Ember Month Security: Ọwọ́ pálábá àwọn ọmọ ẹlégbẹ́ òkùnkùn 15 ségí ní ìpínlẹ̀ Eko

Oríṣun àwòrán, Lagos Police
Ijọba ipinlẹ Eko ni ọwọ awọn ti tẹ awọn ọdaran ti wọn n da agbegbe Ikorodu ati Lekki/Ajah laamu nipinlẹ Eko.
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Eko, Olumuyiwa Adejobi, ninu atẹjade to fi lede naa ni ikọ ọlọpaa to wa ni Ikorodu lo mu awọn ọdaran naa.
Adejobi ni ohun to ṣẹlẹ ni wi pe araalu kan lo ji pe awọn ọlọpaa ni aago mẹrin owurọ lati agbegbe Agunfoye,
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìjà àgbà méjì! Àlàyé rèé lórí ááwọ̀ Femi Fani-Kayode àti Tunde Bakare
- Àwọn àjàkálẹ-àrùn tó ti wáyé rí ṣáájú Coronavirus
- Ta ni Ọ̀jọ̀gbọ́n àkọ́kọ́ nípa ìmọ̀ ọ̀daràn ní Nàíjíríà, Femi Odekunle tí Covid-19 pa?
- Ikú Adewole Oniluola, tó ní ẹ̀bùn ìlù lílù jùlọ lágbàyéé, yóò nípa lórí Yorùbá - Tunde Kelani
- Ayinla Ọmọwura, orin èébú àti oríyìn lo fi di ọ̀rẹ́ àwọ̀n obìnrin
- Ẹ wo ojú àwọn afurasí tí yóò rojọ́ ẹ̀ṣùn àjẹbánu lọ́dún 2021
- Bí Nàíjíríà bá fẹ́ kí ọdún 2021 dára, ohun tí yóò ṣe rèé - Obasanjo
- Ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ méjì fìjà pẹẹ́ta, ẹ̀mí kan bọ́, ọ̀pọ̀ farapa
Nigba ti ikọ ọlọpaa Ikorodu yoo fi de ibẹ ni ọwọ tẹ arakunrin Taiye Lasisi, ti wọn mu pẹlu ibọn ilewọ lọwọ rẹ.
Lẹyin ti ọlọpaa fi panpẹ mu tan ni wọn tu gbogbo agbegbe naa yẹbẹ yẹbẹ, ti ọwọ si tẹ awọn yoo ku.
Lara awọn mẹtala ti wọn mu naa jẹ awọn ẹlẹgbẹ okunkun Aiye, ti wọn si wọn si ti gbe wọn lọ si atimọle.

Oríṣun àwòrán, Lagos Police
Bakan naa ni wọn ri awọn ohun ini gba lọwọ wọn bi ẹrọ ilewọ ati awọn ohun ini miran.
Ninu ọrọ tirẹ, Kọmisọnnna ọlọpaa nipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu ni iwadii ti bẹrẹ lori iṣẹlẹ naa, ati wi pe awọn ko ni fi aye gba iwa ipa ati iwa ọdaran kankan nipinlẹ Eko.
Ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ méjì fìjà pẹẹ́ta, ẹ̀mí kan bọ́, ọ̀pọ̀ farapa
Ìjà kan to waye laarin awọn ọmọ ẹgbẹ meji nilu Ejigbo ti ṣokunfa iku arakunrin kan, Abeeb Abifarin ti agboole Oke Dada nilu Ejigbo nipinlẹ Osun.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Lọjọ isegun ni o padanu emi rẹ ninu ìjà yọbẹ y'ada laarin awọn ẹgbẹ meji nilu naa.
Bakan naa la gbọ pe ọpọ eeyan lo farapa ninu ìjà yii, tó bẹrẹ ni irọlẹ ọjọ Aje ladugbo Ori Eru laarin awọn ọmọ ẹgbẹ Lion Base Club, ti agboole Olukola ati awọn ti Isalẹ Agooji Club.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Àhámọ́ ajínigbé ni ń bá wà lónìí, ọ̀pẹ́ awakọ̀ mi"
- Ẹ wo nkan tí Deeper Life High School tún sọ lórí Don Davis, akọ́kọ̀ọ́ JS1 tí wọ́n fi ipá bálòpọ̀
- Àjọ NIMC ti gbé ìlànà tuntun jáde fún gbígba NIN lọ́nà ìrọ̀rùn
- Wo ọ̀pọ̀ mílíọ̀nù fóónù tí Whatsapp kò ní bá ṣiṣẹ́ mọ́ lọ́dún 2021
- Ibodè àgbáyé ní Saki, ìbẹ̀ ni agbébọn ń gbà wọ ilẹ̀ Káàrọ̀ Oòjíire - Makinde gbarata
Ohun taa gbọ ni pe, wọn yìnbon pa Abeeb bí ọwọ agọ meje kú iṣẹju mẹẹdogun aṣalẹ ọjọ Aje nigba ti ìjà yi bẹ sílẹ.
Awọn kan ti ọrọ naa soju ni, wọn ge apa rẹ jabọ ninu ikọlu yi.

