James Ibori loot, Abubakar Malami, Nigeria: Nàìjíríà ti rí €4.2m gbà padà nínú owó tí Ibori gbé- Malami

Oríṣun àwòrán, CBN
Adajo agba fun ile ede Naijiria, Abubakar Malami ti kede fun awon omo Naijiria pe owo tuntun ti wole fun itesiwaju Naijiria,
Owo yii lo ni o jẹ milionu merin owo poun ile okeere to le ni igba €4,214,017.66m.
Malami fidie mule pe owo yii je lara owo ti gomina ipinle Delta nigba kan ri, James Ibori ati awon ebi re ko ló sile okeere tẹlẹ.
- Nǹkan dé o! Àwọn àgbébọn tún yìnbọn pa ọlọ́pàá méjì lẹ́nu iṣẹ́, wọ́n dáná sun àgọ́ ọlọ́pàá
- Ohun tó ṣẹlẹ̀ ní ìlú Modakeke àti Ile Ife
- Ìròyìn òfegè táwọn èèyàn ń gbé kiri lórí ìjà Israel àti Palestine rèé
- Ohun tí àwon Gómìnà egbẹ́ òsèlú PDP fenukò lé lórí rèé nílùú Ibadan
- Àwọn Aláṣẹ ilẹ̀ Palestine ní eèyàn 139 ló ti kú ní Palestine nínú ìja Isreal àti Palestine
Dokita Umar Jibrilu Gwandu to je olubadamoran lori eto iroyin ati ifitonileti si Adajo Malami lo fi ikede naa sita nilu Abuja loni ojo Isegun, ójó kejidinlogun, osu karun un, odun 2021.
Koda, Olubadamoran Umar fidie mule pe owo naa ti wó asunwon Naijiria ni odiwon iye to ye ko je ni owo pasipaaro Naira lodindin.
Malami ni o fowo si ikede naa ni eyi to fidie mule pe Naijiria ti ri owo naa gba pada.
Malami naa lo buwolu iwe adehun ti ti won fi da owo Ibori naa pada si asunwon Naijiria.










