Sunday Igboho: Bí kò bá sí ìbò láti mọ èrò Yorùbá tó fẹ́ yapa, kò ní sí ìbò òṣèlú ní 2023

Aworan ipolongo iwọde Omo Odua

Ọjọ Satide ni ilana ọmọ Oodua gbe iwọde ipolongo fun idasilẹ orilẹ-ede Yoruba Nation lọ si ilu Ado-Ekiti, nipinlẹ Ekiti.

Nibi iwọde naa ni Igboho ti sọ pe dandan ni ki idasilẹ orilẹede Yoruba Nation waye, nitori pe aidọgba wa ninu bi ijọba ṣe n pin awọn ọrọ Naijiria, ti wọn si tun ti fi ọwọ rọ ẹya Yoruba sẹyin.

Igboho to sọrọ ni ede Yoruba sọ pe "o to gẹ. A gbọdọ duro fun ominira wa, nitori pe a ti jiya to o. Ọmọ Yoruba ni wa, a o si gbọdọ jẹ ẹru nilẹ wa."

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni gbogbo nkan to ba gba ni awọn yoo ṣe lati gba Yoruba kuro ni abẹ isinru Fulani, ti yoo si ya kuro lara Naijiria ti yoo ba fi di ipari oṣu Kejila, ọdun 2021.

Sunday Igboho fi ẹsun kan pe gbogbo alumọni ni Naijiria ni, amọ awọn Fulani lo n ṣakoso wọn, ti wọn si tun jẹ olori ileeṣẹ ijọba gbogbo.

Àkọlé fídíò, Blessing Olajide: Ẹ̀bí akẹ́kọ̀ọ́jáde fásitì Ilorin tí wọn pa ṣàlàyé ikú rẹ̀

O ni gbogbo awọn nkan yii, to fi mọ bi ọpọlọpọ ọdọ to ti kawe tan ko fi ri iṣẹ ṣe, lo mu ki awọn o ma a polongo pe o ti to gẹ ẹ.

Ati pe ti ijọba ko ba fi ṣe idibo lati mọ eero araalu nipa iru Naijiria ti wọn fẹ, ẹya Yoruba ko ni i dibo gbogboogbo lọdun 2023.

O fikun pe ilẹ Yoruba nilo ijọba tiẹ.

O sọ pe nkan to kan lati ṣe bayii ni pe "awọn yoo wọ inu igbo lọ lati le awọn darandaran Fulani yii kuro".

Bakan naa lo sọ nibi iwọde naa, lasiko ti o sabẹwo si aafin Èwí Ado-Ekiti, pe awọn n bọ ni Eko nitori ilẹ baba awọn ni.

Sunday Igboho

Ni nkan bi aago marun irọlẹ ni Sunday Igboho ti ọpọlọpọ eniyan ti n reti nibi iwọde naa de sibẹ pẹlu ọpọ eniyan to n wọ tẹle ni ẹyin.

Ṣaaju ki iwọde naa to bẹrẹ ni awọn eeyan ti pe babi si gbagede Fajuyi Park.

Aworan ipolongo iwọde Omo Odua

Bakan naa ni wọn ṣe abẹwo si aafin Ewi Ado.

Wamuwamu si ni awọn oṣiṣẹ alaabo Amẹtẹkun, ọlọpaa, FRSC, ati awọ̀n mii duro nibi ti iwọde naa ti fẹ ẹ waye.

Àwọn olùwọ́de fún Yoruba Nation ṣe àbẹ̀wò sí àáfin Èwí ti Ado-Ekiti

Awọn oluwọde ọmọ ilẹ Yoruba labẹ asia to n pe fun idasilẹ Oduduwa Republic ti gunlẹ si ipinlẹ Ekiti fun iwọde.

Eruku ti n sọ lala ni ilu Ado Ekiti, ni igbaradi fun iwọde ipolongo idasilẹ Yoruba Nation.

Awọn oṣiṣẹ alaabo Amọtẹkun

Igba akọkọ re ti wọn yoo lọ si ipinlẹ naa ṣugbọn wọn ti n kaakiri awọn ipinlẹ mi ṣaaju asiko yi.

Ni nkan bi ọṣẹ meji sẹyin ni irufẹ iwọde bẹẹ waye ni ilu Akure tii ṣe olu ilu ipinlẹ Ondo.

Ko pẹ si igba ti iwọde yi waye ni Gomina Rotimi Akeredolu figbe sita pe ki awọn eeyan sinmi ahesọ pe oun faramọ idasilẹ Oduduwa Nation.

Àkọlé fídíò, Tunde Bakare: Àjọjẹ kò dún bẹ́nìkan kò ní ló fa ìjà S Igboho,bẹ́ẹ̀ ìjọbati gbẹ́rù kọjá orí

O fọ esi yi ni idahun si ọrọ kan to gbode pe Sunday Adeyemo,Igboho, ni Akeredolu wa lẹyin awọn oluwọde Oduduwa Nation.

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....

A ko ti mọ nkan ti yoo ṣẹlẹ loni ni ipinlẹ Ekiti ṣugbọn ko ti si ijọba ipinlẹ Yoruba kankan to kọdi iwọde awọn oluwọde Ilana Ọmọ Odua.

Gomina Kayode Fayemi

Oríṣun àwòrán, Twitter/Kayode Fayemi

Kayode Fayemi to jẹ Gomina ipinlẹ Ekiti ti wọn n gbe iwọde bọ wa ba ni alaga ẹgbẹ awọn Gomina ni Naijiria.

Lọpọ igba lo ti fi ero ọkan rẹ nipa idasilẹ Oodua Nation han wi pe awọn ti nkan ko rọgbọ fun lo n pe fun ki wọn tu Naijiria ka.

Àkọlé fídíò, Magaret Jimoh: Èrè díẹ̀ ti tó mi níbi oúnjẹ ti mò ń tà- Maggie Rice