Ara adugbo naa kan to ba awọn akọroyin sọrọ, ṣugbọn ti ko fẹ ki wọn darukọ rẹ sọ pe, ọkunrin kan t'awọn ko mọ orukọ rẹ naa tun ku lọjọ ìṣẹgun lẹyin t'awọn agbofinro pẹtu sí aawọ náà tan.
Amọ ṣa ileesẹ wa kò ti ribi fidi ọrọ bayi mu'lẹ.
Pupọ awon ilé ìtajà ni Ejigbo ni wọn sáré ti pa nitori wahala yii, ti won sì tun ti ileesẹ awọn oṣiṣẹ ijọba ibilẹ Ejigbo naa pa, ki awọn oṣiṣẹ pada sílé.
A tún padà gbọ pe awọn to dojú ìjà kọ ara wọn ọhun tun gbe ìjà wọn dé adugbo Sagan, Orieru, Port junction ati roundabout pẹlu nkan ija oloro titi di afẹmọju lojo Ìṣẹgun.
A kò tíì le sọ nkan to fa ìjà yi pato sugbọn finfinfin t'awọn akọroyin lagbegbe naa gbọ ni pe, owo ẹbùn ọdun to to ẹgbẹrun lọna aadọjọ naira (N150,000) lo dá ìjà silẹ.
Ìdájọ́ ọwọ́ tó di lemọ́-lemọ́ n'Ibadan, ohun tó fà á rèé

Oríṣun àwòrán, Plustv africa
Ohun to n mu ki ọpọ eeyan maa dawọle idajọ ọwọ ara ẹni, taa mọ si Jungle Justice, ni ainigbagbọ to kuna ninu eto idajọ ododo ti ofin gbe kalẹ.
Eyi ni ọrọ Amofin Akeem Fadun, eekan agbẹjọro kan nilu Eko lasiko to n ba BBC Yoruba sọrọ lori ohun to mu ki idajọ ọwọ lawujọ di lemọ-lemọ.
Kii ṣe ani-ani mọ pe awọn eeyan ni ipinlẹ Ọyọ n se gbọnmọgbọnmọ fifi idajọ afurasi sọwọ ara wọn, eleyi to si ti n kọ ọpọlọpọ eeyan ati awọn onwoye lominu.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Àhámọ́ ajínigbé ni ń bá wà lónìí, ọ̀pẹ́ awakọ̀ mi"
- Bodè àgbáyé ní Saki, ìbẹ̀ ni agbégbọn ń gbà wọ ilẹ̀ Káàrọ̀ Oòjíire - Makinde gbarata
- Saheed tí wọ́n dáná sun ní OkeAdo, Ibadan, ajínigbé ni àbí àrìnfẹsẹ̀sí?
- Kí ló dé tó jẹ́ sọ́ọ̀sì nìkàn ni ìjọba ń tìlẹ̀kùn mọ́ torí Covid-19? - CAN
- Ẹ wo àwọn ìlúmọ̀ọ́ká ọmọ Nàíjíríà tó jáde láyé lọ́dún 2020
- Ìtàn ìgbé ayé Isola Ogunsola, akọni mánigbàgbé òṣèré tíátà, olórin àti onílù
- "Ma a pa ara mi si Cute Abiola lọrun bo ṣe já mi silẹ tori afẹsọna miran"
- "Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àgbà fipá bá ọmọkùnrin mi lòpọ̀ níléèwé Deeper Life, mò ń fẹ́ ìdájọ́"
- Wo ọ̀pọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ igba tí Primate Ayodele gbé síta fọ́dún 2021
Laarin bi ọsẹ diẹ sẹyin bayii, ko din ni eeyan mẹfa ti awọn eeyan ti dana sun ninu isẹlẹ ọtọọtọ, tori pe wọn fura iwa aidaa kan tabi omiran si wọn.

