Alaafin Palace Lamidi Adeyemi: Wo àwọn obìnrin mẹ́wàá tí ipa wọn kò ṣe fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn ní ààfin Oyo

Oríṣun àwòrán, Alaafin oyo
Ní ilẹ̀ Adúláwọ̀, àwọn kan gbàgbọ́ wí pé àwọn obìnrin kò ní ojúṣe kan gbòógì tí wọ́n dì mú nínú àwùjọ yàtọ̀ sí jíjẹ́ ìyàwó ilé lásán, dáná àti títọ́jú ọmọ.
Ṣé báyìí ni ọ̀rọ̀ ṣe rí ní àwùjọ Yorùbá nítorí àwọn àṣamọ̀ kan pé ìyàrá ìdànà ni gbogbo ẹ̀kọ́ tí ọmọ obìnrin bá ní máa ń parí sí.
Ní Oyo Aláàfin òjò pa ṣẹ̀kẹ̀rẹ̀ ọmọ Àtìbà, àwọn obìnrin mẹ́wàá ló ní ojúṣe pàtàkì tí wọ́n ń kó nínú ààfin.
- 'Ètò ayẹ́yẹ́ ìsìnkú Oba Lamidi Adeyemi kòí tíì wáyé, àfọ̀mọ́ Aàfin ń lọ lọ́wọ́'
- Mọ̀ síi nípa Olorì Abibat Nihinlola Adeyemi tó ti lo ọdún 60 gẹ́gẹ́ bíi olorì láàfin Alaafin Oyo
- Mo ti gbà báyìí pé ohun gbogbo tó n dán kọ́ ni wúrà - Olori Badirat Adeyemi
- Wo ohun tó yẹ kó mọ nípa Baràá ibùgbé ìkẹyìn Aláàfin Olayiwola Adeyemi
- Irú ẹ̀dá wo ni Lamidi Adeyemi? Aláàfin tó rí ìbẹ̀rẹ̀ àti opin sáà gómìnà mọ́kànlélógún l‘Oyo
- Wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn olòrì Alaafin Adeyemi àtàwọn tó bá fẹ́ fẹ́ wọn
- "Kòríkòsùn lèmi àti Alaafin ṣùgbọ́n kété táwọn kan kẹ́ẹ́fín pé èmi láàyò ni gbogbo nǹkan dojúrú." Badirat Ajoke, olorì tẹ́lẹ̀ kẹ́dùn Alaafin
- Wo àwọn òrékelẹ́wà tí yóò ṣe opó lẹ́yìn Aláàfin Oba Adeyemi tó papòdà
Àwọn obìnrin náà nìyí:
Iyamode: Ẹnikẹ́ni tó bá wà ní ipò yìí nìkan ni àṣà Yorùbá fi àyè gbà pé kí Aláàfin ìlú Oyo kúnlẹ̀ fún. Ipò náà jẹ́ èyí tí wọ́n bọ̀wọ̀ fún púpọ̀ ní ìlú Oyo tó fi jẹ́ pé Bàba ni Aláàfin máa ń pè é.
Tí Aláàfin bá ti ń lọlẹ̀ láti kúnlẹ̀ fún Aláàfin náà ni obìnrin yìí náà ni òun náà yóò fi ìkúnlẹ̀ pàdé Aláàfin tí ìyá yìí kò sì fi ọwọ́ rẹ̀ lélẹ̀ nítorí èyí jẹ́ àmì bí àwọn obìnrin ṣe máa ń bọ̀wọ̀ fún ẹni tí ó bá jùwọ́n lọ.
Ní kété tí obìnrin bá ti jẹ Iyamode, kò gbọdọ̀ ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin kankan mọ́ títí yóò fi jáde láyé, òun sì ni àgbà fún gbogbo àwọn obìnrin tó bá wà láàfin tí wọn kò lẹ́tọ̀ọ́ láti máa ní ìbálòpọ̀.
Bákan náà ló jẹ́ ọ̀kan lára àgbà àwọn obìnrin tó jẹ́ aláwo nínú ààfin Oyo.
Ọbaguntẹ: Òun ni ó máa ń ṣojú Aláàfin níbi ètò àwọn Ògbóni. Obìrin tó bá wà ní ipò yìí ní ẹ̀tọ́ sí gbogbo ètò tí àwọn Ológbàni bá ń ṣe tó sì lè wọ yẹ̀wù wọn nígbàkúgbà.
Ẹni Ọja: Òun ni olórí àwọn tó ń bọ Èṣù, òun sì ló wà ní ìkápá ọjà Ọba.
Iya Naso: Aláàfin Oyo ni ìgbàgbọ́ wà pé ó jẹ́ aṣojú Sango ní ilẹ̀ Yorùbá. Ní ààfin Oyo, ibì kan wà tó jẹ́ pé Aláàfin máa ń bọ Sango níbẹ̀, Iya Naso ló wà ní àkóso yàrá yìí.
Bákan náà ló wà ní ìdí àmójútó gbogbo ohun tó ní ṣe pẹ̀lú bíbọ Sango àti ètò rẹ̀ gbogbo.
