Oduduwa Republic Agitators: Bí Oyetola ṣe lé ọ̀gá iléèwé mẹ́tẹ́ẹ̀ta jẹ́ àfihàn ìwà ìkórira sí wa

Awọn to n polongo fun idasilẹ orilẹede Yoruba

Oríṣun àwòrán, Koiki Media

Ẹgbẹ apapọ awọn eeyan to n beere fun idasilẹ orilẹede Yoruba, labẹ aburada Oduduwa Republic Agitators (ORA), ti sọrọ soke lori isẹlẹ to waye nipinlẹ Osun laipẹ yii.

Bẹẹ ba gbagbe, ijọba Osun pasẹ pe ki ọga ileẹkọ giram mẹta lọ rọọkun nile na nitori bi awọn eeyan to n beere fun iyapa orilẹede Naijiria se wọnu ọgba ileewe wọn lati fa oju awọn akẹkọọ ibẹ mọra.

Amọ nigba to n sọ ero rẹ lori isẹlẹ yii, ẹgbẹ ORA ni oun yoo seto atako alagbara nipinlẹ Osun lori igbesẹ ijọba naa nitori iya to fi jẹ awọn ọga ilẹẹkọ naa.

Atẹjade kan ti aarẹ ẹgbẹ agbaye fun Oduduwa Republic Agitators Worldwide (ORA), Segun Damilola Olaniyan fisita lo sisọ loju ọrọ naa.

Ọrọ ti ẹgbẹ Oduduwa Republic Agitators kọ soju opo Facebook rẹ

Oríṣun àwòrán, ODUDUWA REPUBLIC AGITATORS/Facebook

Ẹgbẹ ORA ni bi gomina ipinlẹ Osun, Adegboyega Oyetola se ni ki awọn ọga ileẹkọ mẹtẹẹta naa lọ rọọkun nile fihan pe o korira awọn eeyan to n ja fun orilẹede tuntun naa.

Bakan naa ni wọn leri leka pe loore koore ni awọn yoo maa fi ẹhonu han lori isẹlẹ naa titi ti gomina Oyetola yoo fi da ọga ileẹkọ mẹtẹẹta naa pada.

"A ri igbesẹ gomina Osun gẹgẹ bii iwa ikorira si awọn eeyan to n polongo fun idasilẹ orilẹede Yoruba, a si tako igbesẹ odi to gbe naa pẹlu iwọde alagbara.

Àkọlé fídíò, Bí Oduduwa Republic bá bẹ̀rẹ̀, a ò ní ṣe aburú fún àwọn tó takò wá, ìlànà ààtẹ̀lé rèé - Banji Akintoye

Awọn ọga ileẹkọ naa gbe igbesẹ naa tori ẹtọ ti wọn ni labẹ ofin lati seto ipolongo ni ayika naa.

Gbogbo ọba alaye ati agba ijoye nipinlẹ Osun la fun ni atẹjade yii, ki a le fi isẹlẹ yii to wọn leti."

Ẹgbẹ ORA tẹsiwaju pe oun ti ri daju pe ilẹ Yoruba nikan ni awọn asaaju oselu kii se atilẹyin fun ifẹ araalu nitori ifẹ tara wọn.

Àkọlé fídíò, Báa ṣe lọ́pọlọ tó, ẹnu Yorùbá ò kò, ọgbọ́n táa gbúdọ̀ dá rèé - Ìpàdé àgbààgbà Yorùbá n'Ibadan

Ẹgbẹ naa ni oun lero pe gomina naa yoo se afihan iwa ọmọluabi nipa yiyi igbesẹ rẹ pada ki awọn ọga ileewe mẹtẹẹta le pada si ẹnu isẹ ni kiakia.

Ẹgbẹ ORA ni ti gomina Oyetola ba gbe igbesẹ naa, eyi to tubọ mu ki ifẹ tawọn ni si ru gọgọ si nitori baba ati arakunrin awọn lo jẹ.

Àkọlé fídíò, Hisham Wadan: Ìlanilọ́yẹ̀ nípa àrùn ojú ló mú mi ṣe fíìmù Lost in London