Oba Abdulrasheed Adewale Telu 1: Ìwà ọ̀daràn yóò dínkù tí ìjoba bá bẹ̀rẹ̀ sí ní pa àwọn ọ̀daràn tí wọ́n bá mú- Oluwo ti Iwo

Oluwo

Oríṣun àwòrán, Oluwo of Iwo land

"Iwa ọdaran yoo dinku ti ijọba ba bẹrẹ sini pa awọn ọdaran ti wọn ri mu" - Oluwo

Oluwo ti ilẹ Iwo, Ọba Abdulrosheed Adewale Akanbi Telu I, ti ṣe alaye wi pe adinku yoo deba awọn ọkanojọkan iwa ibajẹ ati iwa ọdaran ti awọn eeyan kan n hu lorilẹede Naijiria ti ijọba ba bẹrẹ sini ṣe idajọ iku lẹsẹkẹsẹ fun awọn ọdaran ti wọn gbamu.

Oluwo ṣe alaye ọrọ naa nibi apẹro laarin agbẹ ati darandaran to waye l'ọjọ Iṣẹgun ni aafin rẹ to n bẹ nilẹ Iwọ.

Ọba alade naa fi kun ọrọ rẹ wi pe aisi idajọ ni kiakia fun awọn ọdaran ti awọn agbofinro orilẹede yii ti ri gbamu jẹ nnkan to n fun awọn eeyan mii ni igboya lati tẹsiwaju ninu iwa ọdaran.

Oluwo fi kun ọrọ rẹ wi gbogbo awọn orilẹede to ti gun oke agba lagbaye lo n ṣe idajọ lẹsẹkẹsẹ fun awọn ọdaran to n da omi alafia ilu ru. O ni igbese yii yoo mu ko nira fun ẹnikẹni lati ṣe ohunkohun to le mu wọn ku iku oro.

Àkọlé fídíò, Epe Fish Market: Wá wo oríṣi ẹja tí o rírí lọ́jà ẹja tó tóbi jùlọ ní Nàíjíríà

Oluwo ni, "Ẹnikẹni ti wọn ba gba mu to ge ọwọ eeyan lati fi ṣe etutu ọla, ki ijọba ge ọwọ tiẹ naa. Bi ẹnikẹni ba ge eeyan lori ki wọn ge ori tiẹ naa".

Igbagbọ Ọba alade yii ni pe idajọ ododo ti ko falẹ rara yoo ṣe afọmọ to pọ ni orilẹede wa.

Ipada ti wọn ṣe ni aafin Oluwo lo da lori ọna ati alafia yoo fi jọba laarin awọn darandaran ati agbẹ tofimọ ikede ofin ti ijọba fi de dida ẹran n'ita gbangba.

Awọn ladelade, Baalẹ, aṣoju ijọba ipinlẹ Ọṣun, ẹgbẹ agbẹ, awọn darandaran ati awọn agbofinro ko gbeyin nibi ipade naa.

Àkọlé fídíò, Face Transplant: DiMeo ṣùn lásìkò tó n wa ọkọ̀ lálẹ́, ló bá jóná nígbà tí ọkọ̀ gbiná

Kò sí Oduduwa Nation kankan ni ilẹ̀ Iwo! Kí n má gbọ́ ọ - Oluwo

Sunday Igboho sọ̀rọ̀ lórí ọ̀rọ̀ Oduduwa Republic, Oluwo fèsì lọ́nà ọ̀tọ̀

Oluwo ti ilu Iwo, Ọba bdulrasheed Akanbi ni ni toun o, oun nigbagbọ ninu orilẹede Naijiria kanṣoṣo.

Oluwo ti Iwo

Oríṣun àwòrán, Oluwo

Kabiyesi ti Ilu Iwo n fesi lori ọrọ to ti n ja rayin-rayin kaakiri orilẹede Naijiria lẹnu ọjọ mẹta yii paapaa laarin ẹya Yoruba pe kí ẹya naa yapa kuro lara Naijiria.

Lori ọrọ yii kan naa, gbajugbaja ajijagbara ilẹ Yoruba, Sunday Adeyemi ti ọpọlọpọ mọ si Sunday Igboho to n gba waju gbẹyin lọwọ lati ja fun iran Yoruba nipa kikoju ẹya Fulani ti wọn ni wọn n ṣe wọn lọṣẹ naa ti sọrọ.

Sunday Igboho ni afi dandan ki iran Yoruba yapa kuro lara Naijiria ki wọn si da duro nitori ijọba to wa lode ti gbe ọrọ ẹlẹyamẹya sori ju.

Ẹwẹ, Oluwo ti Iwo ni "bi a ba ni a o fẹ Naijiria kanṣoṣo mọ, ṣe o tumọ si pe ki a pa ile ẹkọ awọn olukọni ti ijọba to wa ni ilu Iwo ti?".

O tẹ siwaju pe ṣe ki awọn tun kọ iṣẹ akanṣe opopona Iwo-Osogbo-Ibadan ti ajọ FERMA n tun ṣe ti?

"Owo iranwọ ijọba ti wọn n pin titi kan mẹkunu nkọ o?"

Oluwo ni "Orilẹede Naijiria ni ireti ẹya dudu, a gbudọ pawọpọ gẹgẹ bi oṣuṣu ọwọ ka si wa ojutuu ọlọjọ pipẹ si oniruuru iṣoro wa".

Oluwo ni irẹpọ ati ibukun wa ninu ajṣepọ gbogbo ẹya Naijiria.