Oríṣun àwòrán, Tade Oludayo
Amofin Akeem Fadun ni ọpọ igba ni araalu maa mu ọdaran lọ si agọ ọlọpaa ṣugbọn to jẹ wi pe wọn yoo tun ri ọdaran bẹẹ nigboro lẹyin wakati tabi ọjọ diẹ.
Bakannaa lo tun pe fun eto ilanilọyẹ fun araalu lori ipenija ati ewu to wa lori idajọ ọwọ.
Eekan amofin naa fi kun un pe, ọdaran ni ẹnikẹni to ba lọwọ ninu iṣẹlẹ idajọ ọwọ labẹ ofin.

Oríṣun àwòrán, @PoliceNG
O ni nibi ti ọrọ de duro bayii, ijọba gbọdọ bẹrẹ si ni fi awọn to ba n lọwọ ninu iṣẹlẹ didana sun afurasi tabi idajọ ọwọ jofin, lati lee jẹ ifaleti fun awọn eeyan mii lọjọ miran.
Onimọ nipa ofin naa ko ṣai yannana rẹ pe, wahala iwọde #EndSARS to kọja laipẹ yii ti n fun awọn eeyan ni igboya lati hu awọn iwa kotọ.
"Wọn ti lero pe bi awọn ṣe parapọ ba ọpọ dukia jẹ, ti wọn si ṣe ọpọ iwa jagidijagan lasiko naa, ti ko si si ẹni to mu wọn sii, ni awọn ṣe lee maa hu iwa kotọ naa lọ.

