Bola Tinubu: Buhari gba 50m ọ̀dọ́ síṣẹ́ ológun láti pèsè iṣẹ́ àti kojú ìwà ọ̀daràn

Oríṣun àwòrán, The Presidency
Yoruba ni ti a ba le ewure titi, to fi kan ogiri, to ba fi yiju pada, yoo bu olowo rẹ jẹ ni.
Idi ree ti asaaju ẹgbẹ oselu APC nilẹ yii, Asiwaju Bola Ahmed Tinubu fi n lọgun tantan fun ijọba aarẹ Buhari pe aawẹ gbigba lojoojums ti su awọn ọmọ Naijiria.
Tinubu ke gbajare bẹẹ nibi idanilẹkọ ọlọdọọdun ti wọn fi sọri ọjọ ibi ọdun kọkandinlaadọrin rẹ, ikejila iru rẹ, to waye nilu Kano lọjọ Aje.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Buhari ń lọ ṣàyẹ̀wò ara ní London lásìkò táwọn dókítà fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ní ààdọ́ta ọ̀dọ́ kú lẹ́yìn àpèjẹ tí ọmọ Yahoo kan ṣe l'Akute?
- Oluwo àti Alaafin ṣe ìpàdé lórí ìdásílẹ̀ orílẹ̀-èdè Oduduwa, àbọ̀ ìpàdé nàá rè é
- Ọkọ̀ típà pa ọlọ́kadà àti akẹ́kọ̀ọ́ mẹ́rin ní Ibadan
- Kí ló dé tí Osinbajo, Aregbesola, Gbajabiamila atawọn mii kò fi péjú sí ọjọ́ ìbí Tinubu?
- A ti kẹ́kọ̀ọ́, a ti kọ́gbọ́n, lá ṣe ń fa ojú ọ̀dọ́ mọ́ra láti dìbò ní 2023 - PDP pariwo síta
Akori idanilẹkọ naa ni 'Okun to so wa pọ ni ọrọ ajọni wa ati pataki ajọsepọ apapọ fun idagbasoke ati iserere'.
Tinubu ni akoko yii kii se akoko sọwona tabi se ọrọ aje ni koko wọn le, akoko to yẹ ka pese oniruuru anfaani ree.
"Bi orilẹede Amẹrika ba n na owo gọbọi lai wo ẹyin wo, ti wọn si tun n beere owo si fun ipese awọn ohun eelo amayedẹrun ati ipese isẹ.
Ki wa lo de ti ẹyin yoo fi ni ka maa gba aawẹ nigba ti ida mẹtalelọgbọn awọn ọdọ ninu ọgọrun ko ni isẹ lọwọ."
Tinubu fikun pe ọjọ pẹ tawọn ọmọ Naijiria ti n gbaawẹ, bẹẹ si ni airisẹse lo sokunfa iwa idunkookomọni ati ijinigbe atawọn iwa ọdaran miran.
O wa rọ ijọba apapọ lati gba awọn ọdọ to to aadọta miliọnu sisẹ ologun, ki a le koju iwa itajẹsilẹ, idunkooko mọni atawọn iwa miran to n dunkokoo mọ eto aabo wa.
A ti kẹ́kọ̀ọ́, a ti kọ́gbọ́n, lá ṣe ń fa ojú ọ̀dọ́ mọ́ra láti dìbò ní 2023 - PDP pariwo síta

