Biafra Day Celebration, May 30: Àwọn ajìjàngbara Biafra kéde ìsìnmi fáwọn Ibo láti ṣ'àyájọ́ Biafra

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Oni ọgbọnjọ, oṣu karun un, ọdun 2021 lo pe ọdun mẹrinlelaadọta ti oloogbe ọgagun Lt Col. Chukwuemeka Odumegwu Ojukwu kede pe orilẹ-ede Biafra awọn Ibo ti ya kuro lara Naijiria.
Ikede Ojukwu yii lo jẹ ki ogun abẹle bẹ silẹ lọdun 1967, ọdun mẹta gbako ṣi ni wọn fi ja ogun naa.
Eeyan to le lẹgbẹrun lọna ẹẹdẹgbẹta ni ebi ati iṣẹ pa ku ninu ẹya Ibo ninu eyi ti awọn ọmọde ti pọju lọ.
- Ó ń rúgbó bọ̀ o! Àwọn ajìjàgbara Yorùbá Nation fipá ṣí bọ́dà Idiroko, àmọ́...
- Sunday Igboho bẹ̀bẹ̀ lórí ìkùnsínú tó ń wáyé nípa ìwọ́de l‘Ekiti
- ''Ẹ ó ríjà Ọba, tí ẹ bá gbìyànjú láti fọ́wọ́ kan Sunday Igboho''
- Agbébọn yabo ilé Sunday Igboho ní òru mọ́jú
- Arúmọjẹ lásán ni lọkọ-láya tí èmi àti Cute Abiola jọ́ ń ṣe tẹ́lẹ̀, ìyàwó rẹ̀ ti dé- Adeherself
Lati ọdun naa ni ọgbọnjọ, oṣu karun un ti di pataki ninu itan orilẹ-ede Naijiria papaa julọ fawọn ẹya Ibo.
Awọn Ibo naa ko kọkọ ka ọjọ yii kun tẹlẹ, amọ awọn to n pe ifun iyapa Ibo lara Naijiria ti jẹ ki wọn kaa kun bayii.
Lọdọọdun ni awọn ajijigbara fun idaduro ẹya Ibo lara Naijiria maa n sọ fawọn pe ki wọn joko sile lọgbọnjọ oṣu karun lati le fi ṣe ayajọ Biafra.
Ojukwu gan an ni olori Biafra nitori oun lo kede iyapa Ibo lara Naijiria.
Ilu Nnewi ni Ojukwu ti wa nipinlẹ Anambra ṣugbọn ilu Zungeru nipinlẹ Niger ni wọn bi i si lọdun 1933.
Ọmọ onile ọlọna ni Ojukwu i ṣe, awọn obi rẹ ran an nile iwe debi pe o tun kawe ni fasiti niluu London.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Lẹyin ti o kawe gboye ni fasiti niluu London lo darapọ mọ ileeṣẹ ologun Naijiria.
Ojukwu di gomina ologun apa ila -oorun Naijiria lẹyin tawọn ologun ditẹ gbajọba alagbada lọdun 1966 bo tilẹ jẹ pe ko lọwọ ninu iditẹgbajọba ọhun.
Ko gba pe ọga ni Yakubu Gowon to jẹ aarẹ ologun jẹ fun oun, ati pe o ni Gowon n yan awọn ẹya Ibo jẹ.
Lẹyin naa lo kede orilẹ-ede Biafra pe ẹya Ibo ṣetan lati yapa kuro ni Naijiria eyi to jẹ ki ogun bẹ silẹ.
Ojukwu lọ ṣatipo lorilẹede Ivory Coast lọdun 1970 lẹyin ti ogun abẹle pari ki ijọba Naijiria to darijin in lọdun 1982.
- Tí Benue kò bá ní Sunday Igboho tIẹ̀, ìṣekúpaní yóò tẹ̀síwájú - Reno Omokri
- Bí Ààrẹ Buhari bá parí sáà rẹ̀ tán ni ọ̀pọ̀ ọmọ Naijiria yóò mọ rírì iṣẹ́ tó ń ṣe - Ìjọba àpapọ̀
- Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Greenfield tí wọ́n jí gbé ní Kaduna gba òmìnira lẹ́yìn tí àwọn òbí wọn san "180 mílíọ́nù naira"
- Wo ìdí tó fi rọrùn fún Chelsea láti bu ìfọ́jú lu Manchester City lẹ́ẹ̀mẹẹ̀ta léra wọn
Ijọba Naijiria gbe Ojukwu lọdun 1983 lẹyin iṣẹlẹ iditẹgbajọba kan, ṣugbọn wọn pada fi i silẹ lọdun 1984.
Ojukwu ko saaba dasi ọrọ oṣelu mọ lati igba naa titi to fi ku lọdun 2011.















