Harzard Allowance: Ìjọba Nàìjíríà ṣàfikún owó aàbò fáwọn òṣìṣẹ́ elétò ìlera

Oríṣun àwòrán, Ngige
Ìjọba àpapọ̀ ní Nàìjíríà tí fún àwọn òṣìṣẹ́ ẹ̀ka ètò ìlèra ní àfikún owó ìdá 350% sí 600% gẹ́gẹ́ bí owó àjẹ́mónú ewu lẹ́nu iṣẹ́.
Lọ́bẹ́ àfíkún owó náà, àwọn òṣìṣẹ́ kéékèké yóò má gba ìdá àádọ́ta lé ní ọ̀ọ̀dúrún, nígbà tí àwọn àgbààgbà lẹ́nu iṣẹ́ yóò má gba ìdá ẹgbẹ̀ta gẹ́gẹ́ bí àfikún tíwọn.
Mínísítà fún ètò ìgbanisíṣẹ́ àti ọ̀rọ̀ òṣìṣẹ́ Chris Ngige, kéde ọ̀rọ̀ yìí ní ọjọ́ Isegun lẹ́yìn ìpàdé láàrín ìjọba apapọ̀ àti asójú àwọn oṣísẹ́ tó fí mọ́ àwọn ẹgbẹ́ àwọn oṣiṣẹ́ ilera.
- UNILAG jáwé lọ gbélé ẹ fún àwọn olùkọ̀ méjì tí BBC tú àṣírí wọn nínú fíìmù 'Sex For Grades'
- Bíi ti UK, USA, Germany, France lẹ ó lè ṣe ẹ̀sìn tó bá wù yín yàlàyòlò ní orílẹ̀èdè Yorùbá Nation - Igboho
- Pope Francis ṣe àyípadà òfin nínú ìjọ Aguda, ó sọ nkan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àlùfáà tó bá ní ìbálòpọ̀ kò tọ́
- Òṣìsẹ̀ 170 tí Ajimobi lé ni Lautech ni ń o gbà padà, owó osù márun wọ́n yoo di sísan- Gómínà Oyo
- Ohun tí wọ́n ní kí òkóbó Buhari bọ̀ lórí ọ̀rọ̀ àbò ni kó bọ̀, dípò dídúnmọ̀huru mọ́ aráàlú- PDP
Ètò ìpàdé náà tó wáyé gbọ̀gán gbogbonìṣe nínú ilé ìjọba l'Abuja.
Ngige ti tún fẹnu kò pé kí wan sún àsìkò ìfẹ̀yìntì àwọn dókítà, àti àwọn òṣìṣẹ́ ètò ìlera mííràn láti ọdún ọgọ́ta ọdún sí ọdún márùnlélọ́gọ́ta àti ọdún àádọ́rín fáwọ́n dókítà àgbà.
Ìpàdé òun dálé ọ̀rọ̀ owó àjẹmónú ewu lẹ́nu iṣẹ́ àti ọjọ́ orí ìfẹ̀yìnti àwọn òṣìṣẹ́ ètò iléra.
Mínísítà sọ pé ìhà tí ìjọba apapọ̀ ní pé mínísítà kékere lórí ètò ìsúna ọmọ ọba Clem Agba tí tako iye owó tí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ dókìtà (NMA) àti ẹgbẹ́ àwọn òṣìṣẹ́ ètò ilera (JOHESU) mú wá.
" Ìjọba pèsè nǹkan tí ó le sé ṣe láti san, pàápàá jùlọ nítorí bí ètò ọ̀rọ̀ ajé ṣe rí, ọ̀pọ̀ iṣẹ́ gbòògì ti ìjọba ń ṣe ló dálé owó yíyá, tí ibi ti ìjọba tí n rówó pàápàá kò fi bẹ́ẹ̀ ṣe dáada mọ́.
" Nítorí náà wọ́n yóò lọ jábọ̀ fún àwọn ènìyàn wọ́n lórí nǹkan tí ìjọba lágbara láti ṣe."
Ngige fìdí èyí múlẹ̀ nínú àtẹ̀jáde kan ti ìgbákeji olùdarí ètò ìròyìn Charles Akpan fọ́wọ́ sí.
Bákan náà ni àtẹjáde náà fi kun pé kí àwọn adéhùn wọ́n wọ̀nyìí wà bẹ́ẹ̀ títí tí àwọn asojú ẹgbẹ́ yóò fí lọ jábọ̀ fún àwọn ènìyàn kí wọn si padà fún ọ̀rọ̀ sísọ láàrín ọ̀ṣẹ̀ méjì fún ìdúnadúrà míiràn.
Ngige ni bílíọ̀nù mọ́kànlélọ́gbọ̀n ní ìjọba àpapọ̀ ná láàrín oṣù mẹ́tà lórí àwọn òṣìṣẹ́ ètò ààbò lásìkò àjàkálẹ̀ ààrùn Covid-19.

Oríṣun àwòrán, Health workers
"Sùgbọ́n a ti sún kúrò láti sísan ẹgbẹ̀rún márùn naírà lósù títi di àsìkò tí ọ̀rọ̀ Covikd-19 bẹ́ sílẹ̀ èyí sì mú kí ìjọba náà bílíọ̀nù mọ́kànlélọ́gbọ́n láàrín oṣù mẹ́ta.
"Ní tẹ̀mi, mo gba pé ìjọba ti ṣe dáadaa fún àwọn òṣìṣẹ́ yìí láti sún iye tí àwọn òṣìsẹ́ ilérà kékèké sí ìdá ààdọ́ta lé lọ́ọ̀dúnrún àti ìdá ẹgbẹta fún àwọn àgbà òṣìṣẹ́.
- Agbébọn pa ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá nígbàkan rí, Christopher Deja
- Lẹ́kṣọ́rà fásitì FUOYE kan tún kó sí gbaga ẹ̀sùn aṣemáṣe pẹ̀lú akẹ́kọ̀ọ́
- Ènìyàn 28 kú lẹ́yìn ààrùn Coronaviris láàrín wákàtí 24 ní Nàìjíríà
- Ọwọ́ ikọ̀ Amọtẹkun ba Mutiu Abdul-Rasheed, afurasí tó ń ta ẹ̀yà ara èèyàn ní Ibadan
- Ẹ̀yin òṣìṣẹ́ ìjọba, dẹndẹ ìyà yóò jẹ orí yín bí Nàìjíríà bá pínyà pẹ́rẹ́, toríi Yoruba Nation! - Oluwo
- Èrò Akeredolu ni yẹ́n, àwa aṣòfin á ṣẹ̀sẹ̀ jókòó láti yọ tàǹda kúrò nínú ìrẹsí nígba tó bá ya- Senetọ Ajibola














