Insecurity: Amotekun yóò bẹ̀rẹ̀ sí ni káàkiri ibodè nílẹ̀ Yorùbá láti máwọn ọ̀daràn àti ajínigbé- Adetunji adeleye

Ọgagun ọga awọn Amotekun nilẹ Yoruba, Oloye Adetunji Adeleye ti kede pe ọjọ kinni oṣu kẹfa ni ẹṣọ eleto abo naa yoo bẹrẹ si ni maa kaakiri ibode awọn ipinlẹ Yoruba.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Oloye Adeleye sọ pe awọn gomina ti pese ọkọ tawọn maa lo fun iṣẹ yii.
O tun fikun ọrọ rẹ pe kii ṣe wi pe awọn maa ṣiṣẹ ileeṣẹ aṣọbode.
- Ọwọ́ EFCC tẹ ọmọ Yahoo tó fẹ́ ra ọkọ̀ SUV tí iye rẹ̀ tó 44 mílíọ́nù pẹ̀lú Bitcoin
- Àwọn jàndùkú agbébọn ṣekúpa Ahmed Gulak, olùdàmọ́ràn Goodluck Jonathan
- Ọmọ ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn bẹ́ sódò láti bọ́ lọ́wọ́ ọlọ́pàá
- Ẹ̀mí àìrí lé àwọn akẹ́kọ̀ọ́ jáde ni ilé ẹ̀kọ́ St Claire's ní Offa
- Àwọn jàndùkú agbébọn yìnbọn pa ọkùnrin oníṣòwò kan nílùú Ibadan
- Ọ̀pọ̀ ọ̀rẹ́ àti aya lọ lẹ́yìn ti ojú mi lọ ní 2012 ṣùgbọ́n lónìí iṣẹ́ Àdìrẹ ti sọ mi dí eèyàn- Muritala David
''Amotekun nikan kọ lo maa ṣiṣẹ yii, awọn ọlọpaa, DSS ati Civil Defence yoo fọwọ sowọpọ pẹlu wa lati le gbogun tawọn adigunle loju popo.
Ṣe ẹ mọ pe idasilẹ Amotekun wa fun iranwọ fawọn agbofinro ni tẹlẹ.
Ofin to gbe wa kalẹ sọ pe ibi ti apa ba ti n ro wọn ni ki a ti ba wọn gbe e soke.
Awọn eṣọ Amotekun to wa ni ipinlẹ Osun yoo maa ṣiṣẹ pọ pẹlu awọn to wa ni Oyo, awọn ti ipinlẹ Oyo naa yoo gbera lọ si Ondo, bi a o ṣe maa ṣee niyẹn,'' Oloye Adeleye ṣalaye.
- Ó ń rúgbó bọ̀ o! Àwọn ajìjàgbara Yorùbá Nation fipá ṣí bọ́dà Idiroko, àmọ́...
- Kí ló bí ìsinmi tí àwọn ajìjàngbara Biafra kéde fáwọn Ibo láti ṣ'àyájọ́ Biafra?
- Ọwọ́ EFCC tẹ ọmọ Yahoo tó fẹ́ ra ọkọ̀ SUV tí iye rẹ̀ tó 44 mílíọ́nù pẹ̀lú Bitcoin
- Nǹkan bíi ọmọ ilé kéú 150 ni àwọn agbébọn jí gbé lọ ní Niger
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíríà ti kéde pé IPOB àti ESN ló pa Gulak tó kú lánàá
- Amotekun yóò máa ṣọ́ ibodè àwọn ìpínlẹ̀ Yorùbá láti máwọn ọ̀daràn àti ajínigbé
Amotekun yóò máa ṣọ́ ibodè àwọn ìpínlẹ̀ Yorùbá láti máwọn ọ̀daràn àti ajínigbé
Gbogbo eto lo ti to bayii fun ẹṣọ alaabo Amotekun lati maa ṣọ ibode awọn ipinlẹ Yoruba.
Igbesẹ yii gbaye lati pese abo to munadoko kaakiri ilẹ kaarọ o jiire.
Ọgagun ẹṣọ Amotekun ipinlẹ Ondo to tun jẹ alaga awọn ọgagun Amoteukun nilẹ Yoruba, Adetunji Adeleye lo fidi ọrọ yii mulẹ.

Oríṣun àwòrán, Western Nigeria security network
Ọgbẹni Adeleye ni eyi ṣe pataki nitori o maa jẹ ko rọrun lati mu awọn ọdaran to ba sa lati ipinlẹ Yoruba kan si omiran.
Adeleye to sọrọ niluu Akure fidi rẹ mulẹ pe dida ẹranjẹko awọn ti dinku nipinlẹ Ondo bayii.
O ni awọn darandaran ti bẹrẹ si ni sanwo fawọn agbẹ ti wọn ti da ẹran jẹ oko wọn.
Ọgagun Amotekun naa ni gbogbo opopona to wa kaakiri ilẹ Yoruba lawọn ẹṣọ Amotekun yoo maa ṣọ bayii.
''A fẹ rii pe iṣẹlẹ adigunjale ati ijinigbe dinku lawọn opopona wa nilẹ kaarọ o jiire.
A ti ṣe akiyesi pe awọn ibi ti ọna ti bajẹ tawọn awakọ kii ti lanfaani ti sare ni iṣẹlẹ ijinigbe ti maa n saaba ṣẹlẹ.
Bakan naa, a gbọdọ ri wi pe ofin maa dẹran ni gbangba mọ mulẹ kaakiri ilẹ Yoruba.
A ti bẹrẹ si ni mu awọn darandaran to ba dẹran jẹ oko awọn eeyan wa.
Darandaran to ba ti dẹran jẹ oko bayii ti di ọdaran.
- Sunday Igboho bẹ̀bẹ̀ lórí ìkùnsínú tó ń wáyé nípa ìwọ́de l‘Ekiti
- Àwọn jàndùkú agbébọn ṣekúpa Ahmed Gulak, olùdàmọ́ràn Goodluck Jonathan
- Mọ̀ síi nípa Agbẹjọ́rò àti ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọniyàn ni Nàìjíríà tó lọ sí ẹ̀wọ̀n nígbà 32
- Arúmọjẹ lásán ni lọkọ-láya tí èmi àti Cute Abiola jọ́ ń ṣe tẹ́lẹ̀, ìyàwó rẹ̀ ti dé- Adeherself
- Èmi kò pe Arinola Oloko ní 'Thug' o, ìbéèrè ni mó bèèrè lọ́wọ́ ẹ- Remi Tinubu
- Adeherself sọ̀rọ̀ sókè lẹ́yìn tí Cute Abiola ṣe ìgbéyàwó ìdánkọ́nkọ́ l'Ogbomoso















