NIN Registration: Ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́rìnlá ló ń bẹ nílẹ̀ fún àwọn tí kò ní nọ́mbà ìbánimọ̀ NIN ní Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, Nimc
Ijọba apapọ ti fi lelẹ pe ọmọ Naijiria ti ko ba ti ni nọmba idanimọ apapọ orilẹede Naijiria, NIN yoo fi ẹwọn ọdun mẹrinla jora.
Minisita eto ibaraẹnisọrọ ati ọrọ aje igbalode, Ọmọwe Isa Ali Pantami lo sọ eleyi di mimọ lẹyin ipade ọlọsọọsẹ awọn minisita pẹlawọn oniroyin nilu Abuja.
Ọmọwe Patami ṣalaye pe lọwọ yii, o le ni miliọnu mọkalelaadọta ọmọ Naijiria to ti forukọilẹ fun nọmba NIN wọn.
O ni gẹgẹ bi ofin to ti NIN lẹyin lorilẹede Naijiria,yatọ si ẹwọn ọdun mẹrinla, ẹnikẹni to ba kuna ati gba nọmba naa ko ni lẹtọ ati anfani si awọn ohun amayedẹrun ijọba ati eto banki ati eto ibanisọrọ.
O ni numba Idanimọ naa ko ṣee ti ọwọ makaruru bọ bi tii ikaniyan sẹnsọ.
O fi kun un pe ọgọsan o le mẹsan an miliọnu kaadi ibanisọrọ SIM lawọn eeyan ti ṣeto iforukọsilẹ fun lorilẹede Naijiria ninu eyi to jẹ pe aadọjọ miliọnu ninu wọn nikan ni ilana iforukọsilẹ awọn to ni wọn jina denu; ti awọn yooku ko si ni ilana iforukọsilẹ to jina denu.
Ilé ẹjọ́ ti pàṣẹ fún ìjọba Naijiria láti fi ọjọ́ kún gbèdéke gbígba NIN

Oríṣun àwòrán, Nimc
Ile ẹjọ giga kan to jẹ ti ijọba apapọ nilu Eko, ti fofin de ijọba apapọ Naijiria, lati má fi ofin de awọn siimu ti wọn ko ba so pọ mọ NIN titi oṣu Kẹrin.
Ọdun 2020 ni ileesẹ ìjọba to n mojuto eto ibaraẹni sọrọ, pàṣẹ fun awọn ileesẹ ibaraẹni sọrọ pe ki wọn o gbẹsẹ le irú awọn siimu bẹ ẹ.
Gbedeke ọjọ kẹfà, oṣu Kẹrin ti ijọba pa láṣẹ si ti mu ki ọpọ eeyan o ma a yabo awọn ibudo iforukọ silẹ lai naani aarun Covid-19.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Blighted Ovum: Obìnrin kan sọ ohun tójú rẹ̀ rí nígbà tí oyún bàjẹ́ lára rẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀mẹta
- Ìbẹ̀rù títa òkú màálù bíi námọ̀ fún aráàlú gbòde l‘Ondo
- Ẹ má lọgun ‘Oduduwa Nation’ mọ́, Yorùbá ló kàn láti jẹ ààrẹ - Oluwo
- Ṣe bọ́ọ̀lù àfesẹ̀gbá lèyí àbí àfọwọ́gbá? Wo orílẹ̀èdè tó jẹ góòlù 14-0 ní ìdíje bọ́ọ̀lù kan ṣoṣo
- Ṣé ìjọba Bayelsa fún darandaran Fulani ní gbèdéke ọjọ́ mẹ́rìnlá láti fi ìpínlẹ̀ náà sílẹ̀?
- "Akíkanjú bíi Sunday Igboho ni kí Buhari gbà síṣẹ́ ológun, kìí ṣe ajẹbọ́tà"
- Buhari láṣẹ́ lábẹ́ òfin Naijiria lẹ́tọ̀ọ́ láti gba ìtọ́jú lókè òkun - Amòfin
Sugbọn ṣa, ẹnikan to ti fi igba kan jẹ igbakeji aarẹ ẹgbẹ awọn agbẹjọro ni Naijiria, Monday Ubani, pe ẹjọ pe ki ilé ẹjọ́ fi ofin de ileesẹ ìjọba naa lati má fi ofin de awọn siimu ti wọn ko sọ pọ mọ nọmba idanimọ NIN.

