Power Cable Kills Children in Ondo: Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ní àwọn ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ondo ti ní àwọn ọmọdé mẹ́rin ló bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìjàmbá wáyà iná tó já lé àwọn ọmọ náà lórí ní Ilé Oluji, ìjọba ìbílẹ̀ Okeigbo, ìpínlẹ̀ Ondo.
Agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ondo, Funmilayo Odunlami, ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ Karùndínlọ́gbọ̀n, oṣù kẹrin ọdún 2022 sọ pé àwọn ọmọdé náà ṣe kòńgẹ́ ọlọ́jọ́ wọn nígbà tí wáyà iná ọba já lé ṣọ́ọ̀bù tí wọ́n fi irin ṣe kan èyí tí àwọn ọmọ náà wà.
Odunlami ṣàlàyé pé àwọn méjì nínú àwọn ọmọ mẹ́rin tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ ló jẹ́ ọmọ ìyá kan náà tó lọ sí ìlú náà fún ìsinmi ọdún àjíǹde.
- Ẹ dáríjìn mí ọmọdé ló ń ṣe mí, mo kábàmọ́ ìwà tí mo wú - Akẹ́kọ̀ọ́ Chrisland Schools
- Àwọn ènìyàn Nàìjíríà fi ìdùnnú hàn bí ìjọba ṣe ṣí àwọn ibodè mẹ́rin mìíràn
- Ìyànjẹ ni fún ọmọ Naijiria tí mi ò bá fẹ̀hìntì báyìí- Osinbajo
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá sọ nípa ikú Baálẹ̀ àti èèyàn méjì tó kú l'Ondo táwọn ọ̀dọ́ ń so ikú wọn mọ́ agbófinró lọ́rùn
- Ọ̀pọ̀ ènìyàn pàdánù ẹ̀mí wọn bí ilé ìfọpo ṣe bú gbàmù
- Njẹ́ o mọ̀ pé láàrín ìṣẹ́jú méjì, ọmọdé kan ń kú nítorí àìsàn ibà??
- Okùnrin tó so àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ mọ́lẹ̀ bíi ewúrẹ́, tó sì nà wọ́n rí ẹ̀wọ̀n ogún ọdún he
Ó fi kun pé àwọn ọmọ mẹ́fà ló ń ṣeré nínú ṣọ́ọ̀bù náà kí wáyà iná ọba tó já lulẹ̀ tí àwọn mẹ́rin sì bá ìsẹ̀lẹ̀ náà lọ nítorí kò sí afẹ́fẹ́ èémí tí wọn yóò ló fún wọn ní ilé ìwòsàn tí wọ́n gbé wọn lọ.
Ó sọ síwájú pé ọ̀kan nínú àwọn ọmọ méjì tó kù ni ara rẹ̀ ti balẹ̀ lẹ́yìn tó gba ìtọ́jú ní Trauma Centre tó sì ti padà sí ilé, tí ọ̀kan yòókù sì wà ní ilé ìwòsàn O.A.U níbi tó ti ń gba ìtọ́jú lọ́wọ́.
Odunlami ni àwọn ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.
- Wo ohun tó yẹ kó mọ nípa Baràá ibùgbé ìkẹyìn Aláàfin Olayiwola Adeyemi
- Irú ẹ̀dá wo ni Lamidi Adeyemi? Aláàfin tó rí ìbẹ̀rẹ̀ àti opin sáà gómìnà mọ́kànlélógún l‘Oyo
- Wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn olòrì Alaafin Adeyemi àtàwọn tó bá fẹ́ fẹ́ wọn
- "Kòríkòsùn lèmi àti Alaafin ṣùgbọ́n kété táwọn kan kẹ́ẹ́fín pé èmi láàyò ni gbogbo nǹkan dojúrú." Badirat Ajoke, olorì tẹ́lẹ̀ kẹ́dùn Alaafin
- Wo àwọn òrékelẹ́wà tí yóò ṣe opó lẹ́yìn Aláàfin Oba Adeyemi tó papòdà
- Wo Alàáfin 43 tó jẹ́ láti ìgbà ìwásẹ̀ ṣáajú Lamidi Adeyemi tó ṣẹ̀ṣẹ̀ wàjà
- 'Aláàfin ti rí ikú rẹ̀ ṣáájú ọjọ́ tó wàjà, ó sọ̀rọ̀ sílẹ̀ kó tó kú'
- Òrumọ́jú ní ara Oba Lamidi Adeyemi wọ káà ilẹ̀ lọ ní Báárà gẹ́gẹ́ bí ìṣe ìran Yorùbá ṣe làá kalẹ̀
Àwọn ènìyàn korò ojú sí kíkọ́ ilé sábẹ́ wáyà iná
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà, Sẹ́nétọ̀ tó ń ṣojú ẹkùn gúùsù Ondo ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àpapọ̀ ní Abuja, Nicholas Tofowomo ni òun yóò ṣe àrídájú rẹ̀ wí pé àwọn òbí ọmọ tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ náà lọ láti rí ìdájọ́ òdodo gbà tí ilé iṣẹ́ tó ń pín iná mọ̀nàmọ̀nà Benin bá lọ́wọ́ nínú ìṣẹ̀lẹ̀ náà.