Ọrọ to ti ẹnu Kọla Ologbodiyan, akọwe ipolongo fun ẹgbẹ oṣelu PDP lorilẹede Naijiria jade niyi nigba to fi n ba BBC News Yoruba sọrọ.
Ologbondiyan lo salaye lori bi nnkan ṣe n lọ si lagbo oṣelu orilẹede Naijiria ati igbesẹ ti ẹgbẹ oṣelu naa n gbe lati ṣe koriya fawọn ọdọ ati lati pa ina gbogbo aawọ lagbo rẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Sunday Igboho, àwa Yorùbá lókè Ọya kò wálé, a kò fẹ́ Oduduwa Republic - YWG
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ní ààdọ́ta ọ̀dọ́ kú lẹ́yìn àpèjẹ tí ọmọ Yahoo kan ṣe?
- Ọ̀dọ́mọdé olórin ra pósí fún ara rẹ̀ láì tíì kú, ariwo sọ
- Buhari kò ṣèlérí pé Naira kan yóò bá Dọ́là kan dọ́gba - Iléeṣẹ́ ààrẹ
- Àwọn gbajúmọ̀ faraya lórí alágbe tó kọ́ ilé mẹ̀rin, ra mọ́tò mẹ́ta
- Sunday Igboho tutọ́ sókè, fojú gbàá fáwọn èèyàn tó pè é ní oníjìbìtì
- Ìjọba Ọṣun pàṣẹ kí Olùdarí àjọ Amotekun l'Ọṣun wá rojọ́ nítorí ọ̀rọ̀ tó kọ sí Facebook nípa àwọn olùrànlọ́wọ́ gómìnà
- Òjò ìfẹ́ rọ̀, Miss Pepeiye ṣe ìyàwó pẹ̀lú agbábọ́ọ̀lù Super Eagles, Peter Olayinka
- Wo owó àti ìsinmi tí ìjọba yóò san tí oyún bá bàjẹ́ tàbí bímọ kú
- Kí ló dé tí ẹsẹ̀ Tinubu fi yọ̀, tó fẹ́ ṣubú ní Kaduna?
O ni gbogbo aṣiwaju ati ọmọlẹyin gbogbo ninu ẹgbẹ oṣelu naa lo mọ pe ikọsẹ nlanla ni bi ẹgbẹ oṣelu APC ṣe gbajọba ni Naijiria.
Bẹẹ lo tun mẹnuba iriri awọn ọmọ orilẹede Naijiria lati igba ti iṣejọba ẹgbẹ oṣelu APC ti bẹrẹ lọdun 2015.
Ọgbẹni Kọla Ologbodiyan ni ohun ti ẹgbẹ oṣelu APC tawọn ọmọ Naijiria 'gbe wa lati wa ṣeranwọ fun wọn' da silẹ gan, ju eyi ti araalu ti n kọminu le lori lati iṣaaju.
O ni ẹgbẹ oṣelu APC wa lati wa gba agbara ni lai ni imọ ati dari ilu, ṣugbọn ni ipadabọ PDP, araalu yoo mọ pe wọn ti lọ kọ ọgbọn wa.

Oríṣun àwòrán, Pdp
O wa ṣalaye pe, ẹgbẹ oṣelu PDP ti n ṣe agbeyẹwo bi adinku ṣe lee de ba iye owo ti awọn ọdọ yoo maa ra fọọmu idije ẹgbẹ oṣelu naa.
Ṣaaju eto idibo apapọ ọdun 2019, miliọnu mejila naira (N12 million) lawọn to dije fun ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu PDP san.
Awọn to dije fun ipo gomina ipinlẹ san miliọnu mẹfa naira (N6 million), awọn to dije fun ile aṣofin apapọ san miliọnu mẹta abọ Naira (N3.5 million naira) ile asofin ipinlẹ san ẹgbẹrun lọna ẹgbẹta naira (N600, 000).
Agbẹnusọ fun ẹgbẹ oṣelu PDP naa ni, ara awọn igbesẹ tuntun ti awọn n gbero le lori ni riri daju pe owo fifi ifẹ han lati dije nikan lawọn ọdọ n san, gẹgẹ bi wọn ṣe ṣe fawọn obinrin.
O ni gbogbo igbesẹ wọnyii lo ṣi wa labẹ ijiroro lawọn ẹka gbogbo lẹgbẹ oṣelu naa.






















