Sunday Igboho: Àwọn ìkọlù sí mi, ilé àti ìyá mi fihàn pé àwọn kan ń dọdẹ mi

Oríṣun àwòrán, sunday_igboho1/Instagram
Eruku ariwo to sọ lana lori bi ajijagbara ọmọ Yoruba nni, Oloye Sunday Igboho se gba iwe ipe lati ọdọ ọga ọlọpa ni ọjọbọ, ko tii lọ silẹ rara.
Koda, ọpọ eeyan lo si n para poro lori isẹlẹ naa, ati ewu ti wọn lo see se ko wa fun ẹmi ajijagbara naa.
Amọ nigba to n salaye lori idi to fi kọ lati gba iwe ipe naa, to ni awọn gende ọlọpaa mẹẹdogun mu wa sile ohun, Sunday Igboho ni ọrọ naa gbero ni.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Èèmọ̀! West Brom fi omi àbùkù wẹ̀ fún Chelsea lọ́sàn án gangan nílé wọn
- Ọ̀daràn darandaran pàdà sí Igangan, wọ́n gé ọwọ ọ̀gá ilé ẹ̀kọ́
- Ọ̀pọ̀ Sunday Igboho, Nnamdi Kanu ní yóò díde torí ìpànìyàn ojoojúmọ́
- Àwọn èèkàn ọmọ Yorùbá tí ìràwọ̀ Sunday Igboho bo tiwọn mọ́lẹ̀, ló ń dọdẹ rẹ̀ - Fani-Kayode
- "Ikọ̀ Àmọ̀tẹ́kùn, ẹ ṣe pẹ̀lẹ́, ilẹ̀ ń yọ̀"
- Gbàjarè! Ọ̀gá ọlọ́pàá fi ìwé ìpè àti géńdé 15 ránṣẹ́ wá mú mi - Sunday Igboho pariwo
- Ọ̀pọ̀ Sunday Igboho, Nnamdi Kanu ní yóò díde torí ìpànìyàn ojoojúmọ́
Agbẹnusọ fun Igboho, Olayomi Koiki salaye pe iriri to ti waye lati ẹyin wa nilẹ Naijiria lo mu ki awọn ẹsọ ajijagbara naa kọ lati gba lẹta ipe ọhun.
"Bẹẹ ba gbagbe, lẹta ni wọn wọn mu wa sile Dele Giwa lọdun 1986, to di bọnbu to bu kẹu, eyi to ran gbajumọ akọroyin naa sọrun ọsangangan."
Bakan naa lo fikun pe awọn isẹlẹ afunilara to n waye ni ayika ajijagbara naa to fura si pe wọn n dọdẹ rẹ loju mejeeji.
"Abi ki ni ka ti sọ ti ina ti awọn ọbayejẹ kan sọ si ile Igboho ladugbo Soka nilu Ibadan losu diẹ sẹyin, tawọn osisẹ alaabo to wa ninu asọ Khaki naa si tun da lọna lasiko to n lọ silu Eko."
Ko tan sibẹ, Koiki fikun pe awọn afurasi Fulani kan tun kọlu ile Sunday Igboho lọsẹ diẹ sẹyin, tawọn gende kan to wọ asọ ologun naa si tun wa tọpinpin ile rẹ."
Koiki ni oye lagba n wo, ifura si ni oogun agba, tawọn gende agbofinro ba wa tun mu lẹta wa lati ọdọ ọga agba ọlapaa, eyi to mu ifura lọwọ.

Gbàjarè! Ọ̀gá ọlọ́pàá fi ìwé ìpè àti géńdé 15 ránṣẹ́ wá mú mi - Sunday Igboho pariwo