Tofowomo rọ àwọn ènìyàn láti yé kọ́ ilé tàbí ṣọ́ọ̀bù sábẹ́ àwọn wáyà iná èyí tó le ṣe àkóbá fún wọn.
- Àṣírí ńlá tó ń bẹ láàrín Alaafin àtàwọn onílù rẹ̀ rèé
- Aláàfin àti Ọba ilẹ̀ Yorùbá márùn-ún mìí tó wàjà láàrin oṣù márùn-ùn péré
- Nínú àwòràn, wo ìgbà ayé Aláafin Oyo, Ọba Lamidi Adeyemi kẹta tó lọ bá àwọn Baba Ńlá rẹ̀
- Ààrẹ Buhari, Ooni Ile Ife, Obasanjo kẹ́dùn Alaafin Oyo tó wàjà
- Ta ni Yorùbá ń pè ní Abọ́bakú?
- Kéte ti Baba dákẹ́ ni àṣà àti ìṣẹ̀ṣe ti bẹ̀rẹ̀ l'Áàfin - Ẹ wo ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ní Aafin Oyo
- Wo àwọn ǹkan tí o kò mọ̀ nípa Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò tó wàjà
Ohun tó ṣẹlẹ̀ náà dùn wá púpọ̀ - ilé iṣẹ́ tó ń pín iná mọ̀nàmọ́ná
Ọ̀gá àgbà ilé iṣẹ́ tó ń pín iná mọ̀nàmọ́ná tẹ̀ka ìpínlẹ̀ Ondo, Micheal Barnabas ní ìdí tí ìjàmbá náà ni pé abẹ́ wáyà iná tó lágbára ni àwọn ṣọ́ọ̀bù náà wà.
Barnabas ní ó jẹ́ ohun tó bani lọ́kàn jẹ́ wí pé àwọn ògo wẹẹrẹ ni ìṣẹ̀lẹ̀ náà ṣẹlẹ̀ sí tó sì ṣeni láàánú.
Ó fi kun wí pé àwọn kò ní àṣẹ láti lé ẹnikẹ́ni tó bá kọ́lé tàbí tàbí ní ilé ìtajà lábẹ́ àwọn wáyà iná kúrò.
Ó sọ síwájú wí pé ohun tí àwọn yóò máa ṣe báyìí ni láti ri pé àwọn kò fún ilé tàbí ṣọ́ọ̀bù tí wọ́n bá kọ́ sábẹ́ àwọn wáyà ní iná láti fi hàn wọ́n wí pé ohun tí wọ́n ń ṣe kò dára.
- Àjọ NDLEA nawọ́ gán ọkùnrin tó lọ́wọ́ nípa ẹ̀sùn N3bn egbògi Tramadol tí Abba Kyari ń kojú
- 'Mo dáríji ẹni tó pa mí lọ́kọ́, mò sì gbà kí àwọn ọmọ wa fẹ́ ara wọn'
- Adájọ́ sún ìgbẹ́jọ́ síwájú lẹ́yìn tí afurasí kan tó lọ́wọ́ nínú ikú Timothy Adegoke ṣubú nílé ẹjọ́
- Wo bí àwọn Alfa ṣe kírun sí Aláàfin lára àti ètò tó kàn láti gbé e wọ káà ilẹ̀
















