NECO ti kéde Ebikibina Ogborodi gẹ̀gẹ́ bíi ọ̀gá àgbà fìdíhẹẹ́ tuntun

Ebikibina Ogborodi

Oríṣun àwòrán, @thereachfm1049

Awọn alaṣẹ ajọ to n mojuto idanwo aṣekagba ni Naijiria, NECO, ti buwọlu iyansipo ọgbẹni Ebikibina Ogborodi gẹgẹ bii ọga agba fidihẹ fun ajọ naa.

Wọn gbe igbesẹ yii lẹyin ti ọga agba ajọ ọhun tẹlẹ, Godswill Obioma jade laye.

Adari ọọfisi alukoro ajọ naa, Azeez Sani lo fi ọrọ naa lede ninu atẹjade kan nipinlẹ Niger.

Atẹjade ọhun ni "Iyansipo yii n waye lẹyin iku Ọjọgbọn Godswill Obioma to jade laye lọjọ kinni, oṣu Kẹfa, ọdun 2021."

Ki wọn to kede ọgbeni Ogborodi bii adari fidihẹ tuntu fun ajọ NECO, oun ni adari ẹka to n ri si akanṣẹ iṣẹ ninu ajọ ọhun.

Sani ṣalaye pe inu ipade pajawiri kan ti wọn ṣe ni wọn ti kede orukọ adari agba tuntun naa.

Àkọlé fídíò, Adebayo Shittu: Èmi kò ṣẹ Abiola Ajimobi nígbà ayé ẹ, òun ló ṣe mi ṣùgbọ́n.....

O fi kun pe awọn yan Ogborodi sipo naa lẹyi ti wọn ri pe oun ni adari to ga ju ninu ajọ ọhun lọwọ yii.

Awọn alakoso NECO sọ pe gbogbo eto ti wọn ti la kalẹ ṣaaju iku adari agba ana to di oloogbe ni yoo tẹsiwaju.

Ọmọ ijọba ibilẹ Sagbama ni Ogborodi ti wa, iyẹn lati ipinlẹ Bayelsa.

O kẹkọọ gboye ni fasiti ilu Jos lọdun 1986, o si tun kawe siwaju si nile ẹkọ kan naa lọdun 1999.

Àkọlé fídíò, Oba Gbolahan Timson Shomolu Bariga ní 'Restructuring'ti bọ́ aṣọ kò bá Omọyẹ mọ́!

Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?

"NECO Registrar dead": [Professor Godswill Obioma death] and 'how di NECO boss die'

Oríṣun àwòrán, NECO

Ọ̀gá àgbà àjọ tó n mújútó ìdánwó àṣekágbá ní Nàìjíríà (NECO) ọ̀jọ̀gbọ́n Godwill Obioma ti kú

Gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀bí ṣe sọ Obioma kú ni ọjọ́kọ̀kànlélọ́gbọ̀n òsù karun, ọdún 2021, àjọ NECO kéde ni ọjọ́ Isegun.

Ẹni ọdún mẹ́tàdínláàdọ́rin kú lọ́yìn tí ó ṣe àisàn ránpẹ́, gẹ́gẹ́ bi àjọ NECO se sọ pé àwọn ẹbí olóògbé ṣe sọ.

NECO fìdí ọ̀rọ̀ náà múlẹ̀ nínú àtẹ̀jáde tí Mustapha fọwọ́ sí, yàtọ sí ìròyìn tó n fò ká pé àwọn agbébọn ló pa ọjọ̀gbọ́n náà

Ààrẹ Muhammadu Buhari fún Obioma sípò ni ọdún tó kọjá, òun sì lò rọ́pọ̀ ọ̀jọ̀gbọ́n ló rópò Charles Uwakwe ti wọ́n ni ko lọ rọkún nílé nítori ìwà aṣemáṣe lẹ́nu iṣẹ́.

Àkọlé fídíò, Oba Gbolahan Timson Shomolu Bariga ní 'Restructuring'ti bọ́ aṣọ kò bá Omọyẹ mọ́!

Nínú ìròyìn mííràn tó tún jẹyọ nínú àwọn ìwé ìròyìn abẹ́lé ṣàlàyé pé àwọn agbénipa ló wọ inú ọgbà ilé náà ní kété tó dé láti ilú Abuja.

Ìwé ìròyìn náà ṣàlàyé pé aya rẹ̀ Elizabeth Obioma ló ṣàlàyé yiì fún àwọn akọròyìn.

Àkọlé fídíò, Adebayo Murital David: Gbogbo iṣẹ́ tó ń múni là láyé wá láti ọpọlọ ni kìí ṣe agbára