- Wọ́n ti ṣe ìsìnkú àpapọ̀ fún èèyàn 50 lára àwọn tó jóná níbúdò ìfọpo tó gbiná ní Imo
- Èsì àyẹ̀wò ohun tó ṣekú pa gbajúmọ̀ akọrin ẹ̀mí, Osinachi Nwachukwu ti jáde
- Àwọn ológun pa ikọ̀ Boko Haram ogún, wọ́n dóòlà àwọn obìnrin tó wà ní ìgbèkùn
- Èèyàn bí méjì kú, ọ̀pọ̀ farapa lásìkò tí àwọn afurasí ọmọ Auxiliary àti Isota kọlu ara wọn ní Ibadan
- Gomina Yahaya Bello ra fọ́ọ̀mù N100m láti gba iṣẹ́ lọ́wọ́ Ààrẹ Buhari
- Lukman gbẹ̀yín ẹbí lọ bẹ́ orí ìkókó ti wọ́n sìn ní Abeokuta, àṣírí tú bó ṣe fẹ́ tàá
- Óṣe! Àwọn ọmọdé mẹ́rin pàdánù ẹ̀mí wọn bí wáyà iná ṣe já lé wọn lórí
Iya Kere: Ìyá Kere ló máa ń gbé adé sí orí Aláàfin ní ọjọ́ tí wọ́n bá ń ṣe ìwúyè. Òun ló wà nídìí àkóso gbogbo àwọn ohun ọ̀ṣọ́ ìlú Oyo tó fi mọ́ àwọn adé.
Iya Kere ni olórí gbogbo àwọn Ilari inú ààfin, tó sì tún ní agbára lórí àwọn ìlú tó wà ní abẹ́ Oyo bíi Aseyin, Oluwo àti Soun ti ìlú Ogbomoso.
Ẹnikẹ́ni tó bá ti jẹ Iya Kere kìí súnmọ́ ọkùnrin mọ́ títí láé.
Iya Ọba: Ẹni tó bá bí Ọba ló máa ń wà ní ipò yìí àmọ́ tí Ọba kò bá ní ìyá mọ́ láyé, wọ́n á yan ẹnìkan nínú àwọn àgbà obìnrin ilé láti gba ipò náà.
Ìyá Ọba ló máa ń ṣe ẹnì kẹta Aláàfin àti Basorun nínú yàrá nígbà tí wọ́n bá ń ṣọdún Orun nínú oṣù Kẹsàn-án ọdọọdún. Iya Ọba ni olórí fún Basorun.
Iya Monari: Iṣẹ́ Iya Monari ni láti yí ẹni tó bá ń bọ Sango tí wọ́n wá dájọ́ ikú fún lọ́rùn pa nítorí wọ́n kìí fi idà pa ẹni tí Sango bá dájọ́ ikú fún.
Bákan náà ló jẹ́ igbákejì Iya Naso.
- Òrumọ́jú ní ara Oba Lamidi Adeyemi wọ káà ilẹ̀ lọ ní Báárà gẹ́gẹ́ bí ìṣe ìran Yorùbá ṣe làá kalẹ̀
- 'Aláàfin ti rí ikú rẹ̀ ṣáájú ọjọ́ tó wàjà, ó sọ̀rọ̀ sílẹ̀ kó tó kú'
- Wo Alàáfin 43 tó jẹ́ láti ìgbà ìwásẹ̀ ṣáajú Lamidi Adeyemi tó ṣẹ̀ṣẹ̀ wàjà
- Àṣírí ńlá tó ń bẹ láàrín Alaafin àtàwọn onílù rẹ̀ rèé
- Nínú àwòràn, wo ìgbà ayé Aláafin Oyo, Ọba Lamidi Adeyemi kẹta tó lọ bá àwọn Baba Ńlá rẹ̀
- Ta ni Yorùbá ń pè ní Abọ́bakú?
- Aláàfin àti Ọba ilẹ̀ Yorùbá márùn-ún mìí tó wàjà láàrin oṣù márùn-ùn péré
Iya-Fin-Iku: Ìṣe àwọn Oníṣàǹgó ni láti máa fi ẹnìkan jìn sí bíbọ Sango, ipa yìí sì ni Iya-Fin-Iku máa ń kó fún Aláàfin.
Òun náà ló wà ní àkóso àgbò tí wọ́n fi ń bọ Sango.
Iya Lagbo: Ẹni tó bá jẹ ìyá Àrẹ̀mọ ló máa ń wà ní ipò yìí ṣùgbọ́n tí ìyá Àrẹ̀mọ bá ti papòdà, obìnrin olorì mìíràn yóò gba ipò náà.
Iya Lagbo máa ń ṣàkóso apá kan ní ààfin tó sì máa ń wà ní ìṣàkóso gbogbo àgbo àti àgúnmu gbogbo àwọn ènìyàn tó wà ní ààfin tó fi mọ́ Aláàfin.
Aarẹ Oriitẹ: Òun ló jẹ́ olùrànlọ́wọ́ pàtàkì sí Aláàfi, tó máa ń ṣe àkóso gbogbo oúnjẹ àti ibùsùn Aláàfin. Ṣe ìtọ́jú gbogbo àyíká, tó sì máa ń gbé agbòrùn lórí àwọn aláàfin tó bá ṣẹ̀ṣẹ̀ jẹ.
Gbogbo àwọn obìnrin mẹ́wẹ́ẹ̀wá yìí ló máa ń rọgba ká Aláàfin láti ri pé kò ṣi ẹsẹ̀ gbé.
- Ẹ dáríjìn mí ọmọdé ló ń ṣe mí, mo kábàmọ́ ìwà tí mo wú - Akẹ́kọ̀ọ́ Chrisland Schools
- Àwọn ènìyàn Nàìjíríà fi ìdùnnú hàn bí ìjọba ṣe ṣí àwọn ibodè mẹ́rin mìíràn
- Twitter ti gbà láti ta ojú òpó nàá ní $40bn fún Elon Musk, ọkùnrin tó lówó jù ní ayé
- Ìyànjẹ ni fún ọmọ Naijiria tí mo bá fẹ̀yìntì báyìí- Osinbajo
- Wo àwọn ǹkan tí o kò mọ̀ nípa Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò tó wàjà
- Ààrẹ Buhari, Ooni Ile Ife, Obasanjo kẹ́dùn Alaafin Oyo tó wàjà



















