2020 in Retrospect: Abiola Ajimobi, Ibidunni Ighodalo, Buruji Kashamu wà lára àwọn tó bá ọdún yìí lọ

Si ọpọ ọmọ Naijiria, ọdun manigbagbe ni ọdun 2020 jẹ nitori awọn isẹlẹ kasiara to waye ninu ọdun naa.
Yatọ si eyi, ọpọ ẹmi lo sọnu ninu ọdun 2020, eyi ti ko yọ awọn olowo tabi talaka silẹ, koda, o kan ọba ilu ati ijoye pẹlu.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìtàn ìgbé ayé Isola Ogunsola, akọni mánigbàgbé òṣèré tíátà, olórin àti onílù
- Aráàlú dá iná sun èèyàn méjì n‘Ibadan, orí kó ẹni kan yọ
- "Ma a pa ara mi si Cute Abiola lọrun bo ṣe já mi silẹ tori afẹsọna miran"
- "Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àgbà fipá bá ọmọkùnrin mi lòpọ̀ níléèwé Deeper Life, mò ń fẹ́ ìdájọ́"
- Kí ló fa gbas-gbos láàrín Davido àti Burna boy lórílẹ̀èdè Ghana?
- Wo ọ̀pọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ igba tí Primate Ayodele gbé síta fọ́dún 2021
Nibayii ti ọdun 2020 ku ọjọ meji ko kogba wọle, ta si ki ọdun tuntun 2021 kaabọ, ẹ wo diẹ lara awọn eekan ilu ati ilumọọka ọmọ Naijiria to ba ogbologbo ọdun naa lọ.
Akojọpọ awọn ọmọ Kaarọ Oojire to ba ọdun 2020 lọ:
Abiola Ajimobi:

Oríṣun àwòrán, twitter/Ajimobi
Iku doro, iku ṣeka ni ariwo ti ọpọlọpọ ara ipinlẹ Oyo atawọn ọmọ Naijiria lapapọ mu bọnu nigba ti gomina ipinlẹ Oyo tẹlẹri, Abiola Ajimobi jade laye.
Ọjọ Kẹẹdọgbọn osu kẹfa ọdun 2020 si ni Akanji ‘ọmọ ọlọdun mẹjọ’ ki aye pe o digbose, Ajimobi si wa lara awọn eeyan jankan-jankan ti wọn tẹri gbaṣọ lọdun 2020.
Ile iwosan First Cardiology to wa ni Ikoyi niluu Eko ni Ajimobi dakẹ si nibi ti o ti n gba itọju nile iwosan.

Oríṣun àwòrán, Instagram/florenceajimobi
Ẹni ọdun aadọrin ọdun ni Ajimobi nigba to ki aye pe o digba o se.
Gomina Ajimobi jẹ gomina nipinlẹ Oyo laarin ọdun 2007 si ọdun 2019, ko to di wi pe wọn yan si ipọ alaga ẹgbẹ oṣelu APC ko to jade laye.
Ọdun 2020 yii ni ajakalẹ arun Cornavirus tan kalẹ kaakiri agbaye, ti ko si mọ olowo tabi talika, amọ o wọle were, o si mu awọn eniyan to gbajumọ lọ kaakiri agbaye, to fi mọ Abiola Ajimobi.
Sẹnetọ Buruji Kashamu:

Gbajugbaja oniṣowo ati oloṣelu ni Buruji Kashamu nigba aye rẹ, ki o to di oloogbe ni ọjọ Kẹjọ, oṣu Kẹjọ ọdun 2020.
Arun Coronavirus lo tun mu ọmọ bibi ipinlẹ Ogun naa lọ lẹni ọdun mejilelọgọta lẹyin ti arun Coronavirus ba a finran.
Ọkan gboogi ninu ọmọ ẹgbẹ oṣelu PDP ni Kashamu, to si ṣe sẹnetọ laarin ọdun 2015 si 2019.
Mama Abigail Makinde:

