Kayode Fayemi 2023 ambition: Mo ṣì níṣẹ́ púpọ̀ láti ṣe ní ìpìnlẹ̀ Ekiti ká tó máa sọ̀rọ̀ọ̀ ìbò ààrẹ 2023

Oríṣun àwòrán, kfayemi
Gomina ipinlẹ Ekiti to tun jẹ adari gbogbo awọn gomina orilẹede Naijiria, Kayode Fayemi ti fesi lori gbogbo ohun tawọn eeyan n sọ pe o fẹ du ipo aarẹ.
Gẹgẹ bi ọpọlọpọ ọmọ Naijiria ṣe maa n fọ lesi lori awọn nkan ti Fayemi ba sọ lasiko yii pe aluwala olongbo rẹ, ọgbọn ati ko ẹran jẹ lọdun 2023 gẹgẹ bi aarẹ ni.
Ẹwẹ, lori eto ifọrọwanilẹnuwo kan to ṣe pẹlu ileeṣẹ iroyin Channels tv kan "Hard Copy ti wọn ṣe lọjọ Ẹti, ọgbẹni Fayemi ni oun ṣi n dupẹ lọwọ awọn eeyan oun nipinlẹ Ekiti pe wọn nigbagbọ ninu oun lati di gomina wọn.
Fayemi n da atọkun lohun lai fẹ mẹnu ba a boya oun fẹ dije du ipo aarẹ lọdun 2023 abi bẹẹ kọ, ṣe lo ni iṣẹ ṣi ku.
- Wo ìhùwàsí Buhari, àwọn èèkàn Nàìjíríà àti ibòmíì tó ti gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19
- Ṣé lóòtọ́ ni Kayode Fayemi, gómìnà ìpínlẹ̀ Ekiti fẹ́ du ipò ààrẹ orílẹ̀èdè Nàìjíríà?
- Fayemi ló tó gbangba sùn lọ́yẹ́ láti jẹ ààrẹ Nàìjíríà lọdún 2023- Àwọn lọ́balọ́ba Ekiti
- Àwọn kókó ohun tó wà nínú lẹ́tà tí Aláàfin kọ sí Fayemi rèé
- Ṣọ́ra fún ètò àwọn Darandaran, àwọn ọmọ Ekiti nílẹ̀ òkèèrè kìlọ̀ fún Fayemi
- Fayose sí Fayemi: Ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ìpànìyàn tó wáyé níbi ìdìbò Ekiti yóò bèrè
Gomina Fayemi ni "ko si oloṣelu ti wọn yoo fun lanfani lati du ipo aarẹ Nainjiria ti yoo wọn ọn danu sẹyin eti.
O rẹrin keekee lati dahu si ibeere yii ti atọkun ṣaa n tiraka ko le fesi tori ko fẹ fesi sii.
"Mo n rẹrin tori gbogbo igba ni wọn maa n bi mi ni ibeere yii... mi o mọ oloṣelu kankan to mọ ohun to n ṣe ti wọn yoo fi anfani ati dari orilẹede lọ ọ ti ko ni dan an wo, amọ a o tii de bẹyẹn".
Ẹwẹ, Fayemi to jẹ ọkan pataki lara awọn to ri aridaju ituleka igbimọ amuṣya ẹgbẹ oṣelu All Progressive Congress kọ lati sọ oju abẹ nikoo boya oun yoo gbe apoti ibo aarẹ lọdun 2023.
Ṣugbọn Fayemi ni pipari saa oun gẹgẹ bii gomina ipinlẹ Ekiti gangan ni oun gbajumọ eyi ti yoo pari losu kẹwa ọdun 2022.
"Mo ni iṣẹ lọwọ, ka si ma parọ mo dupẹ gidi lọwọ awọn eeyan ipinlẹ Ekiti ti wọn fun mi ni anfani lati dari ipinlẹ naa lẹẹmeji mo dẹ ṣi ni ọpọlọpọ nkan ti mo fẹ ṣe nibẹ".
Fayemi ni nitorina, ọjọ iwaju yoo tọju ara rẹ atipe ohun ti oun mọ bayii ni pe, iṣ wa lọwọ oun bayii.
Nigba to n da si ọrọ lilo Hijab lawọn ileewe ẹlẹsin to n fa rogbodiyan ni ipinlẹ Kwara, gomina Kayode Fayemi ni o yẹ ki orilẹede Naijiria fa ọwọ ẹlẹsinmẹsin to duro gbọingbọin soke wa silẹ patapata.
"O ṣeeṣe ko jẹ ọwọ iṣẹ ati idamu kan lo n fa iru nkan to n ṣẹlẹ yii".
















