Stealing: Ilé-ẹjọ́ ní kí Danladi, awakọ̀ tó jalè gbálẹ̀ kóòtù f'ọ́jọ́ méjì

Ofin

Oríṣun àwòrán, others

Ileẹjọ majisireeti ẹkun Wuse niluu Abuja ti pàṣẹ fun awakọ kan, Ahmed Danladi to jale pe ko gba ilẹ kootu fun ọjọ meji.

Awọn ọlọpaa lo fẹsun ole kan Danladi ẹni ọdun marunlelọgbọn.

Lẹyin ti Danladi gba pe oun jẹbi ẹsun ole ti wọn fi kan an, Adajọ majisireeti Omolola Akindele dajọ pe ki o wa gbale ileẹjọ lai si anfaani lati san owo itanran.

Ileeṣẹ ọlọpaa sọ pe ọkunrin kan Samuel Joseph lo mu ẹjọ Danladi wa lọjọ kinni, oṣu kẹsan an, ọdun 2020 yii.

Awọn ọlọpaa ṣalaye fún ileẹjọ pe ẹrọ ti wọn máa fi n fọ nnkan ọga rẹ ni Danladi jigbe ti o si fẹ ta fawọn to n sa ilẹ kiri ki aṣiri rẹ to tu

Àkọlé fídíò, Mayowa Omoniyi: Kò sí orin Obey, Sunny Ade abí tàkasúfèé tí ń kò le ta gìtá sí