Lagos one-day governor: Gómìnà Sanwo-Olu gba pẹ̀lú gómìna ọlọ́jọ́ kan fún ìpínlẹ̀ Eko dámọ̀ràn lórí ìdàgbàsókè ètò ẹ̀kọ́

Oríṣun àwòrán, Twitter/ babajide sanwo-olu
Gomina Babajide Sanwo-Olu ti ipinlẹ Eko ti gba gomina tuntun fun ipinlẹ naa, Omidan Ẹniọla Ajala lalejo lọfisi rẹ.
Omidan Ẹniọla Ajala ni gomina ọlọjọ kan fun ipinlẹ Eko lẹyin to gbegba oroke nibi idije 'Ta n mọ ọ?' New Era Spelling Bee Competition fawọn akẹkọọ ileewe girama ni ipinlẹ naa.
Lasiko ipade rẹ pẹlu Omidan Ajala atawọn ọmọ igbimọ iṣejọba rẹ, gomina Sanwo-Olu ni idagbasoke eto Ẹkọ ko ni rẹyin ninu eto idagbasoke isọdọtun ti iṣejọba oun gbe kari eyi to pe ni 'THEMES agenda'

Oríṣun àwòrán, Lagos state Government
- Ohun tí Ọlọ́pàá mọ̀ rèé nípa bóyá Agbébọn jí ọmọ ìjọ RCCG mẹ́jọ tó ń lọ jèrè ọkàn gbé!
- Akintoye sá lọ Amẹrika lásìkò ìjọba ológun, ó wá fẹ́ da Naijiria rú báyìí - Akeredolu
- Ọwọ́ agbófinró tẹ obìnrin tó gbé 'cocaine' sínú ojú ara rẹ̀ l'Abuja
- Oríire déé! Ilé aṣòfin ti buwọ́lu Adewale Adeyemo ẹni ọdun 39 bíi igbákejì adarí ẹ̀ka ètò ìsúná ní ilẹ̀ Amẹrika
- Ọ̀jọ̀gbọ́n fásítì tó yì èsì ìbò fún Akpabio yóò ṣẹ̀wọ̀n ọdún mẹ́ta, ẹkọ táa lè kọ́ rèé fún ará yòókù
- Ìdí tí NIN rẹ fi ṣe pàtàkì láti forúkọsílẹ̀ fún ìdánwò JAMB 2021 rèé
O ni ijọba ipinlẹ Eko yoo tubọ maa rii daju pe ayika ikẹkọ ni ipinlẹ naa tubọ ṣi n mu ki eto ẹkọ o dun un kọ fawọn akẹkọọ.
O wa kan sara si omidan Ajala fun ijafafa, iṣọkan akin ati iduro ṣinṣin rẹ pẹlu amọran pe oun atawọn ọmọ igbimọ rẹ ko gbọdọ faye gba igbesẹ ṣiṣe akoso ipinlẹ Eko fun ọjọ kan lati ko si wọn lori to bẹẹ ti wọn yoo fi yẹsẹ kuro lojuna idagbasoke ẹkọ wọn.

Oríṣun àwòrán, Twitter/ babajide sanwo-olu
Omidan Ẹniọla Ajala to jẹ gomina ọjọ kan ni ipinlẹ Eko fun ọdun 2021 jẹ akẹkọọ ileewe girama Lafiaji Senior High school, Lagos Island.
Awọn ọmọ igbimọ rẹ yooku ni Grace Ikhariale lati ileewe girama TinCan Island Senior High School, Tolu , to jẹ igbakeji gomina; Oluwatosin Akinbọdewa lati Iworo Ajido Senior Secondary School, Badagry ni olori ile aṣofin; Eunice Adedọtun lati Agbẹdẹ Senior School Ikorodu ni kọmiṣọna eto ẹkọ, ti Ekene Ezeunala lati Meiran Community High school jẹ alaga igbimọ tẹlekoto lori eto ẹkọ nile aṣofin ipinlẹ naa.
Ninu ọrọ rẹ lasiko to fi n lewaju ipade ọlọsọọsẹ ti igbimọ iṣakoso ijọba ipinlẹ Eko, gomina ọlọjọ kan ni ipinlẹ Eko fun ọdun 2021, omidan Ẹniọla Ajala dupẹ pupọ lọwọ gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu fun ọla, ẹyẹ ati iyi to bu fun awọn akẹkọọ to bori nibi idije 'Ta n mọ ọ?' naa.

Oríṣun àwòrán, Twitter/ babajide sanwo-olu
Bakan naa lo gboriyin fun gomina Sanwo-Olu lori bi o ṣe moju to ọrọ ajakalẹ arun COVID-19 ni ipinlẹ naa, to si rọ awọn akẹkọọ lati maa foju si ẹkọ wọn ki wọn lee bori awọn ipenija gbogbo ni ọna wọn.
Bakan naa ni 'gomina' Ẹniọla Ajala ke si gomina Sanwo-Olu pe ko tubọ pese awọn ohun elo amayedẹrun lawọn ileewe tawọn akẹkọọ to bori idije naa ti jade wa to si tun rọ ijọba lati ṣeto ẹbun to jọju fun awọn obi oun, to gboriyin fun pẹlu bi wọn ṣe tọ ọ ni ọna gbogbo to yẹ.













