Yoruba Nation: Kò yẹ kí èèyàn tó kàwé bíi Akintoye lè tako gómìnà lórí ọ̀rọ̀ tó sọ nípa ìpínlẹ̀ rẹ̀ - Akeredolu

Akeredolu

Oríṣun àwòrán, Rotimi Akeredolu Aketi

Gomina ipinlẹ Ondo, Arakunri Rotimi Akeredolu ti fi ohun ranṣẹ si agba ilẹ Yoruba, Ọjọgbọn Banji Akintoyin lori awuyewuye to n waye lori ọrọ Yoruba Nation.

Ninu atẹjade kan ti olubadamọran pataki fun Akeredolu lori akanṣe iṣẹ, Doyin Odebowale fi lede, o ni iyapa ti Akintoye atawọn ẹmẹwa n lọgun yoo lẹyin.

Akeredolu sọ pe o ṣeni laanu pe eeyan to kawe, to si tun jẹ ọlọpọlọ pipe bii Akintoye le sọ pe gomina ipinlẹ ko laṣẹ lati sọrọ lorukọ awọn eeyan rẹ.

Àkọlé fídíò, Báa ṣe lọ́pọlọ tó, ẹnu Yorùbá ò kò, ọgbọ́n táa gbúdọ̀ dá rèé - Ìpàdé àgbààgbà Yorùbá n'Ibadan

O ni "a ri atẹjade ti awọn kan ti wọn pe ara wọn ni Ilana Omo Oodua gbe jade, eyii to lodi si ọrọ Gomina Akeredolu lori ọrọ ijagbara ilẹ Yoruba."

"Ko yẹ ki a da si ọrọ naa, ṣugbọn a ni lati fesi lẹyin ọrọ ti wọn sọ pe Ọjọgbọn Banji Akintoye sọ, niṣe lo dabi ẹni pe o ṣoro fun Akintoye yii lati ri nnkan lọna miran yatọ si nipa ẹlẹyamẹya."

Aketi

Oríṣun àwòrán, Aketi

Atẹjade ọhun tẹsiwaju pe, ijọba ipinlẹ Ondo ko sọ pe ki ẹnikẹni ma gbe igbesẹ lati dari ẹya Yoruba, ṣugbọn o jẹ ohun iyalẹnu pe wọn lero pe ijagbara wọn ọhun ko ni mu itajẹsilẹ lọwọ.

O ni "Ilẹ Amẹrika ni Akintoye wa lasiko ijọba ologun nigba ti awọn to ni ifẹ Naijiria lọkan ja kii nnka le dara lọjọ naa lọhun, o jẹ ohun to buru jọjọ lati sọ Naijiria sinu idarudapọ bayii nitori ijangbara kan.

Àkọlé fídíò, Bí Oduduwa Republic bá bẹ̀rẹ̀, a ò ní ṣe aburú fún àwọn tó takò wá, ìlànà ààtẹ̀lé rèé - Banji Akintoye

Akeredolu ni o jẹ ohun to buru jai lati maa gbe igbesẹ lati sọ orilẹ-ede Naijiria ti iṣọkan wa di eyii ti awọn eeyan inu rẹ ko ni gbọ ti ara wọn mọ.

O fikun pe, "ẹ jẹ ki a sọ fun yin lẹẹkan si, ipinlẹ Ondo ko ni kopa ninu ija ominira kankan"

"Ti Akintoye ba mọ pe o wu oun lati maa ṣe aṣoju awọn eeyan, ni ṣe lo yẹ ko jọwọ ara rẹ fun wọn."

O pari atẹjade naa pe awọn eeyan ipinlẹ Ondo kii ṣe omugọ, wọn mọ ohun to tọ lati ṣe, wọn si mọ ọrọ ẹni to yẹ ki wọn tẹle.

Àkọlé fídíò, 'Èmi àti ìyàwó mi ti ń gbé pọ̀ nínú ìgbéyàwó wa fún 60 years', ẹ wá kọ́ ẹ̀kọ́ lẹ́nu àgbà méjì
Àkọlé fídíò, 'Òde ìnáwó làwọn èèyàn ma ń rò bí wọ́n bá rí Ankara, ìgbà tí wọ́n rí i lára àga tí mo ṣe, ẹnu wọn ò padé mọ́'