NDLEA visa clearance: Ọwọ́ agbófinró tẹ obìnrin tó gbé 'cocaine' sínú ojú ara rẹ̀ l'Abuja

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ajọ to n gbogun ti lilo egboogi oloro ni Naijiria, NDLEA, ti fi ṣikun ofin mu obinrin ọmọ orilẹ-ede Chad kan pẹlu egboogi oloro ninu oju ara rẹ.
Wọn gba obinirin naa mu ni papakọ ofurufu to wa niluu Abuja nibi to ti n gbiyanju lati tẹkọ leti lọ si Addis Ababa.
Agbẹnusọ NDLEA, Femi Babafemi sọ fun awọn akọroyin pe, wọn ti bẹrẹ iwadii lori iṣẹlẹ naa.
- Akintoye sá lọ Amẹrika lásìkò ìjọba ológun, ó wá fẹ́ da Naijiria rú báyìí - Akeredolu
- Kí ló lè fàá kí Yomi Fabiyi àti PA rẹ̀ máa fẹnu ko ara wọn l'ẹ́nu?
- Oríire déé! Ilé aṣòfin ti buwọ́lu Adewale Adeyemo ẹni ọdun 39 bíi igbákejì adarí ẹ̀ka ètò ìsúná ní ilẹ̀ Amẹrika
- Ọ̀jọ̀gbọ́n fásítì tó yì èsì ìbò fún Akpabio yóò ṣẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́ta, ẹkọ táa lè kọ́ rèé fún ará yòókù
Babafemi sọ pe iroyin kan tun tẹ awọn lọwọ pe ọkunrin kan ti gbe egboogi kokeni wọ ipinlẹ Eko.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, obinrin ti wọn mu yii sọ pe ọkunrin naa lo ni ki oun gbe aadọta kokeni mi, ṣugbọn nigba ti o ṣoro fun oun ni wọn da bi ọgbọn pe ki oun ti mejidinlogun ninu rẹ bọ oju ara.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ṣaaju ni wọn ti kọkọ mu obinrin naa to jẹ onidiri ni Italy lọdun 2016 lasiko to n lọ si Libya.
Obinrin ọhun ti orukẹ rẹ n jẹ Tarmadji ni oun wa si Naijria lati wa pa owo ti oun yoo fi gba ṣọọbu onidiri lẹyin ti nnkan le koko ni Italy nitori ajakalẹ arun Corona.
O pari ọrọ rẹ pe €10,000 ni wọn yoo fun oun to ba jẹ pe oun ṣaṣeyọri ninu kiko oogun oloro naa jade ni Naijiria.
- Arákùnrin òníbálòpọ̀ akọsákọ yarí mọ́ ìjọba lọ́wọ́ lórí àwọn Ìbejì rẹ̀ tí wọ́n bẹ́gi dínà ìrìnàjò wọn
- Ẹ kó àwọn ọmọ yín lọ sílé ẹ̀kọ́ àwọn Musulumi tí ẹ bá fẹ́ kí wọ́n máa lo Hijab - Oyedepo
- Àìgbọ́ra ẹni yé ẹ̀yà Yoruba ló ń ṣe ìdíwọ́ fún òmìnira wa - Àkójọpọ̀ ẹgbẹ́ Yoruba l'àgbáyé
- Ṣé ǹkan ọmọkùnrín rẹ ò ní padà kéré báyìí? Wo tuntun tí onímọ̀ Sáyẹ̀nsì gbéjáde
- Àlùwàlá ológbòò Tinubu pẹ̀lú ₦50m tó f'áwọn ará Katsina, ọgbọ́n àti kẹ́ran jẹ nínú ìbò 2023 ni
- Christopher Sapara-Williams, ọmọ Ijesha tó di agbẹjọ́rò àkọ́kọ́ tó jẹ́ ọmọ Naijiria














