Sunday Igboho news: Ọjọgbọn Akintoye tahùn sí àwọn Ọba àti gómìnà tó ń tako Oduduwa Republic

Àkọlé fídíò, Bí Oduduwa Republic bá bẹ̀rẹ̀, a ò ní ṣe aburú fún àwọn tó takò wá, ìlànà ààtẹ̀lé rèé - Banji Akintoye

"O ya awa gan lẹnu pe Gomina wa kan le laya lati sọ iru ẹ lẹnu rẹ..."

Ọjọgbọn Akintoye ni nkan Gomina ipinlẹ Ondo ṣe bi o ṣe fesi si ọrọ Oduduwa Republic jẹ nkan iyalẹnu. Toripe oun gaan lo ni ki wọn maa kọ orin Orilẹede Yoruba lawọn ileewe ati nibi awọn ayẹyẹ ijọba.

"A mọ wipe Akeredolu ati Fayemi duro gbọin-gbọin lẹyin wa nigba taa fẹ da Amotekun silẹ torinaa to ba wa sọ eleyii, kii ṣe ohun ti yoo bi awa ninu".

Akintoye ni oun mọ Akeredolu daadaa ati pe awọn nkan to n ṣe ye oun daadaa.

Ọjọgbọn jẹ ko di mimọ pe ko si bi gomina kan o ṣe ni tẹ si ifẹ ijọba apapọ lẹẹkọkan lati wa oju ire wọn.

O ni awọn o le pe Akeredolu ni eeyan buruku rara tori ọmọ awọn ni.

O gboriyin fun gbogbo Ọba Yoruba to gbaruku ti igbesẹ Yoruba Nation amọ lori nkan ti Oluwo sọ, ẹ wo iru ọgbọn ti Ọjọgbọn fi gbe ọrọ Oluwo yọ ninu fidio naa.