Yoruba Nation: Ẹ̀yin òṣìṣẹ́ ìjọba, ìyà ń bọ̀ fúń yín bí Nàìjíríà bá túká pẹ́rẹ́ - Oluwo

Oríṣun àwòrán, Oluwo
"Owo oṣu oṣiṣẹ, ipinlẹ Eko nikan lo lẹmi ẹ lai duro de ijọba".
Oluwo ti ilu Iwo, Ọba Abdulrosheed Akanbi ti kilọ pe awọn oṣiṣẹ ijọba ẹkun Guusu - Ila Oorun ni yoo fara gba bi ipinya ba de ba orilẹede Naijiria.
Ọba Abdulrosheed wa rọ awọn ọdọ ilẹ Yoruba to n ja fun idasilẹ Yoruba Nation pe ki wọn na suuru si i.
- Olórùka ti gba òrùka, n kò sí lórí àtẹ mọ́, ẹ má sanwó láti fẹ́ mi - Oluwo figbeta
- Oluwo, tí wọ́n bá rán ọmọ níṣẹ́ ẹrú, kó fi t'ọmọ jẹ - Gani Adams
- Tó bá dá Gani Adams lójú, kó dárúkọ àwọn ọ̀dàlẹ̀ inú Yoruba Nation - OPC New Era
- Ẹ̀yin aṣaájú APC, ẹ́ kábáàmọ̀ ìpinnu tẹ ṣe lórí ìdásílẹ̀ Yoruba Nation - Akitoye
- Bíi ti UK, USA, Germany, France lẹ ó lè ṣe ẹ̀sìn tó bá wù yín yàlàyòlò ní orílẹ̀èdè Yorùbá Nation - Igboho
Oluwo tu ọrọ yii sita nibi eto ti gomina ipinlẹ Osun, Gboyega Oyetola ti ṣe agbekalẹ iwe ilana aato fun awọn ọdọ eyi to waye ni Oṣogbo, olu ilu ipinlẹ Osun.
Ọba Oluwo latilẹ ko figba kankan ti ija fun Yoruba Nation lẹyin ti ko si fi bo ninu awọn atẹjade rẹ.
Nibi eto naa, Oluwo ti Iwo kan sara si ijọba gomina Oyetola pe o ni eto rere fun awọn ọdọ ni ipinlẹ naa o si rọ awọn ọdọ lati pawọpọ pẹlu ijọba ki wọn lee ṣe iṣẹ daadaa fun wọn ju ki wọn maa jijagbara fun ituka kiri.
Oba Abdulrosheed sọ ninu ọrọ rẹ pe ipinlẹ kan ṣoṣo to lee da san owo oṣu awọn oṣiṣẹ rẹ lai duro de ijọba apapọ ni ipinlẹ Eko.
"Awọn ipinlẹ ẹkun Guusu - Ila Oorun to ku o lee san owo awọn oṣiṣẹ wọn bẹ si ni awọn to wọpọ nibẹ, oṣiṣẹ ijọba ni wọn".
- Aàrẹ Muhammadu Buhari gba àmì ẹ̀yẹ Adarí tó dára jùlọ
- UNILAG jáwé lọ gbélé ẹ fún àwọn olùkọ̀ méjì tí BBC tú àṣírí wọn nínú fíìmù 'Sex For Grades'
- Ó yẹ ka fura sí iṣẹ́ tí wọ́n rán Twitter wa ṣe ní Nàìjíríà, ejò fẹ́ lọ́wọ́ ńńú - Lai Mohammed
- Agbébọn pa ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá nígbàkan rí, Christopher Deja
- Lẹ́kṣọ́rà fásitì FUOYE kan tún kó sí gbaga ẹ̀sùn aṣemáṣe pẹ̀lú akẹ́kọ̀ọ́
















