Farmers-Herders Crisis: Ohun ìbànújẹ́ ló sẹlẹ̀ ní Igangan, ìjọba, ẹ dìde bí o ti yẹ- Oba Lamidi Adeyemi

Oríṣun àwòrán, Others
Alaafin ti Oyo, Oba Lamidi Adeyemi ti banujẹ́ gidi lori isele isekupani to waye ni ilu Igangan ni ijoba ibile Ariwa Ibarapa ni ipinle Oyo to wa ni guusu Iwo oorun Naijiria.
Laaro ọjọ Aiku ni iroyin ibanuje naa gba igboro kan pe awọn agbebọn kọlu Igangan nibi ti wọn ti sun ọpọlọpọ ile nina ti wọn si pa awọn mii.
Koda, wọn sun aafin Oba Ashi ti ilu Igangan.
Bode Durojaye to jẹ adari ẹka eto ifitonileti fun Aafin Oba Lamidi Adeyemi lo fi atẹjade naa sita.
O ni Kabiesi ni asiko ti to ki ijọba koowa gbajumọ ọna abayọ si i soro eto aaabo yii lẹyẹ o sọka.
Bakan naa lo banuje lori ipo ti ọrọ ẹlẹyamẹya de duro ni Naijiria ni eyi to yẹ ko jẹ agbara orilẹ-ede yii sugbọn ti ko ri bẹẹ.
Aalfin Oyo gba awọn ẹsọ alaabo lati samulo awon ara ilu ati ọpọlọ pipe awọn iolugbe ileto kọọkan.
Oba Lamidi Adeyemi ni pe laisi eto aabo to mọyan lori, ko le si idagbasoke kankan paapaa ninu eto ọrọ aje.
Kabiesi ni ki ijọba ni ẹka ksskan gbe igbesẹ to kan lati daabo bo awọn ara ilu to n se ijọba le lori.
Àgbẹ̀ míì tún fara gbọgbẹ́ ìbọn ní Igangan láti ọwọ́ afurasí darandaran
Iroyin to n tẹ wa lọwọ ni agbẹ miran tun ti fara gba ọgbẹ ọta ibọn nilu Idiyan, lẹba ilu Igangan, lagbegbe Ibarapa nipinlẹ Oyo, lati ọwọ afurasi Darandaran.
Gẹgẹ bi iwe iroyin Punch ti salaye, ọkunrin kan tii se ara orilẹede Benin, Kaptain Kaston ni afurasi darandaran yinbọn mọ lẹba oko rẹ.
Ọkunrin agbẹ naa, tii se ẹni ọdun mejidinlọgbọn, ti wọn yinbọn mọ ni ejika, ni wọn tun sa ni oniruuru ọgbẹ ni gbogbo ara.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Gbogbo ǹkan tí à ń ṣe láti jà fún ''Yoruba Nation'', ìjà àwọn bàbá wa là ń gbé - Sunday Igboho
- Ìjọba ẹ ṣọ́ra! gbígbégilé ojú òpó Twitter tako ẹ̀tọ́ àwọn ọmọ Naijiria - Gómínà Ṣeyi Makinde
- Ìwádìí tí bẹ̀rẹ̀ lẹ́yìn tí Olùkọ́ lu akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ ọdún mẹ́sàn án pa
- Ìjọba àpapọ̀ kéde ìjìyà fún àwọn tó ṣì n lo Twitter ní Naijiria
- Mọ̀ si i nípa ìtàn eégún Gelede àti pàtàkì eégún náà sí àwọn obìnrin nílẹ̀ Yoruba
- Wo àwọn nkán tó ṣẹlẹ̀ níbi ìwọ́de Yoruba Nation tó ti wáyé sẹ́yìn
Ariwo Kaston to n pa pẹlu irora, ni awọn ero ọna to n kọja lọ gbọ, ti wọn si sare gbe digba digba rele iwosan.
Nigba to n fidi isẹlẹ naa mulẹ, oludasilẹ eto idagbasoke fun ilu Igangan, Oladiran Oladokun salaye pe ọjọ Ẹti ni isẹlẹ naa waye.
"Awọn afurasi ọdaran mẹta lo kọlu oloogbe naa lẹba oko rẹ ladugbo Abojukopo nilu Idiyan, ti wọn si sọ fun pe ko gbọdọ kede pe Fulani lo kọlu oun."
Bakan naa ni aburo ọkunrin naa, Pascal Kaston naa ni wọn ti fi isẹlẹ naa to awọn ọlọpaa leti, ti wọn si ti wa sibi isẹlẹ naa lọjọ Ẹti.
"Wọn yinbọn mọ, ti wọn si tun fi ada ṣa. Wọn ko ge ọwọ rẹ amọ ọpọ ọgbẹ wa ni ọwọ rẹ.
O laju nile iwosan laarọ oni, ti ara rẹ si ti n ya diẹdiẹ.

