b'Ólúwa pàdé'

Oyenusi ló mú mi wọ ẹgbẹ́ adigunjalè kó tó di pé mo b'Ólúwa pàdé - Kayode Williams

Kayode Williams ni igbe aye ọtọọtọ gba a ni ki eeyan lọ sẹwọn ati ki o tẹwọn de eyi to si nilo ilanilọyẹ akọtun.

"O nilo ikọni, idari, ọrọ pe o gba ẹsin kọ leleyii, Ọlọrun gbudọ tun un bi tori eeyan ṣaa ni mi..."

"Ọgbà ẹwọn Nàìjíríà tó kàn rí bíi pé wọn kó ẹranko si Zoo ni kò jẹ kí ayé àwọn ọdáràn yí padà"

O sọ aṣiri bi awọn Pasitọ ati Wolii nla nla ṣe maa n sẹri ibukun sori ibọn wọn ati ifami ororo yan ki wọn to jade lọ ja ole bi wọn ba si dari wọn a wa fi idamẹwa silẹ.

Ko to di atunbi, ogbontarigi ọdaran ni Kayode Williams ti orukọ rẹ ti yipada si Biṣọọbu Kayode Williams bayii.

Kayode Williams

Oríṣun àwòrán, @kayode

Kayode ni kii ṣe pe iwa awọn pasitọ wu oun lorii loun fi faye oun fun Jesu bi ko ṣe pe Ọlọrun diidi gba ẹnu adajọ to paṣẹ ẹwọn ọdun mẹwaa fun un sọrọ sinu aye oun.

Wiliams sọ bi o ṣe pade ogbontarigi adigunjale Ishola Oyenusi to gbajumọ nigba aye rẹ fun dida ilu ru.

O darukọ Ọmọwe Ishola Oyenusi, Babatunde Folorunsho, Baba Koshewọn to jẹ pe ọwọ ọlọpaa ko ki n tẹ ẹ.

Ọmọde ni Kayode nigba naa ṣugbọn itan bi ẹgbẹ awọn agbalagba ọdaran ṣe fi owo tan an toun naa bẹrẹ si ni gbe ibọn to si n mu igbo jẹ ibanujẹ to dori agba kobo.