Oduduwa Republic: Oba Yoruba Bauchi ní wíwọ ara wọn Yorùbá àti Hausa kò ní kí Yorùbá má ya kúrò ní Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, Amani
Oba Yoruba ni Bauchi, Alhaji Tirimisiyu Adegoke ti fesi si ọrọ ọmọ ẹgbẹ Yoruba, Yoruba welfare group (YWG) to sọ pe awọn ko fẹ Oduduwa Republic.
Oba Yoruba Bauchi sọ pe lootọọ ni Hausa ati Yoruba ti wọ inu ara wọn, amọ iyẹn ko ni ki Yoruba maa yapa kuro lara orilẹede Naijiria.
Oba Adegoke ni ti Yoruba ba maa lọ, wọn ni lati joko pẹlu awọn Hausa ki wọn jọ sọ asọyepọ lọna ti ko ni fa ija.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Sunday Igboho, àwa Yorùbá lókè Ọya kò wálé, a kò fẹ́ Oduduwa Republic - YWG
- Ọ̀dọ́mọdé olórin ra pósí fún ara rẹ̀ láì tíì kú, ariwo sọ
- Buhari kò ṣèlérí pé Naira kan yóò bá Dọ́là kan dọ́gba - Iléeṣẹ́ ààrẹ
- Àwọn gbajúmọ̀ faraya lórí alágbe tó kọ́ ilé mẹ̀rin, ra mọ́tò mẹ́ta
- Sunday Igboho tutọ́ sókè, fojú gbàá fáwọn èèyàn tó pè é ní oníjìbìtì
- Ìjọba Ọṣun pàṣẹ kí Olùdarí àjọ Amotekun l'Ọṣun wá rojọ́ nítorí ọ̀rọ̀ tó kọ sí Facebook nípa àwọn olùrànlọ́wọ́ gómìnà
- Òjò ìfẹ́ rọ̀, Miss Pepeiye ṣe ìyàwó pẹ̀lú agbábọ́ọ̀lù Super Eagles, Peter Olayinka
- Wo owó àti ìsinmi tí ìjọba yóò san tí oyún bá bàjẹ́ tàbí bímọ kú
- Kí ló dé tí ẹsẹ̀ Tinubu fi yọ̀, tó fẹ́ ṣubú ní Kaduna?
''Ogun ni emi ko fẹ, ti aṣoyepọ ba le waye, Yoruba ni lati fi ọgbọn ṣe ọrọ naa ko maa ba mu wahala dani.
Otitọ ni pe ọpọ Hausa ti fẹ Yoruba ni iyawo, awọn Yoruba naa ti fẹ Hausa, a ti wọ ara ra ṣugbọn a gbọdọ sọ asọyepọ,'' Oba Adegoke lo sọ bẹẹ.
Oba Yoruba Bauchi ko ṣai sọ pe oun ko mọ ohun kan nipa ẹgbẹ Yoruba YWG ti wọn sọrọ yii gan an.
O fikun ọrọ rẹ pe, ko si ọba Yoruba ni Kaduna ti ẹgbẹ YWG ti bawọn akọroyin sọrọ.
Sunday Igboho, àwa Yorùbá lókè Ọya kò wálé, a kò fẹ́ Oduduwa Republic - YWG

Oríṣun àwòrán, Abdulhakeem Adegoke Facebook
Ẹgbẹ ọmọ Yoruba nipinlẹ mọkandinlogun to wa lapa ariwa orilẹede Naijiria, Yoruba welfare group (YWG) ti sọ pe awọn ko faramọ yiyapa kuro lara Naijiria, lati da Oduduwa Republic silẹ.
Nibi ipade awọn akọroyin to waye lọjọ Aiku niluu Kaduna, aarẹ ẹgbẹ YWG, Abdulhakeem Adegoke sọ pe, awọn Yoruba to wa nilẹ Hausa ko fẹ orilẹede mii lẹyin orilẹede Naijiria.
Ọgbẹni Adegoke ṣalaye pe, awọn Hausa ti gbawọn Yoruba tọwọ tẹsẹ lati igba tawọn ti n jọ n gbe papọ.
''A n sọrọ gẹgẹ bi aṣoju gbogbo ọmọ Yoruba to wa ni ipinlẹ mọkandinlogun nilẹ loke Oya pe, ọmọ Naijiria ni wa, a ko si si lara awọn to n beere fun Oduduwa Nation.
Awọn Yoruba atawọn Hausa ti wọ inu ara wa wọn, awọn baba nla wa nilẹ Yoruba ti wa nilẹ Hausa fun bii igba ọdun.
Ọpọ ninu wa lo ti fẹ awọn Hausa gẹgẹ ọkọ tabi iyawo, bakan naa lawọn Hausa ti fẹ Yoruba.
Ati pe, okoowo wa nilẹ Hausa ju tiriliọnu marun un lọ, gbogbo awa Yoruba ti a wa nilẹ Hausa si tun ju ipinlẹ mẹta nilẹ Yoruba lọ.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post
Nitori naa, a ko le lọ darapọ mawọn ti ko bikita nipa ẹmi ati dukia wa lasiko yii,'' Ọgbẹni Adegoke lo ṣalaye bẹẹ.
Eekan ilẹ Yoruba, Ọjọgbọn Banji Akintoye ati ajijagbara Sunday Adeyemo, ti ọpọ mọ si Sunday Igboho wa lara awọn aṣaaju to n beere fun yiyapa Yoruba kuro lara Naijiria lati da Oduduwa Nation silẹ.




















