Increment in bread price: Ọ̀wọ́ngógó búrẹ́dì gbòde kàn lẹ́yìn tí àwọn oníbúrẹ́dì da iṣẹ́ sílẹ̀

Oríṣun àwòrán, Google
Awọn olugbe ilu Abuja ati Eko ti ke gbajare sita lẹyin ti ọwọngogo burẹdi gbode kan.
Awọn oniburẹdi gunle iyanṣẹlodi lẹyin ti iye owo iyẹfun, suga ati awọn awọn ohun elo miran wọn si.
Awọn to n ta burẹdi lẹgbẹ titi naa faragba ninu iyanṣẹlodi yii, eleyii to fa ọwọngogo burẹdi kaakiri orilẹede Naijiria.
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá sọ afurasí ọlọ́pàá tó yìnbọn fún ọ̀dọ́kùnrin tó fún èèyàn lóyún s'átìmọ́lé
- Àwọn agbófinró ti mú Eji tó jẹ́ igbákejì Ebila, olórí ẹgbẹ́ òkùnkùn "One Million Boys" sí gbaga
- Wo bí odò Nile tó gùn jù l'Áfíríkà, ṣe ń fójúu ilẹ̀ Egypt, Ethiopia àti Sudan han màbo
- Bí ẹgbẹ́ One Million Boys ṣe bẹ̀rẹ̀ rèé àti ọṣẹ́ tó ṣe n'Ibadan
- Èèyàn kan kú, ọmọ méjì sọnù nínú òjò tó rọ̀ nílùú Ilorin
Lara awọn olugbe ilu Abuja sọ wi pe, iyalẹnu lo jẹ fun awọn nigba ti wọn ko ri burẹdi ra jẹ.
O buru to bẹẹ ni opin ọsẹ ni awọn ipinlẹ bii Nasarawa ati Niger nitori iyanṣẹlodi naa bẹrẹ ni Ọjọ Ẹti,ọsẹ to kọja.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Lara awọn oniburẹdi to ba awọn oniroyin sọrọ ni bi o tilẹ jẹpe awọn yoo fopin si iyanṣẹlodi naa, o pọn dandan ki owo burẹdi wọn si.
'' Nibayii, owo iyẹfun ti a n ra ni N10,000 si N12,000, ti da N14,000 bayii.''
''Apo suga ti a n ra ni N11,000 tẹlẹ, ti da N18,000 bayii ati 25-lita ororo ti awọn n ra tẹlẹ ni N8,000 ti da N15,000 bayii.''
Wọn ni ohun to fa ọwọngogo yii ni wi pe, oke okun ni wọn ti n ra awọn eronja yii tẹlẹ, amọ nitori ijọba ti yọ owo iranwọ lori awọn ounjẹ lati okeere, eleyii ti mu ki ohun gbogbo nira fun awọn eniyan.
Ni ipinlẹ Eko bakan naa, awọn oniburẹdi ni ohun to fa ọwọngogo burẹdi ni iye ti wọn ra awọn eronja ti wọn nilo, owo ọkọ to wọn gogo ati bii ijọba apapọ ṣe fi owo kun owo ori ti awọn eniyan n san.
Amọ, Ajọ awọn oniburẹdi ni ipinlẹ Eko ti ni awọn yoo bẹrẹ iṣẹ pada loni, amọ o lera fun awọn lati ta burẹdi ni iye ti wọn n ta a tẹlẹ nitori ọpọlọpọ wọn ti jẹ gbese lori iṣẹ burẹdi tita naa.
- Ọmọ Ààrẹ lẹ́tọ̀ọ́ láti ṣe ìgbéyàwó yálà àwọn ará ìlú fẹ́ràn ìjọba bàbá rẹ̀ tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́ - Aisha Buhari
- Ọkùnrin tí wọ́n fẹ̀sùn kàn pé ó jí ǹkan nílé ìjọsìn rí ẹ̀wọ̀n he!
- Áṣẹyin kìlọ̀ fáwọn adarí olóṣèlú Nàìjíríà láti ṣe ohun tó yẹ nítorí ará ọ̀run ń wò wọ́n!
- Èèyàn kan kú, ọmọ méjì sọnù nínú òjò tó rọ̀ nílùú Ilorin
- Èèyàn 97 ní àrùn Coronavirus tún ṣẹ̀ṣẹ̀ ràn ní Nàìjíríà ní Ọjọ́ Àìkú
- 'Mo mọ̀ọ́mọ̀ sin ọmọ-ọmọ mi, ìkókó jòjòló láàyè ni, nítorí wọ́n fipá bá ọmọbìnrin mi lòpọ̀ ló fi lóyún rẹ̀'!
Àwón Oníbúrẹ́dì ń gbé ìgbésẹ̀ láti fi kún owó Búrẹ̀dí ní Nàìjírià
Ẹgbẹ awọn oniburẹdi ni Naijiria ti apẹjẹ wọn n jẹ Premium Breadmakers Association of Nigeria (PBAN) ati ẹgbẹ awọn alase ti wọn n jẹ Association of Master Bakers and Caterers of Nigeria ti yari fun ijọba Naijiria lori ọwọngogo ohun jijẹ laisko yii.