Oríṣun àwòrán, Instagram/SundayIgboho
Ajijangbara ati ajafẹtọmọniyan, Sunday Igboho ti ke gbajare si awọn araalu pe ijọba Naijiria n gbiyanju lati fi panpẹ ofin mu oun ni bonkẹlẹ.
Agbẹnusọ fun Sunday Igboho, Olayomi Koiki lo fi ọrọ naa lede ninu atẹjade kan to fisita loju opo Facebook rẹ.
Koiki ni "a fẹ fi to gbogbo araye atawọn ọmọ Naijiria leti pe, ọga agba ọlọpaa fi lẹta kan ranṣẹ si Sunday Igboho, ṣugbọn awọn ẹsọ alabo rẹ kọ lati gba lẹta naa."
- O kéré sí Number! 'Àwa ológún ò fi ara wa wọ́lẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ láti máa ṣe alamí lórí irú ẹ Sunday Igboho'
- Wo àwọn ọmọ Yorùbá tó ń ti Sunday Igboho lẹ́yìn bí i iké
- Oluwo, tí wọ́n bá rán ọmọ níṣẹ́ ẹrú, kó fi t'ọmọ jẹ - Gani Adams
- Kò sí Oduduwa Nation kankan ni ilẹ̀ Iwo! Kí n má gbọ́ ọ - Oluwo
- Àìgbọ́ra ẹni yé ẹ̀yà Yoruba ló ń ṣe ìdíwọ́ fún òmìnira wa - Àkójọpọ̀ ẹgbẹ́ Yoruba l'àgbáyé
O fikun pe Ọjọbọ, Ọjọ Kini, Osu Kẹrin, ọdun 2021 ni wọn mu lẹta naa wa sile Igboho lati ipasẹ ileesẹ igbalode afiweransẹ DHL.
Agbẹnusọ fun Igboho tun salaye pe, awọn ọkunrin mẹfa kan ti wọn pe ara wọn ni ọlọpaa ṣugbọn ti wọn ko wọ aṣọ isẹ, atawọn mẹsan an miran
gunlẹ sile Igboho ni deede aago mẹta ọsan Ọjọbọ naa.

Oríṣun àwòrán, Koiki Media
Koiki ni mọto Corolla ni wọn gbe wa sile ajafẹtọ ilu naa, ti wọn si sọ fawọn ẹsọ ile naa pe awọn fẹ ri oloye igboho."
Koiki ṣalaye pe awọn gende ọhun sọ pe ọdọ ọga agba fun ileeṣẹ ọlọpaa Najiria ni awọn ti wa pẹlu lẹta kan lọwọ wọn, ti wọn kọ orukọ Sunday Igboho si lara.
Wọn ni ọga agba ọlọpaa lo ni kawọn fun ni lẹta naa amọ sibẹ ikọ alaabo Sunday Igboho ko tẹwọ gba lẹta ọhun.
Agbẹnusọ fun ajijagbara naa wa n beere ninu atẹjade naa pe Sunday Igboho yoo nifẹ lati mọ idi ti ọga agba yanyan fun ileeṣẹ ọlọpaa yoo ṣe fi iwe pe oun.
Igboho ni ti wọn ba tilẹ fẹ fi iwe pe oun gan, o yẹ ki wọn kọkọ fi iwe pe gbogbo awọn janduku ajinigbe atawọn ọmọ ẹgbẹ Boko Haram, to n da
alaafia Naijiria laamu lati ọjọ yii wa.
Igboho fi kun pe, ti ọga agba ileeṣẹ ọlọpaa ba fẹ ri, n ṣe lo yẹ ko kede nita gbangba dipo ko maa fiwe ipe ranṣẹ si oun nikọkọ.
Koiki pari ọrọ rẹ pe, fifi lẹta ranṣẹ si Igboho ko jẹ itẹwọgba awọn rara, nitori pe, bẹẹ ni ijọba Naijiria ṣe fi lẹta ranṣẹ si ọmọ Yoruba kan ri ni ọpọ
ọdun sẹyin, iyẹn Dele Giwa, eyii to mu ẹmi rẹ lọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Oluwo, tí wọ́n bá rán ọmọ níṣẹ́ ẹrú, kó fi t'ọmọ jẹ - Gani Adams
- Rògbòdìyàn gbòde lọ́jà Bodija torí aṣọ́bodè tó fi tipá kó àpò ìrẹsì tírélà méje lọ
- Àwọn òṣèré tó ti bàjẹ́ láti ilé, ló kó ìbàjẹ́ wọ agbo tiata débi a'ṣọ ìhòòhò - Dele Odule
- Omijé ẹkún ṣàn níbi ìsìnkú sájẹ́ǹtì ọlọ́pàá táwọn tọ́ọ̀gì òṣèlú pa l'Ekiti
- Wo ohun tí yó ṣẹlẹ̀ sí àwọn tí kò ní nọ́mbà ìbánimọ̀ NIN ní Nàìjíríà
- Awọn Dokita 'NARD' da iṣẹ silẹ lati bere ẹtọ wọn lọwọ ijọbaTi ẹ ko ba gbagbe, kii ṣe igba akọkọ ree ti ijọba Naijiria yoo gbiyanju lati fi panpẹ ofin mu Oloye Igboho.Ni nnkan bii oṣu kan ṣẹyin, ni video kan de ori ayelujara, nibi ti awọn ọlọpaa atawọn ikọ DSS ti gbiyanju lati mu Igboho loju ọna marosẹ Ibadan
siluu Eko, lagbegbe Guru Maraji, ṣugbọn ti wọn mu ofo.





















