Òṣìsẹ̀ 170 tí Ajimobi lé ni Lautech ni ń o gbà padà, owó osù márun wọ́n yoo di sísan- Gómínà Oyo

Oríṣun àwòrán, AFP
Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo, onímọ̀ẹ̀rọ Seyi Makinde Ti kéde mímú àdínkù bá owó ilé ìwé fásitì Ladoke Akintola (LAUTECH) pẹ̀lú ìdá márùndínlagbọ̀n nínú ọgọ́rùn.
Gómínà kéde ìgbésẹ̀ tuntun yìí lásíkò tó ṣe àbẹ̀wò àìròtẹ́lẹ̀ sí ilé ìwé náà nílú Ogbomoso, tí ó sì fi kun pé àdíkù owó náà yóò kan gbogbo ipele ẹ̀kọ́ lábẹ́ àkósòso bí ó ti wù kórí.
Nínú àtẹ̀jáde tó padà fọ́wọ́sí, akọ̀wé ìròyìn fún gómìnà Taiwo Adisa sàlàyé nǹkan ti Makinde sọ pé òun dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ bí wọ́n ṣe gba òun láyé bótilẹ̀ jẹ́ pé òun kò fi ìwé ránṣẹ́ kí òun tó ṣe àbẹ̀wò síbẹ̀.
- Olorì Damilola fi èpè ránṣẹ́ sí 'bàbá' rẹ̀ to ní kò padà sọ́dọ̀ Aláàfin
- Àbámọ̀ ńlá ń bọ̀ láìpẹ́ fún àwọn tó fẹ́ dojú ìjọba bolẹ̀, a má tó yọ sí wọn- Buhari
- Wo ìdí tí ECOWAS fi dá Mali dúró, tó tún fún àwọn ológun ní gbèdéke láti gbé ìjọba sílẹ̀
- Ọ̀gá àgbà NECO papòdà- Kà nípa bí Ọjọ́gbọ́n Obioma ṣe kú
- Olorì Damilola fi èpè ránṣẹ́ sí 'bàbá' rẹ̀ to ní kò padà sọ́dọ̀ Aláàfin
- Wo ìdí tó fi ṣeéṣe kí ìjọba àpapọ̀ ó kéde àkọ̀tun ìséde n'ipínlẹ̀ Eko
- Nǹkan kò burú tó báyìí ní ọgbọ̀n ọdún sẹ́yìn tí mo kọrin pé kí Ọlọ́run bá wa tún Nàijíríà ṣe- Funmi Aragbaye
Bákan náà ló ṣe iléri pé láìpẹ̀ láìjìnà, ìpinlẹ̀ Oyo nìkan ni yóò ni ilé ẹ̀kọ́ náà,
O sọ fún àwọn àkẹ́kọ̀ọ́ náà pé lẹ́yìn ìdìbò, ó ti yẹ kí òun pada wá láti dúpẹ́ sùgbọ́n ìgbìyànjú òun láti mú iléri ṣe lo da òun dúró, sùgbọ́n ẹbun àdínkù owó ilé ìwé ni òun múwa láti dúpẹ́.
Makinde ni pe: Àdínkù owó náà kò nií fi ṣe bóya ọmọ ìpińlẹ̀ Oyo ni ẹni náà tàbi bẹ́ẹ̀ kọ́.
Makinde tún sàlàyé pé àra àra àwọn ìlérí tí òun ṣe ni láti ṣe àtúṣe òpópónà "Under -G Stadium pẹlú ètò iná ojú pópó láti dènà ṣíṣe àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ni ìṣekúṣe, jàwọ́n lólè tàbi ṣe ikú pa wọ́n.
Gómìnà sàlàyé pé láti àsìkò yìí lọ, ètò ẹ̀kọ́ tí kò ju ọdún mẹ́rin lọ kò ni kọjá ọdún mẹ́rin bákan ni òun yóò túbọ̀ gba àwọn òṣìṣẹ́ tó le ni àádọ́jọ́ tí ìjọba tó lọ le kúrò lẹ́nú iṣẹ́ si ilé ìwòsàn ìkọ́ni Lautech ti òun yóò si san owó oṣù márùn tí wọ́n jẹ́ wọ́n .
- Ìdí tí a fi mú àwọn olùfẹ̀hónúhàn pé wọ́n tẹ òfin ètò ààbò lójú.
- Àwọn ọ̀dọ́ lé kábíyèsí jáde láàfin l'Ondo
- Adigunjalè ja Ọ̀gá ọlọ́pàá àti ẹni mẹ́ta míràn lólè
- Wo ohun ti yóò ṣẹlẹ̀ sí obìnrin tó bá fi ojú rí Orò
- A ti rí ọmọ ilé kéú 11 míì nínú àwón tí agbébọn jí gbé ní ìpínlẹ̀ Niger
- 'Kò sí ààtò fún òfin Sharia àti ẹtọ àwa ẹlẹsìn Islam nínú Oduduwa Republic, a ò gbà!'