Àwọn agbébọn fi ìbọn fọ́ ẹnìkan l'étí, wọ́n tún jí oníṣòwò kan gbé lọ

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn eeyan ijọba ibilẹ Dambatta nipinlẹ Kano ti fidirẹmulẹ pe awọn afurasi agbebọn kọlu wọn , ti wọn si gbe ọkunrin oniṣowo kan lọ.
Awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn sọ pe ni nkan bi aago mẹwa aabọ owurọ ni Ọjọbọ ni ilu Kore, to wa ni ijọba ibilẹ naa, ni awọn agbebọn naa wọle, ti wọn si n yinbọn.
Wọn ni ibọn naa ba obinrin kan ati ọmọ rẹ.
Bakan naa ni wọn sọ pe eeyan mẹfa ni wọn tu kọlu .
Botilẹ jẹ pe ko si ẹni to ku, iroyin sọ pe ibọn ba ọmọ kekere kan ni eti.
- Wo ìdí tí àgbẹ̀ kan, Muhammad fi da májèlé sínú kànga mẹ́sàn án tí àwọn èèyàn ń mu
- 'Mo bá òkú Blessing tí wọ́n so ọwọ́ ẹ̀ sẹ́yìn pẹ̀lú ìwé pélébé tí wọ́n kọ pé ...'
- Ẹ gbé ìbọn fún àwọn ọmọ àjọ FRSC- Emir Ilorin
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ṣàwárí ibi tí wọ́n ti ń rọ ìbọn AK-47 lábẹ́lé ní Jos
- Nàìjíríà ti di orílẹ̀èdè tó ń ṣàn fún ìbànújẹ́ àti ìpayínkeke- Obasanjo
Awọn olugbe ilu naa sọ pe ko si oṣiṣẹ alaabo kankan to wa ni arọwọto lati doola wọn lasiko ti awọn agbebọn n ṣiṣẹ ọwọ wọn.
Wọn sọ pe ọpọ eeyan ni ẹru ba, ti awọn kan si sa wọ inu igbo lọ.
Alaga ijọba ibilẹ Dambatta, Muhammad Abdullahi Kore sọ pe lootọ ni iṣẹlẹ naa waye, to si sọ pe Emmanuel ni orukọ ẹni ti wọn ji gbe ọhun.
O ni oniṣowo ni ọkunrin naa ni ilu Kore.
Ninu iroyin mii, inu ibanujẹ ati ọfọ ni awọn eniyan ilu Magami ati Mayabaya ni ijọba ibilẹ Gusau nipinlẹ Zamfara wa, lẹyin ti awọn agbebọn kọlu wọn.
Ọjọru ni wọn sọ pe awọn agbebọn naa pa eeyan mẹtadinlogun, ati awọn agbẹ, ko to di pe wọn ko awọn ẹran ọsin wọn lọ.
Ninu oko ni awọn agbẹ naa wa nibi ti wọn ti n ṣiṣẹ, ki ikọlu naa to waye.
Ẹnikan ti ori ko yọ ninu ikọlu naa, amọ ti ko fẹ ki a darukọ rẹ sọ pe awọn ti sin oku eeyan mẹsan-an lara wọn.
Gbogbo igbiyanju BBC lati ba agbẹnusọ ọlọpaa ni ipinlẹ Zamfara sọrọ lo ja si pabo.
- Ilé aṣòfin Naijiria buwọ́lu òfin tí yóò fi òpin sí ìdẹ́yẹsí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tó ní ìwé ẹ̀rí HND
- Àjọ NYSC kò gbèrò rírán àwọn àgùnbánirọ̀ lọ sójú ogun- Àjọ NYSC
- Makinde ṣàfikún owó oṣù àwọn àgùnbánirọ̀ ìpinlẹ Ọyọ láti ẹgbẹ̀rún márùn ún sí ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀dógún náírà
- Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa bí 'twitter' tíjọba dá dúró ní Nàijíríà yóò ṣe kan ọ
- À ń ṣe ara wa ni Bí a bá kọ̀ láti máa lo egbòogi igbó ní Naijiria - Akeredolu
























