FUOYE Sexual harassment: Fásitì FUOYE pàṣẹ lọ rọọ́kún nílé fún lẹ́kṣọ́rà tó ṣe aṣemáṣe pẹ̀lú akẹ́kọ̀ọ́

Oríṣun àwòrán, other
Awọn alaṣẹ Fasiti apapọ nilu Ọyẹ Ekiti, FUOYE ti ni ki olukọ agba kan nibẹ o lọ rọ ọ kun nile lori ẹsun pe o n na ọwọ aṣemaṣe ibalopọ si ọkan lara awọn akẹkọọ ni ileewe naa.
Olukọ naa ti wọn pe orukọ rẹ ni Ọmọwe Mbachaga wa pẹlu ẹka imọ nipa tiata.
Oun ni iroyin nile ẹkọ giga fasiti naa ni wọn ni igbimọ tẹẹkoto ti awọn alaṣẹ ẹka ẹkọ imọ nipa Ọrọ ẹda ati ihuwasi ọmọniyan nileẹkọ giga fasiti naa gbe kalẹ rii pe ọwọ rẹ ko mọ lori awọn ẹsun ti wọn fi kan an.
- Ọwọ́ ikọ̀ Amọtẹkun ba Mutiu Abdul-Rasheed, afurasí tó ń ta ẹ̀yà ara èèyàn ní Ibadan
- Wo bí àwọn arúgbó ṣe le jẹ́ ìgbádùn ètò tí Buhari fi lọ́lẹ̀ fún wọn
- Èrò Akeredolu ni yẹ́n, àwa aṣòfin á ṣẹ̀sẹ̀ jókòó láti yọ tàǹda kúrò nínú ìrẹsí nígba tó bá ya- Senetọ Ajibola
- Òṣìsẹ̀ 170 tí Ajimobi lé ni Lautech ni ń o gbà padà, owó osù márun wọ́n yoo di sísan- Gómínà Oyo
- Nǹkan kò burú tó báyìí ní ọgbọ̀n ọdún sẹ́yìn tí mo kọrin pé kí Ọlọ́run bá wa tún Nàijíríà ṣe- Funmi Aragbaye
- Àwọn ọ̀dọ́ lé kábíyèsí jáde láàfin l'Ondo
- A ti rí ọmọ ilé kéú 11 míì nínú àwón tí agbébọn jí gbé ní ìpínlẹ̀ Niger
Atẹjade kan latọdọ awọn alaṣẹ ile ẹkọ naa eyi ti agbẹnusọ fun giwa ibẹ, Foluṣọ Ogunmọdẹde ṣalaye pe ileewe naa ko ni fi aaye gba iwa aitọ.
O ni: bẹẹni oṣiṣẹ koṣiṣẹ to ba ṣe lodi si iwa ọmọluwabi ni ileewe naa bi o ti wulẹ ko mọ yoo foju wina ofin.
Giwa ileẹkọ naa tun fi kun un pe rirọọkun ti wọn ni ki Ọmọwe Mbachaga o lọ rọọkun nile ni lati lee faaye silẹ fun agbekalẹ igbimọ ẹlẹni marun un kan ti wọn yan.
O ni giwa ile ẹkọ naa gbe igbimọ yii kalẹ lati wadii ẹsun ti wọn fi kan an lọna ati lee mọ otitọ gbogbo to rọ mọ.
Bakan naa ni Giwa ileewe naa tun paṣẹ fun adari ẹka ẹkọ imọ nipa Ọrọ ẹda ati ihuwasi ọmọniyan nileẹkọ giga fasiti naa lati ṣe iwadii lori irufẹ ẹsun nina ọwọ aṣemaṣe ibalopọ si ọkan lara awọn akẹkọọ ni ileẹkọ naa.
O ni ki wọn tun ṣayẹwo irufẹ ẹsun bẹẹ gbogbo ti wọn tun fi kan olukọni miran ni ẹka ẹkọ naa.
- 'Kò sí ààtò fún òfin Sharia àti ẹtọ àwa ẹlẹsìn Islam nínú Oduduwa Republic, a ò gbà!'
- Ọwọ́ ikọ̀ Amọtẹkun ba Mutiu Abdul-Rasheed, afurasí tó ń ta ẹ̀yà ara èèyàn ní Ibadan
- Ilẹ̀ Yorùbá kìí ṣe ibi kátàkárà fún yín, ẹ̀yin àgbà tẹ ń gbárùkù ti ọ̀dọ́ lẹ́yìn láti máa da ìlú rú ẹ sọ́ra - Ẹgbẹ́ YWG
- Èrò Akeredolu ni yẹ́n, àwa aṣòfin á ṣẹ̀sẹ̀ jókòó láti yọ tàǹda kúrò nínú ìrẹsí nígba tó bá ya- Senetọ Ajibola
- Òṣìsẹ̀ 170 tí Ajimobi lé ni Lautech ni ń o gbà padà, owó osù márun wọ́n yoo di sísan- Gómínà Oyo















