Akure school bus hijacked: Mí kò dá àwọn agbébọn náà mọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò bojú- Omolayo Ojo

Àkọlé fídíò, Ondo school bus hijack: Mí kò dá àwọn agbébọn náà mọ̀ ṣùgbọ́n wọn kò bojú- Omolayo Ojo

Wọn gbe ibọn sori mi pe ki n tẹle wọn ni- Omolayo Ojo to jẹ oluranlọwọ akékọọ ninu bọọsi.

Adari ile ẹkọ Chimola Schools ni wọn ti da gbogbo ọmọ pada ati pe ko si ẹni to sọnu mọ nile iwe naa.

Omolayo ti wọn gbebọn si lori naa ba BBC sọrọ lori bi gbogbo ẹ ṣe ṣẹlẹ.

Bakan na ni kọmiṣọnna Bolaji Salami to n tukọ agbofinro ipinlẹ Ondo naa ba BBC Yoruba sọrọ lori ibi ti igbesẹ wiwa bọọsi ati awọn oniṣẹ ibi naa ri de duro.

Akure

A ti rí dírẹ́bà àti olùrànlọ́wọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ nínú bọ́ọ̀sì- Adarí ilé ẹ̀kọ́ Chimola Schools, Akure

Irú èyí kò ṣẹlẹ̀ rí nílé ẹ̀kọ́ wa, ṣùgbọ́n a dúpẹ́ pé a rí gbogbo akẹ́kọ̀ọ́- Bolatito Akindemowa

Arabinrin Bolatito Akindemowa to jẹ oludari ile ẹkọ Chimola schools ni Oba Ile Estate ni ilu Akure nibi ti awọn agbebọn ti sọṣẹ ni aarọ yii ti sọrọ sii lori iṣẹlẹ naa.

O salaye pe lasiko ti direba bọọsi to n ṣa awon ọmọ kaakiri ile wọn n lọ ni nkan bii aago mẹfa abọ owuro oni lo ṣẹlẹ.

Bi a ṣe n sọrọ yii, wọn ti ri direba to wa ọkọ naa ati Omolayo Ojo to jẹ oluranlọwọ awọn akẹkọọ ninu bọọsi naa pada.

Omolayọ Ojo salaye fun BBC Yoruba pe, awọn agbebọn naa gbe oun lọ sinu igbo ni.

O ni: Wọn ja oun sinu igbo naa, wọn si wa ọkọ bọọsi awọn akẹkọọ naa lọ.

Omolayo ni oun rin pada wa si oju titi ti oun si ri awọn alaanu fun pun lowo ọkọ wa si ile ẹkọ pada.

Adari ile ẹkọ naa ni wọn ti fi ọrọ naa to ọlọpaa leti ati pe bọọsi nikan lo ku ti won n wa bayii.

O ni ko si akẹkọọ kanakan to sọnu.

Àwọn ajínigbé ṣọṣẹ́ ní Akure wọ́n kọlu bọ́ọ̀sì iléẹ̀kọ́ kan lọ

Awọn agbebọn kan ti kọlu ọkọ bọọsi ileewe kan lagbegbe Ọba ile Estate ni ilu Akurẹ.

Gẹgẹ bi iroyin ṣe sọ, awọn agbebọn naa ji eeyan kan gbe ninu awọn oṣiṣẹ to wa pẹlu awọn akẹkọọ naa.

aworan awon eeyan kan pẹlu ibon

Oríṣun àwòrán, other

Iṣẹlẹ yii ṣẹlẹ ni nnkan bi agogo meje ku iṣẹju diẹ lowurọ Ọjọbọ.

Iroyin fiyeni pe awọn ajinigbe naa ti wọn to mẹjọ niye wa lori alupupu ọkada nigba ti wọn yi bọọsi naa po ti wọn si wọ dẹrẹba ọkọ naa bs silẹ.

Awọn ajinigbe naa wa bọọsi naa ti nọmba idanimọ rẹ jẹ Lagos LSD 853 FJ lọ pẹlu skan lara awọn oṣiṣẹ naa.

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....