Oríṣun àwòrán, Abdulmumin Rabiu
Ijọba gbọdọ fi awọn eeyan jofin daadaa lori iwa aburu yii, lati jẹ ki araalu mọ pe iyatọ wa laarin kiko ara jọ pọ, ja fun ẹtọ labẹ ofin ati kiko ara jọ pọ hu iwa ọdaran."
Bakannaa ni Amofin Akeem Fadun tun mu aba wa pe, bi araalu ko ba ni igbagbọ ninu ilana idajọ lorilẹede yii, boya ki wọn maa gbe igbimọ kan kalẹ, lati maa tọpinpin bi awọn agbofinro ṣe n yanju awọn afurasi ti wọn ba gbe wa si ọdọ wọn.
Iha wo ni ijọba Oyo kọ si idajọ ọwọ to di lemọ-lemọ?
Ẹwẹ, nigba ti BBC News Yoruba kan si ijọba ipinlẹ Ọyọ, kọmiṣọna feto iroyin ati aṣa, Ọmọwe Wasiu Ọlatubọsun ṣalaye pe ijọba n gbe igbesẹ lati tubọ mu ki okun ati koriya wa fun awọn agbofinro lati ṣiṣẹ wọn.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Dr. Wasiu Adewale Olatubosun
Ọmọwe Ọlatubosun ni itaniji ti bẹrẹ lori iwa kotọ yii, lati mu ki araalu mọ wahala to rọ mọ irufẹ iwa didana sun awọn afurasi.
Bakan naa lo tun rọ awọn ọlọpaa lati rii pe gbogbo afurasi ti wọn ba mu de ọdọ wọn, ni wọn foju wina ofin.
Adigunjalè méjì ko ìjàmbá ọ̀kadà lẹ́yìn ìṣẹ́ ibi n'Ibadan, ọ̀kan kú lójijì, aráàlú dáná sun èkejì
Yoruba ni ọjọ gbogbo ni ti ole, amọ ọjọ kan soso pere ni ti olohun.
Bẹẹ lọrọ ri fun awọn adigunjale meji kan lọjọru nilu Ibadan nigba ti wọn ja ọkunrin kan lole amọ ti ọwọ palaba wọn segi.
Atẹjade kan ti ileesẹ ọlọpa fisita lori isẹlẹ naa salaye pe deede aago mẹta aabọ irọlẹ ọjọru ni isẹlẹ naa waye si ọkunrin kan, ti wọn pe orukọ rẹ ni Tobi Adebayo, ẹni ọdun mẹtadinlọgbọn to wa ninu ọkọ ayọkẹlẹ rẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àwọn ohun kàyéèfì tó le mú kí ọmọbìnrin ní oyún ìju
- Ìrẹ̀sì kò gbọdọ̀ wọlé níbáyìí ta ṣí ẹnu bodè padà - Ìjọba àpapọ̀
- Ìdí tí àwọn ìpińlẹ̀ se ń ti ilé ẹ̀kọ́ ní ìhà ìwọ̀ Oòrun-Àríwá Nàìjíríà rèé
- Abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 yóò dé sí Nàìjíríà nínú oṣù kíní ọdún 2021
- Jide Kosoko forin sẹ́nu pé òun ni igi lẹ́yìn ọgbà Mr Latin lórí ipò ààrẹ TAMPAN tó wà
- Ó pé ọdún mẹ́wàá tí Barrister kú; wo ǹkan tó yẹ láti mọ̀ nípa rẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi olórin, tẹ̀wé-tẹ̀wé, akọ̀wé àti sọ́jà
- Àìmọ̀kan ló mú mi hu ìwà tí mo hù kọjá sẹ́yìn, Jonathan dárí jì mí - Dino Melaye
Gẹgẹ bi ileesẹ ọlọpaa ti wi, adugbo Favours, lopopona Awolowo si Bodija nilu Ibadan ni awọn ọkunrin meji to wa lori ọkada ti sẹburu ọkọ Toyota Corolla rẹ, ti wọn si fi tipa gba foonu ati apo kan ti iwe wa ninu rẹ.
Amọ ẹnikan ti isẹlẹ naa soju rẹ ni owo to to miliọnu marun naira lo wa ninu apo naa, ti ọkunrin ọhun to jẹ olokoowo gbe lọwọ.
Atẹjade naa ni ni kete tawọn adigunjale naa sisẹ laabi ọhun tan, ni wọn fẹsẹ fẹ lori ọkada wọn amọ ti Adebayo atawọn araalu gba ya wọn pẹlu ọkọ rẹ titi to fi le wọn de adugbo dandaru.
Lojiji ni ọkada naa ja sinu koto nla kan, tawọn adigunjale naa si jabọ, bẹẹ ni ọkan ninu wọn dagbere faye loju ẹsẹ nigba ti ekeji fara gbọgbẹ, ti ara rẹ si bo falafala.
Atẹjade ileesẹ ọlọpaa naa ni, ni kete ti iroyin naa kan ọga ọlọpaa to wa ni agọ ọlọpaa Agodi lara lo morile ibi isẹlẹ naa amọ ko to de ibẹ, ẹpa ko boro mọ.
Idi ni pe awọn araalu tinu n bi, ti wọn le ni igba, ti dana sun adigunjale to fara gbọgbẹ naa, tawọn ọlọpaa si ti gbe ajoku rẹ lọ sile igbokusi.
Bakan naa ni ileesẹ ọlọpaa ni aayan ti n lọ lati tanna wadi isẹlẹ naa siwaju si.
Sugbọn isẹlẹ naa da sunkẹrẹ fakẹrẹ ọkọ silẹ ladugbo dandaru si Mokola, tawọn osisẹ Amotekun naa si bawọn peju sibi isẹlẹ ọhun, bẹẹ ni wọn n dari ọkọ lagbegbe naa pẹlu lati dena sunkẹrẹ fakẹrẹ.
Ṣé lóòtọ́ọ́ làwọn ọlọ́ṣà tún gbẹ̀mí èèyàn kan ní Moniya, Ibadan?
Awọn igara ọlọṣa ti yinbọn pa ọkunrin ọlọdẹ kan lagbegbe Mọniya nilu Ibadan.
Arakunrin naa ti awọn ọlọpaa pe orukọ rẹ ni Isau Yisah ni wọn sọ wi pe o n ṣe ṣọ ile epo kan lagbegbe naa lasiko ti awọn ọlọṣa fi ya bo adugbo naa lọjọ Abamẹta.
Gẹgẹ bi ohun ti awọn iroyin kan sọ, awọn ọlọdẹ agbegbe naa, ninu eyi ti Yisah wa doju kọ awọn ọlọṣa naa ki o to di pe awọn ọlọṣaa naa pa Yisah lagbegbe Asanmajana ti ileepo naa wa.
Ohun ti awọn eeyan kan n sọ lagbegbe naa ni pe boya oloogbe naa da awọn kan lara awọn ọlọṣa naa mọ ni wọn ṣe pa.
Ileeṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Ọyọ, la gbọ pe o ti fi idi iṣẹẹ idigun jale naa mulẹ ti wọn si ni iwadii ti bẹrẹ.
Gẹgẹ bi atẹjade kan ṣe sọ, wọn ti gbe oku arakunrin naa lọ sileewosan nla ijsba to wa lagbegbe Mọniya.
















