Constitution review: A fẹ́ kí ará ìlú túbọ̀ ráàyè sọ̀rọ̀ nípa ohun tí wọ́n fẹ́ / kò fẹ́ ni- Ajibola Bashir

Bashir

Oríṣun àwòrán, @Bashir

Kini Ile Igbimọ Asofin Agba fi daa pada fun Akeredolu?

Awọn aṣofin agba naa ti daa pada fun un pe ti ara rẹ lo sọ.

Agbẹnusọ fun ile aṣofin agba, Sẹnetọ Ajibọla Bashiru ni ti ara Akeredolu lo n sọ.

Senetọ Ajibola Bashiru to n ṣoju Osun Central nipinlẹ Osun lo fun un lesi pe ọrọ ko ri bẹẹ.

Agbenusọ naa ni ero ọkan gomina Akeredolu lo fi sita yẹn, awọn ara ilu to ku naa ṣi ni anfani lati sọ ero ti wọn naa.

O tun nilẹyin eyi ni awọn Aṣofin yoo wa joko pẹlu ase lati yọ awọn ero ti ko gbadun da ni ti wọn yoo si mu ero to maa mu ilọsiwaju lo.

Àkọlé fídíò, Oba Gbolahan Timson Shomolu Bariga ní 'Restructuring'ti bọ́ aṣọ kò bá Omọyẹ mọ́!

Awọn aṣofin agba lorilẹ-ede Naijiria ti fun gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu lesi ọrọ rẹ to sọ.

Orọ naa ni pe Akeredolu pe fun wiwọgile ileegbimọ aṣofin apapọ ninu atunṣe iwe ofin orilẹede Naijiria ti awọn aṣofin naa n gbero.

Akeredolu pè fún wíwọ́gilé iléègbìmọ̀ aṣòfin àgbà, àwọn aṣofin àgba ní tẹnu ara rẹ̀ ló ń sọ

Gomina Rotimi Akeredolu ti ipinlẹ̀ Ondo

Oríṣun àwòrán, twitter/Akeredolu

Akeredolu ninu iwoye rẹ nibi apero finukonu lori atunto iwe ofin naa eyi tawọn aṣoju-ṣofin ṣe nilu Akurẹ ṣalaye pe asiko to fun orilẹ-ede Naijiria lati boju wo bibẹgile eto iṣofin oloju meji ti o n ṣe lọwọ.

Koda, o tun ni ki o si sọọ di ẹyọ kan ninu eyi ti ipinlẹ kọọkan yoo ti ni awọn aṣofin mẹrin lati ṣoju rẹ.

Akeredolu pè fún wíwọ́gilé iléègbìmọ̀ aṣòfin àgbà, àwọn aṣofin àgba ní tẹnu ara rẹ̀ ló ń sọ

Ati pe eredi ipade itagbangba lori atunto iwe ofin Naijiria ni lati gbọ oniruuru ero ọkan araalu lori rẹ.

Amọṣa o, araalu ni yoo papa pinnu ohun ti wọn ba n fẹ ni ilana agbekalẹ abala kẹsan iwe ofin Naijiria ti ọdun 1999.

Àkọlé fídíò, Adebayo Murital David: Gbogbo iṣẹ́ tó ń múni là láyé wá láti ọpọlọ ni kìí ṣe agbára

Lara awọn ohun ti gomina Akeredolu, ti igbakeji rẹ Lucky Aiyedatiwa ṣoju fun, ṣalaye ni pe iṣẹ aṣofin ko yẹ ko jẹ ajokoti bii ikoko ọbẹ.

Bikoṣe eyi ti awọn aṣofin yoo maa wọle wa ṣe ni atigbadegba.

Bẹẹni ko si yẹ fawọn aṣofin lati gba owo oṣu kankan ti ko han si igbimọ to n pin owo ijọba lorilẹ-ede Naijiria, RMAC

Àkọlé fídíò, 'Èmi ọmọ Ikorodu ọ̀ga, ọmọ aṣalẹ̀ jẹ́jẹ! Wo bí àwọn ọmọdé tó "tuush" yìí ṣe ń fi oríkì Yorùbá dábíra