Oríṣun àwòrán, @Makinde
Mama Abigail Makinde ni iya gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde.
Iya naa jẹ Olorun nipe ni ẹni ọdun mọkanlelọgọrin pẹlu ọpọ ọmọ ati ọmọ-ọmọ to gbẹyin doloogbe naa.
Gomina Makinde ṣe apejuwe iya rẹ gẹgẹ bi iya rere, iya to ṣọwọn ti ko si ẹni to le dabi rẹ.
Ibidun Ighodalo:

Oríṣun àwòrán, Others
Iroyin iku Abilekọ Igbhodalo lo ba ọpọlọpọ ọmọ Naijiria lojiji, lẹyin to ki aye pe o digboṣe ni Ọjọ Kẹrinla, Oṣu Kẹfa, ọdun 2020 lẹni ọdun mọkandinlogoji.
Ipinlẹ Kaduna ni wọn ti bi Ibidunni Olajumoke Elizabeth Ituah Ighodalo ni ọdun 1980.
Ighodalo fẹ pasito ijọ Trinity House ni ọdun 2007, amọ ti ko si bimọ fun ọpọlọpọ ọdun ki o to di wi pe iroyin kan so wi pe , o gba awọn ọmọ meji tọ.
Ọmọọba Dapọ Ọjọra:

Oríṣun àwòrán, Twitter/bukaola saraki
Ni alẹ ọjọ Ẹti, ọjọ Kọkanla osu Kejila ọdun 20202 ni iroyin jade sigboro pe, ilumọọka ọmọ jayejaye ilu Eko nni, Dapọ Ọjọra ti jade laye.
Yatọ si pe ẹni ọdun mejidinlọgọta ni ko to jade laye, ohun to n ṣe ọpọ eeyan ni haa-hin bayii ni iru iku to gbẹmi rẹ.
Dapọ jẹ ọkan lara awọn ọmọ gbajugbaja oniṣowo nni, Otunba Kunle Ojọra; oun si tun ni ẹgbọnToyin Saraki, to jẹ iyawo aarẹ ile aṣofin agba tẹlẹ, Sẹnetọ Bukọla Saraki.
Bi o tilẹ jẹ wi pe ọpọ lo n sọ kiri pe, Dapọ ṣeku pa ara rẹ ni, sibẹ Sẹnetọ Saraki ti sọrọ sita pe awọn agbofinro ti bẹrẹ iwadii lori rẹ.
Lara awọn ọmọ Yoruba jankan-jankan miran to tun ba ọdun 2020 naa lọ ni Oloye Harry Makinde, Abayomi Jolaoso, Gbolabo Ogunsanwo ati Richard Akinjide.
Amọ, awọn eeyan jankan-jankan ti kii ṣe Yoruba, amọ ti wọn jẹ ilumọọka lorilẹede Naijiria naa ni yii.
Akojọpọ awọn Naijiria mii to ba ọdun 2020 lọ:
Abba Kyari:

Oríṣun àwòrán, others
Ọjọ Ẹti, Ọjọ Kẹtadinlogun, Oṣu Kẹrin, ọdun 2020 ni Abba Kyari d'oloogbe ni ipinlẹ Eko lẹyin ọsẹ diẹ toni aarun coronavirus.
Ọkan pataki ninu ijọba Aarẹ Buhari ni Kyari, ti o si tun jẹ ọrẹ timọtimọ si Aarẹ Buhari.
Oun lo di ipo adari oṣiṣẹ aarẹ Buhari mu, ki o to di wi pe o doloogbe lẹni ọdun mẹtadinlaadọrin.
Awọn eniyan jankan-jankan miran to jade laye lọdun 2020 ni ọgagun Emmanuel Nworah, Paul Efemini Poli (aka Decure), Sẹnatọ Saidu Umar ati Minisita tẹlẹri, Kumo Tonye Graham-Douglas.

