Oríṣun àwòrán, Nimc
Awọn to pe lẹjọ ni ijọba apapọ, Agbẹjọro Agba Naijiria, ileesẹ NCC ati Minisita fun eto ibaraẹni sọrọ.
Ubani sọ ninu iwe ìpéjọ rẹ pe yatọ si pe àṣẹ naa yoo mu inira ba oun, o ni o tun jẹ ọna lati fi ẹtọ ti oun ni lati ni dukia ati lati sọrọ bo ṣe wu oun, dun un.
O ni eyi tako agbekalẹ ofin ọdun 1999. Bakan naa lo fẹ ki ile ẹjọ fi ọjọ kún gbedeke naa.
Ninu idajọ to ṣe lori ẹjọ naa lọjọ kẹtalelogun, oṣu Kẹta, ọdun 2021, Onidajọ M. A Onuetenu pàṣẹ pe ki ijọba fi oṣu meji kún gbedeke naa.
Oṣu meji naa si bẹrẹ lati ọjọ idajọ.
Ile ẹjọ ti wa sọ pe ìnira, ati fifi ẹtọ ẹni dun ni, ni gbedeke ọjọ kẹfa, oṣu Kẹrin yoo jẹ fun awọn ọmọ Naijiria.
Bakan naa ni idajọ naa tun sọ pe gbedeke naa yoo fi araalu sinu ewu aarun Covid-19 nibi ti wọn ba ti n kora jọ pọ̀ nitori pe wọn fẹ ẹ fi orukọ silẹ fun NIN.
Ile ẹjọ si ti kọ lẹta si Minisita eto idajọ, to tun jẹ agbẹjọro agba, Abubakar Malami, lati pasẹ fun gbogbo ileesẹ ti ọrọ kan, pe ki wọn o tẹle idajọ naa.

Ṣé ìjọba Bayelsa fún darandaran Fulani ní gbèdéke ọjọ́ mẹ́rìnlá láti fi ìpínlẹ̀ náà sílẹ̀?

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Laipẹ yii ni iroyin n ja ranyin-ranyin pe awọn alaṣẹ ijọba ni Bayelsa ti fun awọn darandaran Fulani ni gbedeke ọjọ mẹrinla, lati ko aasa wọn kuro ni ipinlẹ naa, ki wọn gba oko ibomiran lọ.
Iroyin yii milẹ diẹ nitori igba akọkọ niyi ti irufẹ aṣẹ bẹẹ yoo jade lawọn agbegbe ti kii ṣe ilẹ Yoruba.
Awọn ijọba ipinlẹ kan atawọn ajijagbara kan ni ilẹ Yoruba lo n gbe igbesẹ lati le awọn darandaran Fulani kuro ni ilẹ Yoruba, tabi mojuto igbokegbodo wọn.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kàyééfì ńlá! Kí ló tún pa ọgbọ̀n Màlúù lójijì l‘Ondo?
- Ọ̀gá ológun, kò yẹ kí jàndùkú gbàkóso agbègbè kankan ní Naijiria - Buhari
- Buhari láṣẹ́ lábẹ́ òfin Naijiria lẹ́tọ̀ọ́ láti gba ìtọ́jú lókè òkun - Amòfin
- Ẹ má lọgun ‘Oduduwa Nation’ mọ́, Yorùbá ló kàn láti jẹ ààrẹ - Oluwo
- "Akíkanjú bíi Sunday Igboho ni kí Buhari gbà síṣẹ́ ológun, kìí ṣe ajẹbọ́tà"
- Wo ìgbà mẹ́fà tí Buhari rìnrin àjò lọ sókè òkun fún ìtọ́jú ara rẹ̀
- Gbọ́ àsọtẹ́lẹ̀ ìdíje àti bí o ṣe lè wo ìfẹsẹ̀wọnsẹ̀ láàrin Nàìjíríà àti ikọ̀ Lesotho
- Ó dára kí Orílẹ̀èdè Naijiria wa ní ìṣọ̀kan jú kí a pínyà lọ - Buhari
- Buhari, ààwẹ̀ gbígbà ṣú ọmọ Nàíjíríà, jọ̀ọ́ ṣètò ìdẹ̀rùn - Tinubu lọgun
- Buhari ń lọ ṣàyẹ̀wò ara ní London lásìkò táwọn dókítà fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì
Ohun ti iroyin to kọkọ jade naa sọ ni pe ijọba ipinlẹ Bayelsa ti fun awọn daranadaran fulani to wa ni ipinlẹ naa ni ọsẹ meji lati fi kuro nibẹ nitori gbọnmọgbọnmọ wahala ati ijinigbe to n wọ tọ wọn lẹyin ni ipinlẹ naa.
Amọṣa, nigba ti BBC News yoo kan si awọn alaṣẹ ijọba ipinlẹ naa, wọn ni bẹẹ kọ lọrọ ri o. ṣugbọn iroyin naa tun fẹ fara jọ ootọ diẹ.
Kọmiṣọna eto ọgbin ati ohun alumọni ni ipinlẹ Bayelsa, David Alagoa ṣalaye pe, igbimọ to n mojuto akoso ohun ọsin ni ipinlẹ naa, ṣe ipade pẹlawọn adari ẹgbẹ Miyetti Allah, MACBAN.
O ni ijọba atawọn adari ẹgbẹ naa ti fimọ ṣọkan pe wọn yoo ni awọn aṣayan agbegbe tawọn darandaran Fulani yoo maa ko maluu wọn jẹ si.
O ni wọn fi imọ ṣọkan lori idi ti awọn darandaran fi ni lati kuro ni ipinlẹ naa.
Ohun ti wọn wa fohun si ni pe, ki wọn maa lọ sawọn agbegbe ijẹko ti oyinbo n pe ni Ranching.





















