Sunday Igboho: Aago kan ààbọ̀ òru ní àwọn agbébọn gúnlẹ̀ láti sun ilé mi

Oríṣun àwòrán, Sunday Igboho/Instagram
Iroyin to n tẹ wa lọwọ ni yajo yajo ti kede pe awọn agbebọn kan ya bo ile ajijagbara fun ilẹ Yoruba, oloye Sunday Adeyemo, ti ọpọ eeyan mọ si Sunday Igboho.
Iroyin naa fikun pe se ni iro ibọn n dun lakọ lakọ niwaju ile Sunday Igboho ni oru mọ̀ju ọjọ Aje, ti gbogbo agbegbe Soka, ti ile ajijagbara naa wa, ko si fara rọ̀ laajin oru.
Nigba to n fi idi isẹlẹ naa mulẹ fun BBC Yoruba, agbẹnusọ fun Igboho lorilẹede Naijiria, Dapo Salami salaye pe deede aago kan oru ni awọn eeyan naa gunlẹ sinu ile naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ikú Jelili kó lọ lásán, iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ Jonathan ọlọ́pàá tó ṣekúpa ní Quilox
- Ọjọ́ ìsinmi òni ro! Agbébọn ṣé ikọlù sílé ìjọ́sìn ní Kaduna, wọ́n jí ọ̀pọ̀ olùjọ́sìn gbé lọ
- Ẹgbẹ́ òṣèré tíátà TAMPAN sọ̀rọ̀ sókè lórí ẹ̀ṣùn bíbá ọmọdé lòpọ̀ tí wọn fi kan Baba Ijesha
- Kí ló fa ìjà láàárín Eedris Abdulkareem àti Festus Keyamo?
- Ẹgbẹ́ Oduduwa Republic Agitators ní ìwọ́de alágbára ń bọ̀ l‘Osun
- Pásítọ̀ pín ounjẹ iṣínu àwẹ̀ Ramadan fún àwọn Músùlùmí
- Kábíyèsí Ooni ti forí jin Sunday Igboho lẹ́yìn tó túúbá- Ààfin Ile Ife
- Àwọn ọ̀nà tá gbà rèé tí orílẹ̀èdè Oduduwa yóò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́ - Gani Adams
Salami ni awọn alatilẹyin Sunday Igboho to wa ninu ile pẹlu rẹ gbena woju awọn eeyan to wa se ikọlu naa, ti wọn si le wọn danu.
" A ko le sọ iye eeyan to wa loru mọju lati wa kọlu ile Sunday Igboho amọ wọn pọ, ti a ko si tun mọ iru awọn eeyan to fi oru boju wa.
A ko mọ boya janduku ni wọn tabi ọmọ ologun sugbọn wọn wa pẹlu ọpọ kẹẹgi pẹtiroolu, o si foju han pe wọn wa lati sun ile mọ Igboho lori ni.
Ọpẹlọpẹ awọn ọmọ ẹyin igboho to tako awọn eeyan yii lati sisẹ laabi wọn, ti wọn si fi ẹsẹ fẹ.
Dapọ Salami wa fi ọwọ gbaya pe ko si ohunkohun to se ajijagbara fun ilẹ Yoruba naa, saka ni ara rẹ da.



















