2023 elections: Àwọn lọ́balọ́ba Ekiti ní Fayemi kójú òṣùnwọ̀n láti jẹ ààrẹ Nàìjíríà lọ́dún 2023

Oríṣun àwòrán, Facebook/Kayode Fayemi
Ẹgbẹ lọbalọba ni ipinlẹ Ekiti ti buwọlu Gomina Kayode Fayemi fun idibo aarẹ ọdun 2023 ni orilẹede Naijiria.
Awọn ọba alaye ọhun fẹnu ko nibi ipade ti wọn ṣe ni Ado-Ekiti lọjọ kẹrinlelogun oṣu keji pe Fayemi lo to gbangba sun lọyẹ lati tukọ orilẹede Najiria.
Awọn ọba alaye sọ pe awọn yoo gbe igbimọ kan dide eyi ti yoo rọ Fayemi lati dije fun ipo aarẹ ninu idibo gbogbogbo ọdun 2023 ni Naijiria.
- Kí ló ṣe ọkùnrin yìí tó dédé ń sá lọ láàrin ìgboro ní ìhòhò ọmọlúàbí?
- Fifi òfin de dída máàlù kiri kò lè dẹ́kun àawọ̀ láàrin àwọn àgbẹ̀ àti darandaran àyàfi... - Fayemi
- Fayemi: Àfàìmọ̀ kí ìjọba má bá àwọn jàndùkù ajínigbé sọ̀rọ̀, àmọ́ onímọ̀ nípa ètò àbò ní ...
- Ọkọ mi ni èmi ni mo sòkùnfa ǹkan tó ṣẹlẹ̀ sí Faizat lati inú oyún- Ìyá Faizat
- 'Wọ́n ní kí n fún Faizal ní màjélè, abiyamọ ni mí, tí Ọlọ́run ò bá mú u lọ, mi ò ní pa á'
- Òní ni ìsìnkú àwọn akọni tó bá ìjàmbá ọkọ̀ Bàálù lọ ní Abuja
- Ọ̀rọ̀ aàbò ní Nàìjíríà ti di kí olórí dorí ẹ mú- Femi Falana
- Kí ni ìtumọ̀ pé Mide Funmi Martins kò sí níbi tí Damilare àti Shina Peters ti parí ìjà?
Awọn lọbalọba Ekiti sọrọ yii di mimọ lẹyin ti wọn gbọrọ lẹnu ẹgbẹ kan ti akori rẹ n jẹ "Our Belief Project" ti Ọgbẹni Aloba Abejide ṣe agbatẹru rẹ.
Ọgbẹni Abejide lo kọkọ rọ awọn ọba alaye naa lati ba gomina ipinlẹ Ekiti sọrọ pe ko kede erongba rẹ lati dupo aarẹ lọdun 2023 ni kiakia.
Alaga awọn igbimọ lọbalọba ipinlẹ Ekiti, Alawe ti Ilawe-Ekiti, Ọba Adebanji Ajibade Alabi Afuntade Kinni sọ pe eeyan bi Fayemi ti ori rẹ pe ti o si ni okun lo le dari Naijiria bayii pẹlu oriṣiiriṣii iṣoro to n koju orilẹede yii bayii.
''Fayemi wa lara awọn to doju ija kọ awọn ologun lati rii pe Naijiria pada si ijọba awarawa.
Bakan naa Fayemi tun ti gboye ni fasiti lori ogun, nitorinaa oun lo le wa ojutu si eto abo to mẹhẹ ni Naijiria to ba le di aarẹ lọdunm 2023, Alawe lo sọ bẹẹ.
Oba Afuntade Kinni fikun ọrọ rẹ pe o ti to asiko ki ọmọbibi Ekiti naa jẹ aarẹ orilẹede Naijiria lẹyin ti wọn ti ran awọn ẹya mii lọwọlọwọ lati doke.
Alawe ni Sultan ilu Sokokto Abubakar S'aad ati Gomina Nasir El-Rufai ipinlẹ Kaduna gan an ti sọ tẹlẹ pe awọn ni igbagbọ ninu Fayemi.
Oba alaye naa rọ gbogbo awọn oloṣelu nipinlẹ Ekiti lati gbaruku ti Fayemi lọdun 2023.















