Osinbajo 2023: Ìyànjẹ ni fún ọmọ Naijiria tí mo bá fẹ̀yìntì báyìí- Osinbajo

Oríṣun àwòrán, @Yemi Osinbajo
Igbakeji aarẹ, Yemi Osinbajo ti sọ pe iwa ọdalẹ ati iyanjẹ ni yoo jẹ, ti oun ba fi kọ̀ lati dije fun ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023.
Awọn iwe iroyin abẹle sọ pe igbakeji aarẹ sọ ọrọ naa lasiko to bẹ gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu, ati awọn agba ẹgbẹ osẹlu APC wo nilu akurẹ, lọjọ Aje.
Nibẹ ni Osinbajo ti sọ erongba rẹ fun wọn pe, oun fẹ atilẹyin wọn fun ipo aarẹ.

Oríṣun àwòrán, laolu akande
Ọjọgbọn Osinbajo sọ pe oun ko fẹ ki anfaani na fo oun ru, ati pe o jẹ oore-ọfẹ lati sin ilu.
- Àjọ NDLEA nawọ́ gán ọkùnrin tó lọ́wọ́ nípa ẹ̀sùn N3bn egbògi Tramadol tí Abba Kyari ń kojú
- Adájọ́ sún ìgbẹ́jọ́ síwájú lẹ́yìn tí afurasí kan tó lọ́wọ́ nínú ikú Timothy Adegoke ṣubú nílé ẹjọ́
- Èyí lohun tí Aisha Buhari sọ fáwọn olùdíje dupò ààrẹ ní Nàìjíríà níbi àpèjẹ ìṣínu Iftah tó pè
- Irú ẹ̀dá wo ni Lamidi Adeyemi? Aláàfin tó rí ìbẹ̀rẹ̀ àti opin sáà gómìnà mọ́kànlélógún l‘Oyo
- Àwọn olùdíje sípò Ààrẹ lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP túká, ìmọ̀ràn wọn ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá sọ nípa ikú Baálẹ̀ àti èèyàn méjì tó kú l'Ondo táwọn ọ̀dọ́ ń so ikú wọn mọ́ agbófinró lọ́rùn
"Mo pinnu lati dije fun ipo aarẹ, nitori iriri ti mo ni gẹgẹ bi adele aarẹ fun oṣu meje, iṣẹ kekere kọ ni mo ṣe nigba naa."
"Ni bayii ti anfaani ṣi silẹ fun mi, ati awọn eeyan ti mo mọ kakiri agbaye, iwa ọdalẹ ni yoo jẹ́ fun Naijiria, ti mo ba kọ lati sin orilẹ-ede yii."
Osinbajo sọ pe ojoojumọ ni awọn eeyan n fi ẹmi wọn lelẹ fun Naijiria, nitoyi naa ni ko ṣe bojumu fun oun lati fẹhinti bayii fun igbadun, lai dupo aarẹ.
Lowurọ ọjọ Aje, ọjọ kọkanla ọdun 2022, ni igbakeji aarẹ Naijiria, Ọjọgbọn Yemi Osinbajo kede erongba rẹ lati dije fun ipo aarẹ, fun gbogbo aye.
Awọn oloṣelu wo lo ti fi erongba ati dije ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023 han?
Bola Ahmed Tinubu:
Bọla Tinubu jẹ ọkan lara awọn eekan ẹgbẹ oṣelu APC, ohun si ni gomina ipinlẹ Eko laarin ọdun 199 si 2007.
- Wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn olòrì Alaafin Adeyemi àtàwọn tó bá fẹ́ fẹ́ wọn
- "Kòríkòsùn lèmi àti Alaafin ṣùgbọ́n kété táwọn kan kẹ́ẹ́fín pé èmi láàyò ni gbogbo nǹkan dojúrú." Badirat Ajoke, olorì tẹ́lẹ̀ kẹ́dùn Alaafin
- Njẹ́ o mọ̀ pé láàrín ìṣẹ́jú méjì, ọmọdé kan ń kú nítorí àìsàn ibà??
- Àjọ NDLEA nawọ́ gán ọkùnrin tó lọ́wọ́ nípa ẹ̀sùn N3bn egbògi Tramadol tí Abba Kyari ń kojú
Rochas Okorocha:
Okorocha ni gomina ipinlẹ Imo tẹlẹ, igba akọkọ rẹ si kọ niyi lati dije, lẹyin to ti kọkọ gbe igba ibo fun ipo aarẹ labẹ ẹgbẹ oṣelu AA nigba kan ri.
Rochas Okorocha fi erongba rẹ lati dije han ninu lẹta kan to kọ ranṣẹ si aarẹ ile aṣofin agba, Sẹnetọ Ahmad Lawan lọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu kini ọdun 2022.
Khadija Okunnu -Lamidi:
Oun ni obinrin akọkọ to jade lati kede pe oun fẹ dije fun ipo aarẹ lọdun 2023. Ko tii kede ẹgbẹ oṣelu kankan ti o wa bayii na. Ohun to sọ ni pe ẹgbẹ oṣelu to ba ni iran kan naa pẹlu oun loun yoo ba lọ.
Dele Momodu:
loṣu kẹta ọdun 2023 ni Dele Mọmọdu kede pe oun naa yoo dije ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu PDP.
Igba akọkọ kọ niyi ti Dele Mọmọdu yoo maa fifẹhan si didije fun ipo aarẹ ni Naijiria.
- Wo àwọn gbajúmọ̀ òṣèré Yorùbá tí kìí ṣe ọmọ káàárọ̀ oòjíire
- Ǹjẹ́ o mọ àwọn òṣèré bí Oyin Adejọbi, Funmi Martins àtàwọn míì tó ti dágbére fáyé?
- Ìtàn ìgbé ayé Isola Ogunsola 'I-sho Pepper', ògbóǹtagí òṣèré tíátà tó s'eré Yorùbá yíká Nàìjíríà
- Kí ló wà ní ìdí igbá tí àwọn olorì Aláàfin máa ń tí lóde Ọ̀yọ̀
- Ìjà Awolowo, Akintola àti ogun 'Wẹtiẹ', ẹ̀kọ́ wo ló kọ́ wa?
- Igbo Olodumare rèé, níbi tí Ìgbín ti tóbi ju Ìjàpá lọ
- Ìdílé márùn-ún tó gbajúmọ̀ fún òwò ẹrú nílẹ̀ Yorùbá
Yahaya Bello:
Yahaya Bello ni gomina ipinlẹ Kogi lọwọ yii. Laipẹ yii loun pẹlu kede pe oun naa nifẹ si ipo aarẹ lọdun 2023.
Awọn miran to tun ti gbe igbesẹ yii kan naa ni aarẹ ile aṣofin agba tẹlẹ ri, Dokita Bukọla Saraki, alaga igbimọ awọn gomina lorilẹede Naijiria, NGF to tun jẹ gomina ipinlẹ Ekiti, Ọmọwe Kayọde Fayẹmi, minisita fọrọ oṣiṣẹ ati igbanisiṣẹ, Dokita Chris Ngige ati bẹẹ lọ.

