Oríṣun àwòrán, Twitter/OkayAfrica
Wọn kede ni ipinl\e Eko pe alekun yoo ba iye owo burẹdi ati awọn ohun jijẹ ti wọn fi iyẹfun ati ṣuga ṣe laipẹ nitori pe awọn ti bẹrẹ igbesẹ lati mu ẹkunwo naa di ajumọṣe.
Ogbẹni Tosin Jemide to jẹ Aarẹ ẹgbẹ PBAN ni Naijiria sọrọ lori iṣoro ti awọn ọmọ ẹgbẹ n koju lẹnu oko owo naa bayii.
- Jàńdùkú olóṣèlú gbàkóso ilé aṣòfin l‘Ondo
- Adájọ́ ní kí Ahmed Danladi, tó jẹ́ awakọ̀ tó jalè gbálẹ̀ kóòtù f'ọ́jọ́ méjì ní Abuja
- Wo àmì márùn-un tí o fi le mọ ẹni tó fẹ́ gbẹ̀mí ara rẹ̀
- Ọ̀dọ́ Nàíjíríà fèsì padà fún Buhari lórí ìkéde pé kí wọn padà sóko
- Wo ìyá ọlọ́mọ mẹ́ta tó ti pé ọdún 48 tó ń ṣe ìdánwò WAEC, kó le di nọ́ọ́sí
Ṣaaju ni awọn ọmọ Naijiria kan ti pariwo pe owo burẹdi ti le sii nigboro ati pe kii ṣe ounjẹ mẹkunnu mọ.
Jemide ni owo ti awọn ọmọ ẹgbẹ n ra Suga ati iyẹfun lasiko yii ti kuro ni keremi lati nkan bii oṣu mẹfa sẹyin lo ti n gbowo lori siii lọsẹẹsẹ.
O ni koda, awon ohun eelo lati fi ṣe burẹdi miran yatọ si ṣuga ati iyẹfun gan an kọja bẹẹ.
Aarẹ naa ni orin o to gẹ ni ẹgbẹ mejeeji n kọ lasiko yii fun ijọba.
O ni asiko ti to ki ijọba pese iranlọwọ fawọn oniṣe burẹdi ki ara le rọ tẹru tọmọ.
Ẹgbẹ yii tu bẹnu atẹ lu bi erongba ijọba lati ọdun 2012 ko ṣe tii so eso rere di asiko yii.

Oríṣun àwòrán, @Kitchnbutterfly
O ni bẹẹ awọn oniburẹdi san ida mẹẹdogun ti ijọba n beere fun owo idagbasoke ki ijọba to le mu idagbasoke ba awọn oniburẹdi.
Ni ipari, ẹgbẹ mejeeji parọwa fun awọn ara ilu lati murasilẹ lati maa ra burẹdi ni owo to le diẹ si ti atẹyinwa ni eyi ti kii ṣe ẹbi awọn oniburẹdi rara.
- Wo ìyá ọlọ́mọ mẹ́ta tó ti pé ọdún 48 tó ń ṣe ìdánwò WAEC, kó le di nọ́ọ́sí
- Wo fọ́tò àrà MC Oluomo, Pasuma àtàwọn òṣèré tíátà míì níbi ìṣílé Iyabo Ojo
- Adájọ́ ní kí Ahmed Danladi, tó jẹ́ awakọ̀ tó jalè gbálẹ̀ kóòtù f'ọ́jọ́ méjì ní Abuja
- Wo àmì márùn-un tí o fi le mọ ẹni tó fẹ́ gbẹ̀mí ara rẹ̀
- Àjọ Elétò ìdìbò INEC ti sọ̀rọ̀ lórí iná tó jó àwọn káàdì ìdìbò ní Ondo















